< Psalms 69 >

1 For the Leader; upon Shoshannim. A Psalm of David. Save me, O God; for the waters are come in even unto the soul.
Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
2 I am sunk in deep mire, where there is no standing; I am come into deep waters, and the flood overwhelmeth me.
Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
3 I am weary of my crying; my throat is dried; mine eyes fail while I wait for my God.
Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
4 They that hate me without a cause are more than the hairs of my head; they that would cut me off, being mine enemies wrongfully, are many; should I restore that which I took not away?
Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
5 O God, Thou knowest my folly; and my trespasses are not hid from Thee.
Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
6 Let not them that wait for Thee be ashamed through me, O Lord GOD of hosts; let not those that seek Thee be brought to confusion through me, O God of Israel.
Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
7 Because for Thy sake I have borne reproach; confusion hath covered my face.
Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
8 I am become a stranger unto my brethren, and an alien unto my mother's children.
Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
9 Because zeal for Thy house hath eaten me up, and the reproaches of them that reproach Thee are fallen upon me.
nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10 And I wept with my soul fasting, and that became unto me a reproach.
Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11 I made sackcloth also my garment, and I became a byword unto them.
nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
12 They that sit in the gate talk of me; and I am the song of the drunkards.
Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
13 But as for me, let my prayer be unto Thee, O LORD, in an acceptable time; O God, in the abundance of Thy mercy, answer me with the truth of Thy salvation.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
14 Deliver me out of the mire, and let me not sink; let me be delivered from them that hate me, and out of the deep waters.
Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
15 Let not the waterflood overwhelm me, neither let the deep swallow me up; and let not the pit shut her mouth upon me.
Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
16 Answer me, O LORD, for Thy mercy is good; according to the multitude of Thy compassions turn Thou unto me.
Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
17 And hide not Thy face from Thy servant; for I am in distress; answer me speedily.
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
18 Draw nigh unto my soul, and redeem it; ransom me because of mine enemies.
Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
19 Thou knowest my reproach, and my shame, and my confusion; mine adversaries are all before Thee.
Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
20 Reproach hath broken my heart; and I am sore sick; and I looked for some to show compassion, but there was none; and for comforters, but I found none.
Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
21 Yea, they put poison into my food; and in my thirst they gave me vinegar to drink.
Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
22 Let their table before them become a snare; and when they are in peace, let it become a trap.
Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
23 Let their eyes be darkened, that they see not; and make their loins continually to totter.
Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
24 Pour out Thine indignation upon them, and let the fierceness of Thine anger overtake them.
Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
25 Let their encampment be desolate; let none dwell in their tents.
Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
26 For they persecute him whom Thou hast smitten; and they tell of the pain of those whom Thou hast wounded.
Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
27 Add iniquity unto their iniquity; and let them not come into Thy righteousness.
Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
28 Let them be blotted out of the book of the living, and not be written with the righteous.
Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
29 But I am afflicted and in pain; let Thy salvation, O God, set me up on high.
Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
30 I will praise the name of God with a song, and will magnify Him with thanksgiving.
Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
31 And it shall please the LORD better than a bullock that hath horns and hoofs.
Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
32 The humble shall see it, and be glad; ye that seek after God, let your heart revive.
Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
33 For the LORD hearkeneth unto the needy, and despiseth not His prisoners.
Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
34 Let heaven and earth praise Him, the seas, and every thing that moveth therein.
Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
35 For God will save Zion, and build the cities of Judah; and they shall abide there, and have it in possession.
nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
36 The seed also of His servants shall inherit it; and they that love His name shall dwell therein.
àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.

< Psalms 69 >