< Psalms 58 >
1 For the Leader; Al-tashheth. A Psalm of David; Michtam. Do ye indeed speak as a righteous company? Do ye judge with equity the sons of men?
Fún adarí orin. Tí ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Ẹ̀yin ha ń sọ òdodo nítòótọ́ ẹ̀yin ìjọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ tí ó ṣe títọ́ ẹ̀yìn ọmọ ènìyàn?
2 Yea, in heart ye work wickedness; ye weigh out in the earth the violence of your hands.
Bẹ́ẹ̀ kọ́, nínú ọkàn yín ẹ̀yìn ń gbèrò àìṣòdodo, ọwọ́ yín sì tú ìwà ipá jáde ni ayé.
3 The wicked are estranged from the womb; the speakers of lies go astray as soon as they are born.
Ní inú ìyá wọn wá ni ènìyàn búburú tí ṣìnà, lójúkan náà tí a ti bí wọn, wọn a máa ṣèké.
4 Their venom is like the venom of a serpent; they are like the deaf asp that stoppeth her ear;
Oró wọn dàbí oró ejò, wọn dàbí adití ejò paramọ́lẹ̀ tí ó di ara rẹ̀ ni etí,
5 Which hearkeneth not to the voice of charmers, or of the most cunning binder of spells.
tí kò ní gbọ́ ìpè àwọn atunilójú, bí ó ti wù kí ó máa fi ọgbọ́n ṣe ìtujú tó.
6 Break their teeth, O God, in their mouth; break out the cheek-teeth of the young lions, O LORD.
Ká eyín ẹnu wọn, Ọlọ́run; ní ẹnu wọn, ká ọ̀gàn àwọn ọmọ kìnnìún, Olúwa.
7 Let them melt away as water that runneth apace; when he aimeth his arrows, let them be as though they were cut off.
Jẹ́ kí wọn parẹ́ bí omi tó ń sàn lọ; nígbà tí ó bá fa ọfà rẹ̀, kí ọ̀kọ̀ wọn kí ó ṣẹ́.
8 Let them be as a snail which melteth and passeth away; like the untimely births of a woman, that have not seen the sun.
Jẹ́ kí wọn rí bí ìgbín tí rẹ̀ dànù tí ó sì ṣègbé bí ọmọ tí oṣù rẹ̀ kò pé, kí wọn má ṣe rí oòrùn.
9 Before your pots can feel the thorns, He will sweep it away with a whirlwind, the raw and the burning alike.
Kí ìkòkò yín kí ó tó mọ ìgbóná ẹ̀gún; bóyá ní tútù tàbí ní gbígbẹ, yóò fi ìjì gbá wọn lọ.
10 The righteous shall rejoice when he seeth the vengeance; he shall wash his feet in the blood of the wicked.
Olódodo yóò yọ̀ nígbà a bá ń gbẹ̀san wọn, nígbà tí wọn bá wẹ ẹsẹ̀ wọn nínú ẹ̀jẹ̀ ènìyàn búburú.
11 And men shall say: 'Verily there is a reward for the righteous; verily there is a God that judgeth in the earth.'
Àwọn ènìyàn yóò wí pé, “Lóòtítọ́ èrè àwọn ń bẹ fún olódodo; lóòtítọ́ òun ni Ọlọ́run tí ń ṣe ìdájọ́ ní ayé.”