< Psalms 52 >

1 For the Leader. Maschil of David; when Doeg the Edomite came and told Saul, and said unto him: 'David is come to the house of Ahimelech.' Why boastest thou thyself of evil, O mighty man? The mercy of God endureth continually.
Fún adarí orin. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí Doegi ará Edomu tọ Saulu lọ láti sọ fún pé, “Dafidi wà ní ilé Ahimeleki.” Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe féfé nínú ìwà ìkà, ìwọ alágbára ọkùnrin? Èéṣe tí ìwọ fi ń gbéraga nígbà gbogbo, ìwọ ẹni ẹ̀gàn níwájú Ọlọ́run?
2 Thy tongue deviseth destruction; like a sharp razor, working deceitfully.
Ahọ́n rẹ̀ ń gbìmọ̀ ìparun; ó dàbí abẹ mímú, ìwọ ẹni tí ń hùwà ẹ̀tàn.
3 Thou lovest evil more than good; falsehood rather than speaking righteousness. (Selah)
Ìwọ fẹ́ràn ibi ju ìre lọ, àti èké ju kí ó sọ òtítọ́ lọ.
4 Thou lovest all devouring words, the deceitful tongue.
Ìwọ fẹ́ràn ọ̀rọ̀ ìpanilára gbogbo, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn!
5 God will likewise break thee for ever, He will take thee up, and pluck thee out of thy tent, and root thee out of the land of the living. (Selah)
Ọlọ́run yóò sì lù ọ́ bolẹ̀ láéláé, yóò sì dì ọ́ mú, yóò sì já ọ kúrò ni ibùjókòó rẹ, yóò sì fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè. (Sela)
6 The righteous also shall see, and fear, and shall laugh at him:
Àwọn olódodo yóò rí, wọn yóò sì bẹ̀rù wọn yóò sì rẹ́rìn-ín rẹ̀, wí pé,
7 'Lo, this is the man that made not God his stronghold; but trusted in the abundance of his riches, and strengthened himself in his wickedness.'
“Èyí ni ọkùnrin náà ti kò fi Ọlọ́run ṣe agbára rẹ̀, bí kò ṣe ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ rẹ̀ ni ó gbẹ́kẹ̀lé, ó sì mu ara rẹ̀ le nínú ìwà búburú rẹ̀.”
8 But as for me, I am like a leafy olive-tree in the house of God; I trust in the mercy of God for ever and ever.
Ṣùgbọ́n èmi dàbí igi Olifi tí ó gbilẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run; èmi gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọ́run tí kì í kùnà láé àti láéláé.
9 I will give Thee thanks for ever, because Thou hast done it; and I will wait for Thy name, for it is good, in the presence of Thy saints.
Èmi yóò yìn ọ títí fún ohun tí ó ti ṣe; èmi ní ìrètí nínú orúkọ rẹ, nítorí orúkọ rẹ dára. Èmi yóò yìn ọ́ níwájú àwọn ènìyàn mímọ́.

< Psalms 52 >