< Psalms 3 >

1 A Psalm of David, when he fled from Absalom his son. LORD, how many are mine adversaries become! Many are they that rise up against me.
Saamu ti Dafidi. Nígbà ti ó sá fún ọmọ rẹ̀ Absalomu. Olúwa, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí! Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó!
2 Many there are that say of my soul: 'There is no salvation for him in God.' (Selah)
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé “Ọlọ́run kò nígbà á là.” (Sela)
3 But thou, O LORD, art a shield about me; my glory, and the lifter up of my head.
Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, Olúwa; ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè.
4 With my voice I call unto the LORD, and He answereth me out of His holy mountain. (Selah)
Olúwa ni mo kígbe sókè sí, ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. (Sela)
5 I lay me down, and I sleep; I awake, for the LORD sustaineth me.
Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn; mo sì tún padà jí, nítorí Olúwa ni ó ń gbé mi ró.
6 I am not afraid of ten thousands of people, that have set themselves against me round about.
Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká.
7 Arise, O LORD; save me, O my God; for Thou hast smitten all mine enemies upon the cheek, Thou hast broken the teeth of the wicked.
Dìde, Olúwa! Gbà mí, Ọlọ́run mi! Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n; kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú.
8 Salvation belongeth unto the LORD; Thy blessing be upon Thy people. (Selah)
Láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìgbàlà ti wá. Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. (Sela)

< Psalms 3 >