< Psalms 16 >

1 Michtam of David. Keep me, O God; for I have taken refuge in Thee.
Miktamu ti Dafidi. Pa mí mọ́, Ọlọ́run, nítorí nínú rẹ ni ààbò mi wà.
2 I have said unto the LORD: 'Thou art my Lord; I have no good but in Thee';
Mo sọ fún Olúwa, “Ìwọ ni Olúwa mi, lẹ́yìn rẹ èmi kò ní ìre kan.”
3 As for the holy that are in the earth, they are the excellent in whom is all my delight.
Sí àwọn ènìyàn tí ó wà ní ayé, àwọn ni ológo nínú èyí tí ayọ̀ mí wà.
4 Let the idols of them be multiplied that make suit unto another; their drink-offerings of blood will I not offer, nor take their names upon my lips.
Ìṣòro àwọn wọ̀n-ọn-nì yóò pọ̀ sí i, àní àwọn tí ń tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn. Ẹbọ ohun mímu ẹ̀jẹ̀ wọn ni èmi kì yóò ta sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá orúkọ wọn lẹ́nu mi.
5 O LORD, the portion of mine inheritance and of my cup, Thou maintainest my lot.
Olúwa, ni ìpín ìní mi tí mo yàn àti ago mi, ó ti pa ohun tí í ṣe tèmi mọ́.
6 The lines are fallen unto me in pleasant places; yea, I have a goodly heritage.
Okùn ààlà ilẹ̀ ti bọ́ sí ọ̀dọ̀ mi ní ibi dídára; nítòótọ́ mo ti ní ogún rere.
7 I will bless the LORD, who hath given me counsel; yea, in the night seasons my reins instruct me.
Èmi yóò yin Olúwa, ẹni tí ó gbà mí ní ìyànjú; ní òru, ọkàn mí ń bá mi sọ̀rọ̀.
8 I have set the LORD always before me; surely He is at my right hand, I shall not be moved.
Mo ti gbé Olúwa síwájú mi ní ìgbà gbogbo. Nítorí tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún mi, a kì yóò mì mí.
9 Therefore my heart is glad, and my glory rejoiceth; my flesh also dwelleth in safety;
Nítorí èyí, ọkàn mi yọ̀, ahọ́n mi pẹ̀lú ń fò fáyọ̀; ara mi pẹ̀lú yóò sinmi ní ààbò,
10 For Thou wilt not abandon my soul to the nether-world; neither wilt Thou suffer Thy godly one to see the pit. (Sheol h7585)
nítorí ìwọ kò ní fi ọ̀kan sílẹ̀ nínú isà òkú, tàbí kí ìwọ jẹ́ kí ẹni mímọ́ rẹ kí ó rí ìdíbàjẹ́. (Sheol h7585)
11 Thou makest me to know the path of life; in Thy presence is fulness of joy, in Thy right hand bliss for evermore.
Ìwọ ti fi ipa ọ̀nà ìyè hàn mí; Ìwọ yóò kún mi pẹ̀lú ayọ̀ ní iwájú rẹ, pẹ̀lú ìdùnnú ayérayé ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.

< Psalms 16 >