< Psalms 124 >

1 A Song of Ascents; of David. 'If it had not been the LORD who was for us', let Israel now say;
Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi. “Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,” kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;
2 'If it had not been the LORD who was for us, when men rose up against us,
ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa, nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,
3 Then they had swallowed us up alive, when their wrath was kindled against us;
nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,
4 Then the waters had overwhelmed us, the stream had gone over our soul;
nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,
5 Then the proud waters had gone over our soul.'
nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa.
6 Blessed be the LORD, who hath not given us as a prey to their teeth.
Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.
7 Our soul is escaped as a bird out of the snare of the fowlers; the snare is broken, and we are escaped.
Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ.
8 Our help is in the name of the LORD, who made heaven and earth.
Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa, tí ó dá ọ̀run òun ayé.

< Psalms 124 >