< Job 8 >
1 Then answered Bildad the Shuhite, and said:
Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé,
2 How long wilt thou speak these things, seeing that the words of thy mouth are as a mighty wind?
“Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó? Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
3 Doth God pervert judgment? Or doth the Almighty pervert justice?
Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí? Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
4 If thy children sinned against Him, He delivered them into the hand of their transgression.
Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i, ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
5 If thou wouldest seek earnestly unto God, and make thy supplication to the Almighty;
Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò, tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
6 If thou wert pure and upright; surely now He would awake for thee, and make the habitation of thy righteousness prosperous.
Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin: ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ, òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
7 And though thy beginning was small, yet thy end should greatly increase.
Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í, bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.
8 For inquire, I pray thee, of the former generation, and apply thyself to that which their fathers have searched out —
“Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
9 For we are but of yesterday, and know nothing, because our days upon earth are a shadow —
Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan, nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
10 Shall not they teach thee, and tell thee, and utter words out of their heart?
Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ? Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
11 Can the rush shoot up without mire? Can the reed-grass grow without water?
Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀ tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
12 Whilst it is yet in its greenness, and not cut down, it withereth before any other herb.
Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀, ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀.
13 So are the paths of all that forget God; and the hope of the godless man shall perish;
Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
14 Whose confidence is gossamer, and whose trust is a spider's web.
Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò, àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
15 He shall lean upon his house, but it shall not stand; he shall hold fast thereby, but it shall not endure.
Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró, yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
16 He is green before the sun, and his shoots go forth over his garden.
Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn, ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
17 His roots are wrapped about the heap, he beholdeth the place of stones.
Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká, ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
18 If he be destroyed from his place, then it shall deny him: 'I have not seen thee.'
Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀, nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
19 Behold, this is the joy of his way, and out of the earth shall others spring.
Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.
20 Behold, God will not cast away an innocent man, neither will He uphold the evil-doers;
“Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
21 Till He fill thy mouth with laughter, and thy lips with shouting.
títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu, àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
22 They that hate thee shall be clothed with shame; and the tent of the wicked shall be no more.
ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”