< Ezekiel 12 >

1 The word of the LORD also came unto me, saying:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 'Son of man, thou dwellest in the midst of the rebellious house, that have eyes to see, and see not, that have ears to hear, and hear not; for they are a rebellious house.
“Ọmọ ènìyàn, ìwọ ń gbé ní àárín ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn. Wọ́n lójú láti fi ríran, ṣùgbọ́n wọn kò ríran, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n létí láti fi gbọ́rọ̀ ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́rọ̀, torí pé ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn ni wọ́n.
3 Therefore, thou son of man, prepare thee stuff for exile, and remove as though for exile by day in their sight; and thou shalt remove from thy place to another place in their sight; it may be they will perceive, for they are a rebellious house.
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, palẹ̀ ẹrù rẹ mọ́ láti lọ sí ìgbèkùn, ní ọ̀sán gangan ní ojú wọn, kúrò láti ibi tí ìwọ wà lọ sí ibòmíràn. Bóyá bí wọ́n bá rí ọ, wọn yóò sì ronú bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.
4 And thou shalt bring forth thy stuff by day in their sight, as stuff for exile; and thou shalt go forth thyself at even in their sight, as when men go forth into exile.
Di ẹrù ìgbèkùn rẹ lójú wọn ní ọ̀sán án gangan, nígbà tí ó bá sì di alẹ́, ní ojú wọn, máa lọ sí ìgbèkùn gẹ́gẹ́ bí àwọn tí ó lọ ìgbèkùn ṣe máa ń ṣe.
5 Dig thou through the wall in their sight, and carry out thereby.
Dá ògiri lu ní ojú wọn, kí ìwọ sì gba ibẹ̀ kó ẹrù rẹ jáde.
6 In their sight shalt thou bear it upon thy shoulder, and carry it forth in the darkness; thou shalt cover thy face, that thou see not the ground; for I have set thee for a sign unto the house of Israel.'
Gbé ẹrù rẹ lé èjìká ní ojú wọn, bo ojú rẹ, kí ìwọ má ba à rí ilẹ̀, sì ru ẹrù rẹ lọ ní alẹ́ nítorí pé mo fi ọ́ ṣe àmì fún ilé Israẹli.”
7 And I did so as I was commanded: I brought forth my stuff by day, as stuff for exile, and in the even I digged through the wall with my hand; I carried out in the darkness, and bore it upon my shoulder in their sight.
Mo ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi. Mo kó ẹrù mi jáde ní ọ̀sán án láti lọ fun ìgbèkùn. Nígbà tó di ìrọ̀lẹ́, mo dá ògiri lu pẹ̀lú ọwọ́ mi. Mo sì gbe ẹrù mi lé èjìká nínú òkùnkùn ní ojú wọn.
8 And in the morning came the word of the LORD unto me, saying:
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
9 'Son of man, hath not the house of Israel, the rebellious house, said unto thee: What doest thou?
“Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli tilẹ̀ bi ọ́ pé, ‘Kí ni ohun tí o ń ṣe túmọ̀ sí?’
10 Say thou unto them: Thus saith the Lord GOD: Concerning the prince, even this burden, in Jerusalem, and all the house of Israel among whom they are,
“Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ yìí kan àwọn ọmọ-aládé Jerusalẹmu àti gbogbo ilé Israẹli tí ó wà ní àárín rẹ.
11 say: I am your sign: like as I have done, so shall it be done unto them — they shall go into exile, into captivity.
Sọ fún wọn pé, Èmi jẹ́ àmì fún yín’. “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí wọn. Wọn ó kó lọ sí ìgbèkùn. Gẹ́gẹ́ bí ẹni ti a dè ní ìgbèkùn.
12 And the prince that is among them shall bear upon his shoulder, and go forth in the darkness; they shall dig through the wall to carry out thereby; he shall cover his face, that he see not the ground with his eyes.
“Ọmọ-aládé tí ó wà ní àárín wọn yóò di ẹrù rẹ̀ lé èjìká ní alẹ́ yóò sì jáde lọ, òun náà yóò da ògiri lu kí ó le gba ibẹ̀ jáde. Yóò sì bo ojú rẹ̀ kí ó má ba à rí ilẹ̀.
13 My net also will I spread upon him, and he shall be taken in My snare; and I will bring him to Babylon to the land of the Chaldeans; yet shall he not see it, though he shall die there.
Èmi yóò ta àwọ̀n mi lé e lórí, yóò sì kó sínú okùn, Èmi yóò sì mú lọ sí Babeli, ní ilẹ̀ Kaldea, ṣùgbọ́n kò ní fojúrí ilẹ̀ náà ibẹ̀ ni yóò kú sí.
14 And I will disperse toward every wind all that are round about him to help him, and all his troops; and I will draw out the sword after them.
Gbogbo àwọn tó yí i ká láti ràn án lọ́wọ́ ọ̀pá ìtẹ̀lẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ni Èmi yóò túká sí afẹ́fẹ́, èmi yóò sì tún fi idà lé wọn kiri.
15 And they shall know that I am the LORD, when I shall scatter them among the nations, and disperse them in the countries.
“Wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa nígbà tí mo bá tú wọn ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì fọ́n wọn ká sí ilẹ̀ káàkiri.
16 But I will leave a few men of them from the sword, from the famine, and from the pestilence; that they may declare all their abominations among the nations whither they come; and they shall know that I am the LORD.'
Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ díẹ̀ kù lára wọn, ní ọwọ́ idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, kí wọn le jẹ́wọ́ gbogbo ìṣe ìríra wọn ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè yìí. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
17 Moreover the word of the LORD came to me, saying:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
18 'Son of man, eat thy bread with quaking, and drink thy water with trembling and with anxiety;
“Ọmọ ènìyàn, jẹ oúnjẹ rẹ pẹ̀lú ìwárìrì, sì mu omi rẹ pẹ̀lú ìwárìrì àti àìbalẹ̀ àyà.
19 and say unto the people of the land: Thus saith the Lord GOD concerning the inhabitants of Jerusalem in the land of Israel. They shall eat their bread with anxiety, and drink their water with appalment, that her land may be desolate from all that is therein, because of the violence of all them that dwell therein.
Sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti ilẹ̀ Israẹli pé, pẹ̀lú àìbalẹ̀ àyà ni wọn yóò máa jẹun wọn, wọn yóò sì mu omi pẹ̀lú àìnírètí, kí ilẹ̀ wọn lè di ahoro torí ìwà ipá àwọn tó ń gbé ibẹ̀.
20 And the cities that are inhabited shall be laid waste, and the land shall be desolate; and ye shall know that I am the LORD.'
Ìlú tó jẹ́ ibùgbé ènìyàn tẹ́lẹ̀ yóò di òfo, ilẹ̀ náà yóò sì di ahoro. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
21 And the word of the LORD came unto me, saying:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
22 'Son of man, what is that proverb that ye have in the land of Israel, saying: The days are prolonged, and every vision faileth?
“Ọmọ ènìyàn, irú òwe wo ni ẹ pa nílẹ̀ Israẹli pé: ‘A fa ọjọ́ gùn, gbogbo ìran di asán’?
23 Tell them therefore: Thus saith the Lord GOD: I will make this proverb to cease, and they shall no more use it as a proverb in Israel; but say unto them: The days are at hand, and the word of every vision.
Nítorí náà wí fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò fi òpin sí òwe yìí, wọn kò ní ipa mọ́ ní Israẹli.’ Sọ fún wọn, ‘Ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí nígbà tí gbogbo ìran àti ìsọtẹ́lẹ̀ yóò sì wá sí ìmúṣẹ.
24 For there shall be no more any vain vision nor smooth divination within the house of Israel.
Nítorí kò ní sí ìran asán tàbí àfọ̀ṣẹ tí ó ń pọ́n ni mọ́ ní àárín ilé Israẹli.
25 For I am the LORD; I will speak, what word soever it be that I shall speak, and it shall be performed; it shall be no more delayed; for in your days, O rebellious house, will I speak the word, and will perform it, saith the Lord GOD.'
Ṣùgbọ́n, Èmi Olúwa yóò sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò sì ṣẹ láì falẹ̀. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ní àsìkò yín, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀ ilé ni Èmi yóò mú ọ̀rọ̀ yówù tí mo bá sọ ṣẹ.’”
26 Again the word of the LORD came to me, saying:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
27 'Son of man, behold, they of the house of Israel say: The vision that he seeth is for many days to come, and he prophesieth of times that are far off.
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ń wí pé, ‘Ìran ọjọ́ pípẹ́ ni ìwọ rí, ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ nípa àsìkò tó jìnnà réré.’
28 Therefore say unto them: Thus saith the Lord GOD: There shall none of My words be delayed any more, but the word which I shall speak shall be performed, saith the Lord GOD.'
“Nítorí náà sọ fún wọn, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, kò sí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ mi tí yóò sún síwájú mọ́; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ tí mo bá sọ yóò ṣẹ.’”

< Ezekiel 12 >