< Deuteronomy 33 >

1 And this is the blessing wherewith Moses the man of God blessed the children of Israel before his death.
Èyí ni ìbùkún tí Mose ènìyàn Ọlọ́run bùkún fún àwọn ọmọ Israẹli kí ó tó kú.
2 And he said: The LORD came from Sinai, and rose from Seir unto them; He shined forth from mount Paran, and He came from the myriads holy, at His right hand was a fiery law unto them.
Ó sì wí pé, “Olúwa ti Sinai wá, ó sì yọ sí wọn láti Seiri wá ó sì tàn án jáde láti òkè Parani wá. Ó ti ọ̀dọ̀ ẹgbẹgbàarùn-ún àwọn mímọ́ wá láti ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni òfin kan a mú bí iná ti jáde fún wọn wá.
3 Yea, He loveth the peoples, all His holy ones — they are in Thy hand; and they sit down at Thy feet, receiving of Thy words.
Nítòótọ́, ó fẹ́ràn àwọn ènìyàn an rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ wà ní ọwọ́ rẹ̀. Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti foríbalẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀,
4 Moses commanded us a law, an inheritance of the congregation of Jacob.
òfin tí Mose fi fún wa, ìní ti ìjọ ènìyàn Jakọbu.
5 And there was a king in Jeshurun, when the heads of the people were gathered, all the tribes of Israel together.
Òun ni ọba lórí Jeṣuruni ní ìgbà tí olórí àwọn ènìyàn péjọpọ̀, pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
6 Let Reuben live, and not die in that his men become few.
“Jẹ́ kí Reubeni yè kí ó má ṣe kú, tàbí kí ènìyàn rẹ mọ níwọ̀n.”
7 And this for Judah, and he said: Hear, LORD, the voice of Judah, and bring him in unto his people; his hands shall contend for him, and Thou shalt be a help against his adversaries.
Èyí ni ohun tí ó sọ nípa Juda: “Olúwa gbọ́ ohùn Juda kí o sì mú tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ wá. Kí ọwọ́ rẹ̀ kí ó tó fún un, kí ó sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀!”
8 And of Levi he said: Thy Thummim and Thy Urim be with Thy holy one, whom Thou didst prove at Massah, with whom Thou didst strive at the waters of Meribah;
Ní ti Lefi ó wí pé, “Jẹ́ kí Tumimu àti Urimu rẹ kí ó wà pẹ̀lú ẹni mímọ́ rẹ. Ẹni tí ó dánwò ní Massa, ìwọ bá jà ní omi Meriba.
9 Who said of his father, and of his mother: 'I have not seen him'; neither did he acknowledge his brethren, nor knew he his own children; for they have observed Thy word, and keep Thy covenant.
Ó wí fún baba àti ìyá rẹ pé, ‘Èmi kò buyì fún wọn.’ Kò mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, tàbí mọ àwọn ọmọ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó dúró lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
10 They shall teach Jacob Thine ordinances, and Israel Thy law; they shall put incense before Thee, and whole burnt-offering upon Thine altar.
Ó kọ́ Jakọbu ní ìdájọ́ rẹ̀ àti Israẹli ní òfin rẹ̀. Ó mú tùràrí wá síwájú rẹ̀ àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹbọ sísun sórí i pẹpẹ rẹ̀.
11 Bless, LORD, his substance, and accept the work of his hands; smite through the loins of them that rise up against him, and of them that hate him, that they rise not again.
Bùsi ohun ìní rẹ̀, Olúwa, kí o sì tẹ́wọ́gbà iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀. Lu ẹgbẹ́ àwọn tí ó dìde sí i; àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, kí wọn kí ó má ṣe dìde mọ́.”
12 Of Benjamin he said: The beloved of the LORD shall dwell in safety by Him; He covereth him all the day, and He dwelleth between his shoulders.
Ní ti Benjamini ó wí pé, “Jẹ́ kí olùfẹ́ Olúwa máa gbé ní àlàáfíà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun a máa bò ó ní gbogbo ọjọ́, ẹni tí Olúwa fẹ́ràn yóò máa sinmi láàrín èjìká rẹ̀.”
13 And of Joseph he said: Blessed of the LORD be his land; for the precious things of heaven, for the dew, and for the deep that coucheth beneath,
Ní ti Josẹfu ó wí pé, “Kí Olúwa bùkún ilẹ̀ rẹ, fún ohun iyebíye láti ọ̀run pẹ̀lú ìrì àti ibú tí ó ń bẹ níṣàlẹ̀;
14 And for the precious things of the fruits of the sun, and for the precious things of the yield of the moons,
àti fún èso iyebíye tí ọ̀run mú wá àti ti ohun iyebíye tí ń dàgbà ní oṣooṣù;
15 And for the tops of the ancient mountains, and for the precious things of the everlasting hills,
pẹ̀lú ohun pàtàkì òkè ńlá ìgbàanì àti fún ohun iyebíye ìgbà ayérayé;
16 And for the precious things of the earth and the fulness thereof, and the good will of Him that dwelt in the bush; let the blessing come upon the head of Joseph, and upon the crown of the head of him that is prince among his brethren.
Pẹ̀lú ohun iyebíye ayé àti ẹ̀kún un rẹ̀ àti fún ìfẹ́ ẹni tí ó ń gbé inú igbó. Jẹ́ kí gbogbo èyí sinmi lé orí Josẹfu, lórí àtàrí ẹni tí ó yàtọ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀.
17 His firstling bullock, majesty is his; and his horns are the horns of the wild-ox; with them he shall gore the peoples all of them, even the ends of the earth; and they are the ten thousands of Ephraim, and they are the thousands of Manasseh.
Ní ọláńlá ó dàbí àkọ́bí akọ màlúù; ìwo rẹ̀, ìwo àgbáǹréré ni. Pẹ̀lú wọn ni yóò fi ti àwọn orílẹ̀-èdè, pàápàá títí dé òpin ayé. Àwọn sì ni ẹgbẹẹgbàárùn mẹ́wàá Efraimu, àwọn sì ni ẹgbẹẹgbẹ̀rún Manase.”
18 And of Zebulun he said: Rejoice, Zebulun, in thy going out, and, Issachar, in thy tents.
Ní ti Sebuluni ó wí pé, “Yọ̀ Sebuluni, ní ti ìjáde lọ rẹ, àti ìwọ Isakari, nínú àgọ́ rẹ.
19 They shall call peoples unto the mountain; there shall they offer sacrifices of righteousness; for they shall suck the abundance of the seas, and the hidden treasures of the sand.
Wọn yóò pe àwọn ènìyàn sórí òkè àti níbẹ̀ wọn yóò rú ẹbọ òdodo, wọn yóò mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òkun, nínú ìṣúra tí ó pamọ́ nínú iyanrìn.”
20 And of Gad he said: Blessed be He that enlargeth Gad; he dwelleth as a lioness, and teareth the arm, yea, the crown of the head.
Ní ti Gadi ó wí pé, “Ìbùkún ni ẹni tí ó mú Gadi gbilẹ̀! Gadi ń gbé níbẹ̀ bí kìnnìún, ó sì fa apá ya, àní àtàrí.
21 And he chose a first part for himself, for there a portion of a ruler was reserved; and there came the heads of the people, he executed the righteousness of the LORD, and His ordinances with Israel.
Ó sì yan ilẹ̀ tí ó dára jù fún ara rẹ̀; ìpín olórí ni a sì fi fún un. Nígbà tí ó rí tí gbogbo àwọn ènìyàn péjọ, ó mú òdodo Olúwa ṣẹ, àti ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli.”
22 And of Dan he said: Dan is a lion's whelp, that leapeth forth from Bashan.
Ní ti Dani ó wí pé, “Ọmọ kìnnìún ni Dani, tí ń fò láti Baṣani wá.”
23 And of Naphtali he said: O Naphtali, satisfied with favour, and full with the blessing of the LORD: possess thou the sea and the south.
Ní ti Naftali ó wí pé, “Ìwọ Naftali, kún fún ojúrere Ọlọ́run àti ìbùkún Olúwa; yóò jogún ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gúúsù.”
24 And of Asher he said: Blessed be Asher above sons; let him be the favoured of his brethren, and let him dip his foot in oil.
Ní ti Aṣeri ó wí pé, “Ìbùkún ọmọ ni ti Aṣeri; jẹ́ kí ó rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kí ó sì ri ẹsẹ̀ rẹ̀ sínú òróró.
25 Iron and brass shall be thy bars; and as thy days, so shall thy strength be.
Bàtà rẹ̀ yóò jẹ́ irin àti idẹ, agbára rẹ̀ yóò sì rí bí ọjọ́ rẹ̀.
26 There is none like unto God, O Jeshurun, who rideth upon the heaven as thy help, and in His excellency on the skies.
“Kò sí ẹlòmíràn bí Ọlọ́run Jeṣuruni, ẹni tí ń gun ọ̀run fún ìrànlọ́wọ́ rẹ àti ní ojú ọ̀run nínú ọláńlá rẹ̀.
27 The eternal God is a dwelling-place, and underneath are the everlasting arms; and He thrust out the enemy from before thee, and said: 'Destroy.'
Ọlọ́run ayérayé ni ibi ìsádi rẹ, àti ní ìsàlẹ̀ ni apá ayérayé wà. Yóò lé àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ, ó sì wí pé, ‘Ẹ máa parun!’
28 And Israel dwelleth in safety, the fountain of Jacob alone, in a land of corn and wine; yea, his heavens drop down dew.
Israẹli nìkan yóò jókòó ní àlàáfíà, orísun Jakọbu nìkan ní ilẹ̀ ọkà àti ti ọtí wáìnì, níbi tí ọ̀run ti ń sẹ ìrì sílẹ̀.
29 Happy art thou, O Israel, who is like unto thee? a people saved by the LORD, the shield of thy help, and that is the sword of thy excellency! And thine enemies shall dwindle away before thee; and thou shalt tread upon their high places.
Ìbùkún ni fún ọ, Israẹli, ta ni ó dàbí rẹ, ẹni tí a gbàlà láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Òun ni asà àti ìrànwọ́ rẹ̀ àti idà ọláńlá rẹ̀. Àwọn ọ̀tá rẹ yóò tẹríba fún ọ, ìwọ yóò sì tẹ ibi gíga wọn mọ́lẹ̀.”

< Deuteronomy 33 >