< 1 Chronicles 2 >
1 These are the sons of Israel: Reuben, Simeon, Levi, and Judah, Issachar, and Zebulun;
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli. Reubeni, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Sebuluni,
2 Dan, Joseph, and Benjamin, Naphtali, Gad, and Asher.
Dani, Josẹfu, Benjamini; Naftali, Gadi: àti Aṣeri.
3 The sons of Judah: Er, and Onan, and Shelah; which three were born unto him of Bath-shua the Canaanitess. And Er, Judah's first-born, was wicked in the sight of the LORD; and He slew him.
Àwọn ọmọ Juda: Eri, Onani àti Ṣela, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kenaani, ọmọbìnrin Ṣua. Eri àkọ́bí Juda, ó sì burú ní ojú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.
4 And Tamar his daughter-in-law bore him Perez and Zerah. All the sons of Judah were five.
Tamari, aya ọmọbìnrin Juda, ó sì bí Peresi àti Sera sì ní ọmọ márùn-ún ní àpapọ̀.
5 The sons of Perez: Hezron, and Hamul.
Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
6 And the sons of Zerah: Zimri, and Ethan, and Heman, and Calcol, and Dara: five of them in all.
Àwọn ọmọ Sera: Simri, Etani, Hemani, Kalkoli àti Dara, gbogbo wọn jẹ́ márùn-ún.
7 And the sons of Carmi: Achar, the troubler of Israel, who committed a trespass concerning the devoted thing.
Àwọn ọmọ Karmi: Akani, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Israẹli nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.
8 And the sons of Ethan: Azariah.
Àwọn ọmọ Etani: Asariah.
9 The sons also of Hezron, that were born unto him: Jerahmeel, and Ram, and Chelubai.
Àwọn ọmọ tí a bí fún Hesroni ni: Jerahmeeli, Ramu àti Kalebu.
10 And Ram begot Amminadab; and Amminadab begot Nahshon, prince of the children of Judah;
Ramu sì ni baba Amminadabu, àti Amminadabu baba Nahiṣoni olórí àwọn ènìyàn Juda.
11 and Nahshon begot Salma, and Salma begot Boaz;
Nahiṣoni sì ni baba Salmoni, Salmoni ni baba Boasi,
12 and Boaz begot Obed, and Obed begot Jesse;
Boasi baba Obedi àti Obedi baba Jese.
13 and Jesse begot his first-born Eliab, and Abinadab the second, and Shimea the third;
Jese sì ni baba Eliabu àkọ́bí rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì sì ni Abinadabu, ẹlẹ́ẹ̀kẹta ni Ṣimea,
14 Nethanel the fourth, Raddai the fifth;
ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Netaneli, ẹlẹ́ẹ̀karùnún Raddai,
15 Ozem the sixth, David the seventh.
ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Osemu àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dafidi.
16 And their sisters were Zeruiah and Abigail. And the sons of Zeruiah: Abishai, and Joab, and Asahel, three.
Àwọn arábìnrin wọn ni Seruiah àti Abigaili. Àwọn ọmọ mẹ́ta Seruiah ni Abiṣai, Joabu àti Asaheli.
17 And Abigail bore Amasa; and the father of Amasa was Jether the Ishmaelite.
Abigaili ni ìyá Amasa, ẹni tí baba rẹ̀ sì jẹ́ Jeteri ará Iṣmaeli.
18 And Caleb the son of Hezron begot children of Azubah his wife — and of Jerioth — and these were her sons: Jesher, and Shobab, and Ardon.
Kalebu ọmọ Hesroni ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó rẹ̀ Asuba (láti ọ̀dọ̀ Jerioti). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ rẹ̀: Jeṣeri, Ṣobabu àti Ardoni.
19 And Azubah died, and Caleb took unto him Ephrath, who bore him Hur.
Nígbà tí Asuba sì kú, Kalebu sì fẹ́ Efrata ní aya, ẹni tí ó bí Huri fún un.
20 And Hur begot Uri, and Uri begot Bezalel.
Huri ni baba Uri, Uri sì jẹ́ baba Besaleli.
21 And afterward Hezron went in to the daughter of Machir the father of Gilead; whom he took to wife when he was threescore years old; and she bore him Segub.
Nígbà tí ó yá, Hesroni sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Makiri baba Gileadi (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Segubu.
22 And Segub begot Jair, who had three and twenty cities in the land of Gilead.
Segubu sì jẹ́ baba Jairi, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́tàlélógún ní ilẹ̀ Gileadi.
23 And Geshur and Aram took Havvoth-jair from them, with Kenath, and the villages thereof, even threescore cities. All these were the sons of Machir the father of Gilead.
(Ṣùgbọ́n Geṣuri àti Aramu sì fi agbára gba Hafoti-Jairi, àti Kenati pẹ̀lú gbogbo agbègbè rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Makiri baba Gileadi.
24 And after that Hezron was dead in Caleb-ephrath, then Abiah Hezron's wife bore him Ashhur the father of Tekoa.
Lẹ́yìn tí Hesroni sì kú ni Kalebu Efrata, Abijah ìyàwó rẹ̀ ti Hesroni sì bí Aṣihuri baba Tekoa fún un.
25 And the sons of Jerahmeel the first-born of Hezron were Ram the first-born, and Bunah, and Oren, and Ozem, Ahijah.
Ọmọ Jerahmeeli àkọ́bí Hesroni: Ramu ọmọ àkọ́bí rẹ̀ Buna, Oreni, Osemu àti Ahijah.
26 And Jerahmeel had another wife, whose name was Atarah; she was the mother of Onam.
Jerahmeeli ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Atara; ó sì jẹ́ ìyá fún Onamu.
27 And the sons of Ram the first-born of Jerahmeel were Maaz, and Jamin, and Eker.
Àwọn ọmọ Ramu àkọ́bí Jerahmeeli: Maasi, Jamini àti Ekeri.
28 And the sons of Onam were Shammai, and Jada; and the sons of Shammai: Nadab, and Abishur.
Àwọn ọmọ Onamu: Ṣammai àti Jada. Àwọn ọmọ Ṣammai: Nadabu àti Abiṣuri.
29 And the name of the wife of Abishur was Abihail; and she bore him Ahban, and Molid.
Orúkọ ìyàwó Abiṣuri ni Abihaili ẹni tí ó bí Ahbani àti Molidi.
30 And the sons of Nadab: Seled, and Appaim; but Seled died without children.
Àwọn ọmọ Nadabu Seledi àti Appaimu. Seledi sì kú láìsí ọmọ.
31 And the sons of Appaim: Ishi. And the sons of Ishi: Sheshan. And the sons of Sheshan: Ahlai.
Àwọn ọmọ Appaimu: Iṣi, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣeṣani. Ṣeṣani sì jẹ́ baba fún Ahlai.
32 And the sons of Jada the brother of Shammai: Jether, and Jonathan: and Jether died without children.
Àwọn ọmọ Jada, arákùnrin Ṣammai: Jeteri àti Jonatani. Jeteri sì kú láìní ọmọ.
33 And the sons of Jonathan: Peleth, and Zaza. These were the sons of Jerahmeel.
Àwọn ọmọ Jonatani: Peleti àti Sasa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Jerahmeeli.
34 Now Sheshan had no sons, but daughters. And Sheshan had a servant, an Egyptian, whose name was Jarha.
Ṣeṣani kò sì ní ọmọkùnrin àwọn ọmọbìnrin nìkan ni ó ní. Ó sì ní ìránṣẹ́ ará Ejibiti tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jariha.
35 So Sheshan gave his daughter to Jarha his servant to wife; and she bore him Attai.
Ṣeṣani sì fi ọmọ obìnrin rẹ̀ ní aya fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Jariha, ó sì bí ọmọ fún tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Attai.
36 And Attai begot Nathan, and Nathan begot Zabad;
Attai sì jẹ́ baba fún Natani, Natani sì jẹ́ baba fún Sabadi,
37 and Zabad begot Ephlal, and Ephlal begot Obed;
Sabadi ni baba Eflali, Eflali jẹ́ baba Obedi,
38 and Obed begot Jehu, and Jehu begot Azariah;
Obedi sì ni baba Jehu, Jehu ni baba Asariah,
39 and Azariah begot Helez, and Helez begot Eleasah;
Asariah sì ni baba Helesi, Helesi ni baba Eleasa,
40 and Eleasah begot Sisamai, and Sisamai begot Shallum;
Eleasa ni baba Sismai, Sismai ni baba Ṣallumu,
41 and Shallum begot Jekamiah, and Jekamiah begot Elishama.
Ṣallumu sì ni baba Jekamiah, Jekamiah sì ni baba Eliṣama.
42 And the sons of Caleb the brother of Jerahmeel were Mesha his first-born, who was the father of Ziph, and the sons of Mareshah the father of Hebron.
Àwọn ọmọ Kalebu arákùnrin Jerahmeeli: Meṣa àkọ́bí rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Sifi, àti àwọn ọmọ rẹ̀ Meraṣa, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hebroni.
43 And the sons of Hebron: Korah, and Tappuah, and Rekem, and Shema.
Àwọn ọmọ Hebroni: Kora, Tapua, Rekemu, àti Ṣema.
44 And Shema begot Raham, the father of Jorkeam; and Rekem begot Shammai.
Ṣema ni baba Rahamu, Rahamu sì jẹ́ baba fún Jorkeamu. Rekemu sì ni baba Ṣammai.
45 And the son of Shammai was Maon; and Maon was the father of Beth-zur.
Àwọn ọmọ Ṣammai ni Maoni, Maoni sì ni baba Beti-Suri.
46 And Ephah, Caleb's concubine, bore Haran, and Moza, and Gazez; and Haran begot Gazez.
Efani obìnrin Kalebu sì ni ìyá Harani, Mosa àti Gasesi, Harani sì ni baba Gasesi.
47 And the sons of Jahdai: Regem, and Jotham, and Geshan, and Pelet, and Ephah, and Shaaph.
Àwọn ọmọ Jahdai: Regemu, Jotamu, Geṣani, Peleti, Efani àti Ṣaafu.
48 Maacah, Caleb's concubine, bore Sheber and Tirhanah.
Maaka obìnrin Kalebu sì ni ìyá Seberi àti Tirhana.
49 And the wife of Shaaph the father of Madmannah bore Sheva the father of Machbenah and the father of Gibea. And the daughter of Caleb was Achsah.
Ó sì bí Ṣaafu baba Madmana, Ṣefa baba Makbena àti baba Gibeah, ọmọbìnrin Kalebu sì ni Aksa.
50 These were the sons of Caleb. The sons of Hur the first-born of Ephrath: Shobal the father of Kiriath-jearim;
Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kalebu. Àwọn ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata: Ṣobali baba Kiriati-Jearimu.
51 Salma the father of Beth-lehem, Hareph the father of Beth-gader.
Salma baba Bẹtilẹhẹmu àti Harefu baba Beti-Gaderi.
52 And Shobal the father of Kiriath-jearim had sons: Haroeh, and half of the Menuhoth.
Àwọn ọmọ Ṣobali baba Kiriati-Jearimu ni: Haroe, ìdajì àwọn ará Manaheti.
53 And the families of Kiriath-jearim: the Ithrites, and the Puthites, and the Shumathites, and the Mishraites; of them came the Zorathites, and the Eshtaolites.
Àti ìdílé Kiriati-Jearimu: àti àwọn ara Itri, àti àwọn ará Puti, àti àwọn ará Ṣumati àti àwọn ará Miṣraiti: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sorati àti àwọn ará Eṣtaoli ti wá.
54 The sons of Salma: Beth-lehem, and the Netophathites, Atroth-beth-joab, and half of the Manahathites, the Zorites.
Àwọn ọmọ Salma: Bẹtilẹhẹmu, àti àwọn ará Netofa, Atrotu Beti-Joabu, ìdajì àwọn ará Manahati, àti ará Sori,
55 And the families of scribes that dwelt at Jabez: the Tirathites, the Shimeathites, the Sucathites. These are the Kenites that came of Hammath, the father of the house of Rechab.
àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jabesi: àti àwọn ọmọ Tirati àti àwọn ará Ṣimeati àti àwọn ará Sukati. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Keni, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hamati, baba ilé Rekabu.