< 1 Chronicles 11 >

1 Then all Israel gathered themselves to David unto Hebron, saying: 'Behold, we are thy bone and thy flesh.
Gbogbo àwọn Israẹli kó ara wọn jọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa í ṣe.
2 In times past, even when Saul was king, it was thou that didst lead out and bring in Israel; and the LORD thy God said unto thee: Thou shalt feed My people Israel, and thou shalt be prince over My people Israel.'
Ní àtijọ́, kódà nígbà tí Saulu jẹ ọba, ìwọ ni ẹni tí ó darí Israẹli ní ojú ogun wọn. Olúwa Ọlọ́run rẹ sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò sì jẹ́ olùṣọ́ Israẹli ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún wọn.’”
3 So all the elders of Israel came to the king to Hebron; and David made a covenant with them in Hebron before the LORD; and they anointed David king over Israel, according to the word of the LORD by the hand of Samuel.
Nígbà tí gbogbo àwọn ìjòyè Israẹli tí wọ́n ti wá sọ́dọ̀ ọba Dafidi ni Hebroni. Ó sì ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú wọn ní Hebroni níwájú Olúwa, wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba lórí Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa láti ọwọ́ Samuẹli.
4 And David and all Israel went to Jerusalem — the same is Jebus — and the Jebusites, the inhabitants of the land, were there.
Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jáde lọ sí Jerusalẹmu (tí ṣe Jebusi). Àwọn Jebusi ara ilẹ̀ náà ń gbé níbẹ̀.
5 And the inhabitants of Jebus said to David: 'Thou shalt not come in hither.' Nevertheless David took the stronghold of Zion; the same is the city of David.
Àwọn ará ìlú Jebusi sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò sì gbọdọ̀ wọ ìhín yìí wá.” Ṣùgbọ́n Dafidi kó ìlú odi Sioni—èyí tí í ṣe ìlú Dafidi.
6 And David said: 'Whosoever smiteth the Jebusites first shall be chief and captain.' And Joab the son of Zeruiah went up first, and was made chief.
Dafidi ti wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá tètè kọlu àwọn ará Jebusi ni yóò di olórí àti balógun.” Joabu ọmọ Seruiah sì kọ́kọ́ gòkè lọ, bẹ́ẹ̀ ni ó sì gba olórí.
7 And David dwelt in the stronghold; therefore they called it the city of David.
Dafidi sì ń gbé inú ìlú odi, nítorí náà ni wọ́n fi ń pè é ni ìlú Dafidi.
8 And he built the city round about, from Millo even round about; and Joab repaired the rest of the city.
Ó sì kọ́ àwọn ìlú náà yíkákiri; láti Millo yíkákiri; Joabu sì tún ìyókù àwọn ìlú náà ṣe.
9 And David waxed greater and greater; for the LORD of hosts was with him.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ń ga, ó sì pọ̀ sí i, nítorí pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú rẹ̀.
10 Now these are the chief of the mighty men whom David had, who held strongly with him in his kingdom, together with all Israel, to make him king, according to the word of the LORD concerning Israel.
Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè alágbára ọkùnrin Dafidi, àwọn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fún ìjọba rẹ̀ ní àtìlẹ́yìn tó lágbára láti mú un tàn káàkiri gbogbo ilẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí.
11 And this is the number of the mighty men whom David had: Jashobeam, the son of a Hachmonite, the chief of the captains; he lifted up his spear against three hundred and slew them at one time.
Èyí sì ni iye àwọn akọni ọkùnrin Dafidi: Jaṣobeamu ọmọ Hakumoni, òun sì ni olórí nínú àwọn ìjòyè, ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa ní ogun ẹ̀ẹ̀kan.
12 And after him was Eleazar the son of Dodo, the Ahohite, who was one of the three mighty men.
Lẹ́yìn rẹ̀ sì ni Eleasari ọmọ Dodo àwọn ará Ahohi, ọ̀kan lára àwọn mẹ́ta ọkùnrin alágbára.
13 He was with David at Pas-dammim, and there the Philistines were gathered together to battle, where was a plot of ground full of barley; and the people fled from before the Philistines.
Ó sì wà pẹ̀lú Dafidi ní Pasi-Dammimu nígbà tí àwọn ará Filistini kó ara wọn jọ láti jagun, níbi tí ilẹ̀ kan wà tí ó kún fún ọkà barle. Àwọn ènìyàn sì sálọ kúrò níwájú Filistini.
14 But they stood in the midst of the plot, and defended it, and slew the Philistines; and the LORD saved them by a great victory.
Ṣùgbọ́n wọ́n mú ìdúró wọn ní àárín pápá náà. Wọ́n sì gbà a wọ́n sì gún àwọn ará Filistini mọ́lẹ̀, Olúwa sì mú ìgbàlà ńlá fún wọn.
15 And three of the thirty chiefs went down to the rock to David, unto the cave of Adullam; and the host of the Philistines were encamped in the valley of Rephaim.
Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀ tọ́ Dafidi wá lọ sí orí àpáta nínú ihò Adullamu, nígbà tí àwọn ẹgbẹ́ Filistini sì dúró ní àfonífojì ní orí òkè Refaimu.
16 And David was then in the stronghold, and the garrison of the Philistines was then in Beth-lehem.
Ní àsìkò náà Dafidi sì ń bẹ nínú ìlú odi, ẹgbẹ́ ogun àwọn ará Filistini sì ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu.
17 And David longed, and said: 'Oh that one would give me water to drink of the well of Beth-lehem, which is by the gate!'
Dafidi sí pòǹgbẹ fún omi ó sì wí pé, “Háà, ẹnìkan yóò ha bu omi láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu fún un mu?”
18 And the three broke through the host of the Philistines, and drew water out of the well of Beth-lehem, that was by the gate, and took it, and brought it to David; but David would not drink thereof, but poured it out unto the LORD,
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn mẹ́ta náà sì là láti ogun ará Filistini, ó sì fa omi jáde láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu ó sì gbé padà tọ Dafidi wá. Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti mu ú: dípò, ó sì tú jáde níwájú Olúwa.
19 and said: 'My God forbid it me, that I should do this; shall I drink the blood of these men that have put their lives in jeopardy? for with the jeopardy of their lives they brought it.' Therefore he would not drink it. These things did the three mighty men.
“Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí èmi ó má ṣe ṣe èyí!” ó wí pé. “Ṣé kí èmi kí ó mú ẹ̀jẹ̀ ọkùnrin yí ẹni tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu?” Nítorí wọ́n fi ẹ̀mí wọn wéwu láti mú padà wá, Dafidi kò ní mu ú. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn akọni mẹ́ta ọkùnrin náà ṣe ohun ìyanu ńlá.
20 And Abishai, the brother of Joab, he was chief of the three; for he lifted up his spear against three hundred and slew them, and had a name among the three.
Abiṣai arákùnrin Joabu ìjòyè àwọn mẹ́ta. Ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún àwọn ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn mẹ́ta.
21 Of the three in the second rank he was the most honourable, and was made their captain; howbeit he attained not to the first three.
Ó sì gba ìlọ́po ọlá lórí àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ó sì di olórí wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ka kún ara wọn.
22 Beniah the son of Jehoiada, the son of a valiant man of Kabzeel, who had done mighty deeds, he smote the two altar-hearths of Moab; he went down also and slew a lion in the midst of a pit in time of snow.
Benaiah ọmọ Jehoiada ó sì jẹ́ akọni oníjà láti Kabṣeeli, ẹni tí ó ṣe iṣẹ́ agbára ńlá. Ó sì pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu, ó sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí inú ihò lákokò yìnyín dídì, ó sì pa kìnnìún kan
23 And he slew an Egyptian, a man of great stature, five cubits high; and in the Egyptian's hand was a spear like a weaver's beam; and he went down to him with a staff, and plucked the spear out of the Egyptian's hand, and slew him with his own spear.
Ó sì pa ara Ejibiti ẹni tí ó ga ní ìwọ̀n ẹsẹ̀ méje àti ààbọ̀ ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti wọn ní ọ̀kọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìdábùú igi ahunṣọ àti ọ̀pá ní ọwọ́ rẹ̀, Benaiah sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú kùmọ̀. Ó sì gba ọ̀kọ̀ náà láti ọwọ́ ará Ejibiti ó sì pa á pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀.
24 These things did Benaiah the son of Jehoiada, and had a name among the three mighty men.
Nǹkan wọ̀nyí sì ní ìwà akin Benaiah ọmọ Jehoiada; ohun náà pẹ̀lú sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn akọni ọkùnrin mẹ́ta.
25 Behold, he was more honourable than the thirty, but he attained not to the first three; and David set him over his guard.
Ó sì ní ọlá púpọ̀ ju àwọn ọgbọ̀n lọ, ṣùgbọ́n a kò kà á láàrín àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta. Dafidi sì fi sí ìkáwọ́ àwọn ẹ̀ṣọ́.
26 Also the mighty men of valour: Asahel the brother of Joab, Elhanan the son of Dodo of Beth-lehem;
Àwọn akọni ọkùnrin náà nìyí: Asaheli arákùnrin Joabu, Elhanani ọmọ Dodo láti Bẹtilẹhẹmu,
27 Shammoth the Harorite, Helez the Pelonite;
Ṣamotu ará Harori, Helesi ará Peloni
28 Ira the son of Ikkesh the Tekoite, Abiezer the Anathothite;
Ira ọmọ Ikẹsi láti Tekoa, Abieseri láti Anatoti,
29 Sibbecai the Hushathite, Ilai the Ahohite;
Sibekai ará Huṣati, láti ará Ahohi
30 Mahrai the Netophathite, Heled the son of Baanah the Netophathite;
Maharai ará Netofa, Heledi ọmọ Baanah ará Netofa,
31 Ithai the son of Ribai of Gibeah of the children of Benjamin, Benaiah the Pirathonite;
Itai ọmọ Ribai láti Gibeah ní Benjamini, Benaiah ará Piratoni,
32 Hurai of Nahale-gaash, Abiel the Arbathite;
Hurai láti àfonífojì Gaaṣi, Abieli ará Arbati,
33 Azmaveth the Baharumite, Eliahba the Shaalbonite;
Asmafeti ará Bahurimu Eliaba ará Ṣaalboni.
34 the sons of Hashem the Gizonite, Jonathan the son of Shageh the Hararite;
Àwọn ọmọ Haṣemu ará Gisoni Jonatani ọmọ Ṣage ará Harari.
35 Ahiam the son of Sacar the Hararite, Eliphal the son of Ur;
Ahiamu ọmọ Sakari ará Harari, Elifali ọmọ Uri
36 Hepher the Mecherathite, Ahijah the Pelonite;
Heferi ará Mekerati, Ahijah ará Peloni,
37 Hezro the Carmelite, Naarai the son of Ezbai;
Hesro ará Karmeli Naarai ọmọ Esbai,
38 Joel the brother of Nathan, Mibhar the son of Hagri;
Joẹli arákùnrin Natani Mibari ọmọ Hagari,
39 Zelek the Ammonite, Nahrai the Berothite, the armour-bearer of Joab the son of Zeruiah;
Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beroti ẹni tí ó jẹ́ ẹni tí n ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah.
40 Ira the Ithrite, Gareb the Ithrite;
Ira ará Itri, Garebu ará Itri,
41 Uriah the Hittite, Zabad the son of Ahlai;
Uriah ará Hiti Sabadi ọmọ Ahlai.
42 Adina the son of Shiza the Reubenite, a chief of the Reubenites, and thirty with him;
Adina ọmọ Ṣisa ará Reubeni, ẹni tí ó jẹ́ ìjòyè ará Reubeni, àti pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀.
43 Hanan the son of Maacah, and Joshaphat the Mithnite;
Hanani ọmọ Maaka. Jehoṣafati ará Mitini.
44 Uzzia the Ashterathite, Shama and Jeiel the sons of Hotham the Aroerite;
Ussia ará Asiterati, Ṣama àti Jeieli àwọn ọmọ Hotami ará Aroeri,
45 Jediael the son of Shimri, and Joha his brother, the Tizite;
Jediaeli ọmọ Ṣimri, àti arákùnrin Joha ará Tisi
46 Eliel the Mahavite, and Jeribai, and Joshaviah, the sons of Elnaam, and Ithmah the Moabite;
Elieli ará Mahafi Jeribai àti Joṣafia àwọn ọmọ Elnaamu, Itimah ará Moabu,
47 Eliel, and Obed, and Jaasiel the Mezobaite.
Elieli, Obedi àti Jaasieli ará Mesoba.

< 1 Chronicles 11 >