< Zechariah 6 >

1 Againe, I turned and lift vp mine eyes, and looked: and beholde, there came foure charets out from betweene two mountaines, and the mountaines were mountaines of brasse.
Mo sì yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, kẹ̀kẹ́ mẹ́rin jáde wá láti àárín òkè ńlá méjì, àwọn òkè ńlá náà sì jẹ́ òkè ńlá idẹ.
2 In the first charet were red horses, and in the second charet blacke horses,
Àwọn ẹṣin pupa wà ní kẹ̀kẹ́ èkínní; àti àwọn ẹṣin dúdú ní kẹ̀kẹ́ èkejì.
3 And in the thirde charet white horses, and in the fourth charet, horses of diuers colours, and reddish.
Àti àwọn ẹṣin funfun ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹta; àti àwọn adíkálà àti alágbára ẹṣin ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹrin.
4 Then I answered, and saide vnto the Angell that talked with mee, What are these, my Lord?
Mo sì dáhùn, mo sì béèrè lọ́wọ́ angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni ìwọ̀nyí, olúwa mi.”
5 And the Angell answered, and sayde vnto mee, These are the foure spirites of the heauen, which goe foorth from standing with the Lord of all the earth.
Angẹli náà si dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀mí mẹ́rin ti ọ̀run, tí wọn ń lọ kúrò lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ara wọn hàn níwájú Olúwa gbogbo ayé.
6 That with the blacke horse went forth into the land of the North, and the white went out after them, and they of diuers colours went forth toward the South countrey.
Àwọn ẹṣin dúdú tí ó wà nínú rẹ̀ jáde lọ sí ilẹ̀ àríwá; àwọn funfun sì jáde lọ si ìwọ̀-oòrùn; àwọn adíkálà sì jáde lọ sí ìhà ilẹ̀ gúúsù.”
7 And the reddish went out, and required to go, and passe through the world, and he sayde, Goe passe through the worlde. So they went thorowout the world.
Àwọn alágbára ẹṣin sì jáde lọ, wọ́n sì ń wá ọ̀nà àti lọ kí wọn bá a lè rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ni ayé; ó sì wí pé, “Ẹ lọ, ẹ lọ rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé!” Wọ́n sì rín síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé.
8 Then cryed hee vpon me, and spake vnto me, saying, Beholde, these that goe towarde the North countrey, haue pacified my spirit in the North countrey.
Nígbà náà ni ohùn kan sì ké sí mi, ó sì bá mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wò ó, àwọn wọ̀nyí tí ó lọ síhà ilẹ̀ àríwá ti mú ẹ̀mí mi parọ́rọ́ ni ilẹ̀ àríwá.”
9 And the worde of the Lord came vnto me, saying,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
10 Take of them of ye captiuitie, euen of Heldai, and of Tobijah, and Iedaiah, which are come from Babel, and come thou the same day, and goe vnto the house of Ioshiah, the sonne of Zephaniah.
“Mú nínú ìgbèkùn, nínú àwọn Heldai, tí Tobiah, àti ti Jedaiah, tí ó ti Babeli dé, kí ìwọ sì wá ní ọjọ́ kan náà, kí o sì wọ ilé Josiah ọmọ Sefaniah lọ.
11 Take euen siluer, and golde, and make crownes, and set them vpon the head of Iehoshua, the sonne of Iehozadak the hie Priest,
Kí o sì mú fàdákà àti wúrà, kí o sì fi ṣe adé púpọ̀, sì gbé wọn ka orí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
12 And speake vnto him, saying, Thus speaketh the Lord of hostes, and sayth, Behold the man whose name is the Branch, and he shall growe vp out of his place, and he shall build the Temple of the Lord.
Sì sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé, wo ọkùnrin náà ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹ̀ka; yóò sì yọ ẹ̀ka láti abẹ́ rẹ̀ wá, yóò si kọ́ tẹmpili Olúwa wa.
13 Euen hee shall build the Temple of the Lord, and he shall beare the glory, and shall sit and rule vpon his throne, and he shalbe a Priest vpon his throne, and the counsell of peace shall be betweene them both.
Òun ni yóò sì kọ́ tẹmpili Olúwa òun ni yóò sì wọ̀ ní ògo, yóò sì jókòó, yóò sì jẹ ọba lórí ìtẹ́ rẹ̀; òun ó sì jẹ́ àlùfáà lórí ìtẹ́ rẹ̀; ìmọ̀ àlàáfíà yóò sì wá láàrín àwọn méjèèjì.’
14 And the crownes shall be to Helem, and to Tobijah, and to Iedaiah, and to Hen the sonne of Zephaniah, for a memoriall in the Temple of the Lord.
Adé wọ̀nyí yóò sì wà fún Helemu àti fún Tobiah, àti fún Jedaiah, àti fún Heni ọmọ Sefaniah fún ìrántí ni tẹmpili Olúwa.
15 And they that are farre off, shall come and build in the Temple of the Lord, and ye shall know, that the Lord of hostes hath sent me vnto you. And this shall come to passe, if ye will obey the voyce of the Lord your God.
Àwọn tí ó jìnnà réré yóò wá láti kọ́ tẹmpili Olúwa, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rán mi sí yín. Yóò sì rí bẹ́ẹ̀ bí ẹ̀yin yóò bá gbà ohùn Olúwa, Ọlọ́run yín gbọ́ nítòótọ́.”

< Zechariah 6 >