< Ruth 4 >
1 Then went Boaz vp to the gate, and sate there, and beholde, the kinsman, of whome Boaz had spoken, came by: and he sayd, Ho, snch one, come, sit downe here. And he turned, and sate downe.
Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
2 Then he tooke ten men of the Elders of the citie, and sayd, Sit ye downe here. And they sate downe.
Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
3 And he said vnto ye kinsman, Naomi, that is come againe out of ye countrey of Moab, wil sell a parcel of land, which was our brother Elimelechs.
ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
4 And I thought to aduertise thee, saying, Buy it before the assistants, and before the Elders of my people. If thou wilt redeeme it, redeeme it: but if thou wilt not redeeme it, tel me: for I know that there is none besides thee to redeeme it, and I am after thee. Then he answered, I wil redeeme it.
Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
5 Then said Boaz, What day thou buyest the field of the hand of Naomi, thou mnst also buy it of Ruth the Moabitesse the wife of the dead, to stirre vp the name of the dead, vpon his inheritance.
Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
6 And the kinsman answered, I can not redeeme it, lest I destroy mine owne inheritance: redeeme my right to thee, for I can not redeeme it.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
7 Now this was the maner beforetime in Israel, concerning redeeming and changing, for to stablish all things: a man did plucke off his shooe, and gaue it his neighbour, and this was a sure witnes in Israel.
Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
8 Therefore the kinsman sayd to Boas, Buy it for thee: and he drew off his shooe.
Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
9 And Boaz sayd vnto the Elders and vnto all the people, Ye are witnesses this day, that I haue bought all that was Elimelechs, and all that was Chilions and Mahlons, of the hand of Naomi.
Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
10 And moreouer, Ruth the Moabitesse the wife of Mahlon, haue I bought to be my wife, to stirre vp the name of the dead vpon his inheritance, and that the name of the dead be not put out from among his brethren, and from the gate of his place: ye are witnesses this day.
Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
11 And all the people that were in the gate, and the Elders sayd, We are witnesses: the Lord make the wife that commeth into thine house, like Rahel and like Leah, which twaine did build the house of Israel: and that thou mayest doe worthily in Ephrathah, and be famous in Beth-lehem,
Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
12 And that thine house be like the house of Pharez (whom Thamar bare vnto Iudah) of the seede which the Lord shall giue thee of this yong woman.
Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
13 So Boaz tooke Ruth, and she was his wife: and when he went in vnto her, the Lord gaue that she conceiued, and bare a sonne.
Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
14 And the women sayd vnto Naomi, Blessed be the Lord, which hath not left thee this day without a kinsman, and his name shalbe continued in Israel.
Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
15 And this shall bring thy life againe, and cherish thine olde age: for thy daughter in lawe which loueth thee, hath borne vnto him, and she is better to thee then seuen sonnes.
Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
16 And Naomi tooke the childe, and layde it in her lap, and became nource vnto it.
Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
17 And the women her neighbours gaue it a name, saying, There is a childe borne to Naomi, and called the name thereof Obed: the same was the father of Ishai, the father of Dauid.
Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
18 These now are ye generations of Pharez: Pharez begate Hezron,
Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
19 And Hezron begate Ram, and Ram begate Amminadab,
Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
20 And Amminadab begate Nahshon, and Nahshon begate Salmah,
Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
21 And Salmon begate Boaz, and Boaz begat Obed,
Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
22 And Obed begate Ishai, and Ishai begate Dauid.
Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.