< Psalms 90 >

1 A prayer of Moses, the man of God. Lord, thou hast bene our habitation from generation to generation.
Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run. Olúwa, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
2 Before the mountaines were made, and before thou hadst formed the earth, and the world, euen from euerlasting to euerlasting thou art our God.
Kí a tó bí àwọn òkè ńlá àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé, láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
3 Thou turnest man to destruction: againe thou sayest, Returne, ye sonnes of Adam.
Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀, wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
4 For a thousande yeeres in thy sight are as yesterday when it is past, and as a watch in the night.
Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún ọdún bá kọjá lójú rẹ, bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
5 Thou hast ouerflowed them: they are as a sleepe: in the morning he groweth like the grasse:
Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú; wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
6 In the morning it florisheth and groweth, but in the euening it is cut downe and withereth.
Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
7 For we are consumed by thine anger, and by thy wrath are we troubled.
A pa wá run nípa ìbínú rẹ nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
8 Thou hast set our iniquities before thee, and our secret sinnes in the light of thy countenance.
Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ, àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
9 For all our dayes are past in thine anger: we haue spent our yeeres as a thought.
Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ; àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
10 The time of our life is threescore yeeres and ten, and if they be of strength, fourescore yeeres: yet their strength is but labour and sorowe: for it is cut off quickly, and we flee away.
Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá, bi ó sì ṣe pé nípa agbára tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún, agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni, nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò, àwa a sì fò lọ.
11 Who knoweth the power of thy wrath? for according to thy feare is thine anger.
Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ? Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
12 Teach vs so to nomber our dayes, that we may apply our heartes vnto wisdome.
Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára, kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
13 Returne (O Lord, howe long?) and be pacified toward thy seruants.
Yípadà, Olúwa! Yóò ti pẹ́ tó? Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
14 Fill vs with thy mercie in the morning: so shall we reioyce and be glad all our dayes.
Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ, kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀ kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
15 Comfort vs according to the dayes that thou hast afflicted vs, and according to the yeeres that we haue seene euill.
Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú, fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
16 Let thy worke bee seene towarde thy seruants, and thy glory vpon their children.
Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
17 And let the beautie of the Lord our God be vpon vs, and direct thou the worke of our hands vpon vs, euen direct the worke of our handes.
Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa; fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa, bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.

< Psalms 90 >