< Psalms 24 >

1 A Psalme of David. The earth is the Lordes, and all that therein is: the worlde and they that dwell therein.
Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
2 For he hath founded it vpon the seas: and established it vpon the floods.
nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
3 Who shall ascende into the mountaine of the Lord? and who shall stand in his holy place?
Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
4 Euen he that hath innocent handes, and a pure heart: which hath not lift vp his minde vnto vanitie, nor sworne deceitfully.
Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
5 He shall receiue a blessing from the Lord, and righteousnesse from the God of his saluation.
Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
6 This is the generation of them that seeke him, of them that seeke thy face, this is Iaakob. (Selah)
Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
7 Lift vp your heads ye gates, and be ye lift vp ye euerlasting doores, and the King of glory shall come in.
Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
8 Who is this King of glorie? the Lord, strong and mightie, euen the Lord mightie in battell.
Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
9 Lift vp your heads, ye gates, and lift vp your selues, ye euerlasting doores, and the King of glorie shall come in.
Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
10 Who is this King of glory? the Lord of hostes, he is the King of glorie. (Selah)
Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)

< Psalms 24 >