< Psalms 132 >

1 A song of degrees. Lord, remember Dauid with all his affliction.
Orin fún ìgòkè. Olúwa, rántí Dafidi nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
2 Who sware vnto the Lord, and vowed vnto the mightie God of Iaakob, saying,
Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa, tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
3 I will not enter into the tabernacle of mine house, nor come vpon my pallet or bed,
Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ, bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
4 Nor suffer mine eyes to sleepe, nor mine eye lids to slumber,
Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi, tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
5 Vntill I finde out a place for the Lord, an habitation for the mightie God of Iaakob.
títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa, ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
6 Lo, we heard of it in Ephrathah, and found it in the fieldes of the forest.
Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata: àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
7 We will enter into his Tabernacles, and worship before his footestoole.
Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀: àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
8 Arise, O Lord, to come into thy rest, thou, and the Arke of thy strength.
Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ: ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
9 Let thy Priests be clothed with righteousnesse, and let thy Saints reioyce.
Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ: kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
10 For thy seruant Dauids sake refuse not the face of thine Anointed.
Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
11 The Lord hath sworne in trueth vnto Dauid, and he wil not shrinke from it, saying, Of the fruite of thy body will I set vpon thy throne.
Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi, Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀, nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
12 If thy sonnes keepe my couenant, and my testimonies, that I shall teach them, their sonnes also shall sit vpon thy throne for euer.
Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́ àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
13 For the Lord hath chosen Zion, and loued to dwell in it, saying,
Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni: ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
14 This is my rest for euer: here will I dwell, for I haue a delite therein.
Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé: níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé: nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
15 I will surely blesse her vitailes, and will satisfie her poore with bread,
Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀: èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
16 And will clothe her Priests with saluation, and her Saints shall shoute for ioye.
Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀: àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
17 There will I make the horne of Dauid to bud: for I haue ordeined a light for mine Anoynted.
Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀, èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
18 His enemies will I clothe with shame, but on him his crowne shall florish.
Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.

< Psalms 132 >