< Psalms 106 >

1 Praise ye the Lord. Praise ye the Lord because he is good, for his mercie endureth for euer.
Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
2 Who can expresse the noble actes of the Lord, or shewe forth all his prayse?
Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
3 Blessed are they that keepe iudgement, and doe righteousnesse at all times.
Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
4 Remember me, O Lord, with the fauour of thy people: visite me with thy saluation,
Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
5 That I may see the felicitie of thy chosen, and reioyce in the ioy of thy people, and glorie with thine inheritance.
kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
6 We haue sinned with our fathers: we haue committed iniquitie, and done wickedly.
Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
7 Our fathers vnderstoode not thy wonders in Egypt, neither remembred they the multitude of thy mercies, but rebelled at the Sea, euen at the red sea.
Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
8 Neuerthelesse he saued them for his Names sake, that he might make his power to be knowen.
Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
9 And he rebuked the red Sea, and it was dryed vp, and he led them in the deepe, as in the wildernesse.
O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
10 And he saued them from ye aduersaries hand, and deliuered them from ye hand of the enemie.
O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
11 And the waters couered their oppressours: not one of them was left.
Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
12 Then beleeued they his wordes, and sang prayse vnto him.
Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
13 But incontinently they forgate his workes: they wayted not for his counsell,
Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
14 But lusted with concupiscence in the wildernes, and tempted God in the desert.
Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
15 Then he gaue them their desire: but he sent leannesse into their soule.
Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
16 They enuied Moses also in the tentes, and Aaron the holy one of the Lord.
Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
17 Therefore the earth opened and swallowed vp Dathan, and couered the companie of Abiram.
Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
18 And the fire was kindled in their assembly: the flame burnt vp the wicked.
Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
19 They made a calfe in Horeb, and worshipped the molten image.
Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
20 Thus they turned their glory into the similitude of a bullocke, that eateth grasse.
Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
21 They forgate God their Sauiour, which had done great things in Egypt,
Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
22 Wonderous woorkes in the lande of Ham, and fearefull things by the red Sea.
iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
23 Therefore he minded to destroy them, had not Moses his chosen stand in the breach before him to turne away his wrath, least he shoulde destroy them.
Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
24 Also they contemned that pleasant land, and beleeued not his worde,
Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
25 But murmured in their tentes, and hearkened not vnto the voice of the Lord.
Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
26 Therefore hee lifted vp his hande against them, to destroy them in the wildernesse,
Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
27 And to destroy their seede among the nations, and to scatter them throughout the countries.
láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
28 They ioyned themselues also vnto Baalpeor, and did eate the offrings of the dead.
Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
29 Thus they prouoked him vnto anger with their owne inuentions, and the plague brake in vpon them.
wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
30 But Phinehas stoode vp, and executed iudgement, and the plague was staied.
Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
31 And it was imputed vnto him for righteousnes from generation to generation for euer.
A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
32 They angred him also at the waters of Meribah, so that Moses was punished for their sakes,
Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
33 Because they vexed his spirite, so that hee spake vnaduisedly with his lippes.
Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
34 Neither destroied they the people, as the Lord had commanded them,
Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
35 But were mingled among the heathen, and learned their workes,
Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
36 And serued their idoles, which were their ruine.
Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
37 Yea, they offered their sonnes, and their daughters vnto deuils,
Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
38 And shed innocent blood, euen the blood of their sonnes, and of their daughters, whome they offred vnto the idoles of Canaan, and the lande was defiled with blood.
Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
39 Thus were they steined with their owne woorkes, and went a whoring with their owne inuentions.
Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
40 Therefore was the wrath of the Lord kindled against his people, and he abhorred his owne inheritance.
Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
41 And hee gaue them into the hande of the heathen: and they that hated them, were lordes ouer them.
Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
42 Their enemies also oppressed them, and they were humbled vnder their hand.
Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
43 Many a time did hee deliuer them, but they prouoked him by their counsels: therefore they were brought downe by their iniquitie.
Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
44 Yet hee sawe when they were in affliction, and he heard their crie.
Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
45 And he remembred his couenant towarde them and repented according to the multitude of his mercies,
ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
46 And gaue them fauour in the sight of all them that lead them captiues.
Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
47 Saue vs, O Lord our God, and gather vs from among the heathen, that we may praise thine holy Name, and glorie in thy praise.
Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
48 Blessed be the Lord God of Israel for euer and euer, and let all the people say, So be it. Praise yee the Lord.
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!

< Psalms 106 >