< Psalms 105 >

1 Praise the Lord, and call vpon his Name: declare his workes among the people.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Sing vnto him, sing prayse vnto him, and talke of all his wonderous workes.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Reioyce in his holy Name: let the heart of them that seeke the Lord, reioyce.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Seeke the Lord and his strength: seeke his face continually.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Remember his marueilous woorkes, that he hath done, his wonders and the iudgements of his mouth,
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 Ye seede of Abraham his seruant, ye children of Iaakob, which are his elect.
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 He is the Lord our God: his iudgements are through all the earth.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 He hath alway remembred his couenant and promise, that he made to a thousand generations,
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 Euen that which he made with Abraham, and his othe vnto Izhak:
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 And since hath confirmed it to Iaakob for a lawe, and to Israel for an euerlasting couenant,
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 Saying, Vnto thee will I giue the land of Canaan, the lot of your inheritance.
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 Albeit they were fewe in nomber, yea, very fewe, and strangers in the land,
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 And walked about from nation to nation, from one kingdome to another people,
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 Yet suffered he no man to doe them wrong, but reprooued Kings for their sakes, saying,
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 Touche not mine anointed, and doe my Prophets no harme.
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Moreouer, he called a famine vpon ye land, and vtterly brake the staffe of bread.
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 But he sent a man before them: Ioseph was solde for a slaue.
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 They helde his feete in the stockes, and he was laide in yrons,
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 Vntill his appointed time came, and the counsell of the Lord had tryed him.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 The King sent and loosed him: euen the Ruler of the people deliuered him.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 He made him lord of his house, and ruler of all his substance,
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 That he shoulde binde his princes vnto his will, and teach his Ancients wisedome.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Then Israel came to Egypt, and Iaakob was a stranger in the land of Ham.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 And he increased his people exceedingly, and made them stronger then their oppressours.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 He turned their heart to hate his people, and to deale craftily with his seruants.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 Then sent he Moses his seruant, and Aaron whom he had chosen.
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 They shewed among them the message of his signes, and wonders in the land of Ham.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 He sent darkenesse, and made it darke: and they were not disobedient vnto his commission.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 He turned their waters into blood, and slewe their fish.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Their land brought foorth frogs, euen in their Kings chambers.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 He spake, and there came swarmes of flies and lice in all their quarters.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 He gaue them haile for raine, and flames of fire in their land.
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 He smote their vines also and their figge trees, and brake downe the trees in their coastes.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 He spake, and the grashoppers came, and caterpillers innumerable,
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 And did eate vp all the grasse in their land, and deuoured the fruite of their ground.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 He smote also all the first borne in their land, euen the beginning of all their strength.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 He brought them forth also with siluer and golde, and there was none feeble among their tribes.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 Egypt was glad at their departing: for the feare of them had fallen vpon them.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 He spred a cloude to be a couering, and fire to giue light in the night.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 They asked, and he brought quailes, and he filled them with the bread of heauen.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 He opened the rocke, and the waters flowed out, and ranne in the drye places like a riuer.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 For he remembred his holy promise to Abraham his seruant,
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 And he brought forth his people with ioy, and his chosen with gladnesse,
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 And gaue them the lands of the heathen, and they tooke the labours of the people in possession,
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 That they might keepe his statutes, and obserue his Lawes. Prayse ye the Lord.
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Psalms 105 >