< Proverbs 22 >

1 A good name is to be chosen aboue great riches, and louing fauour is aboue siluer and aboue golde.
Yíyan orúkọ rere sàn ju púpọ̀ ọrọ̀ lọ, àti ojúrere dára ju fàdákà àti wúrà lọ.
2 The rich and poore meete together: the Lord is the maker of them all.
Ọlọ́rọ̀ àti tálákà péjọpọ̀: Olúwa ni ẹlẹ́dàá gbogbo wọn.
3 A prudent man seeth the plague, and hideth himselfe: but the foolish goe on still, and are punished.
Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ti rí ibi tẹ́lẹ̀, ó ṣé ara rẹ̀ mọ́: ṣùgbọ́n àwọn òpè tẹ̀síwájú, a sì jẹ wọ́n ní yà.
4 The rewarde of humilitie, and the feare of God is riches, and glory, and life.
Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù Olúwa ni ọrọ̀ ọlá, àti ìyè.
5 Thornes and snares are in the way of the frowarde: but he that regardeth his soule, will depart farre from them.
Ègún àti ìdẹ̀kùn ń bẹ ní ọ̀nà aláyídáyidà: ẹni tí ó bá pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóò jìnnà sí wọn.
6 Teache a childe in the trade of his way, and when he is olde, he shall not depart from it.
Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tí yóò tọ̀: nígbà tí ó bá dàgbà, kì yóò kúrò nínú rẹ̀.
7 The rich ruleth the poore, and the borower is seruant to the man that lendeth.
Ọlọ́rọ̀ ṣe olórí olùpọ́njú, ajigbèsè sì ṣe ìránṣẹ́ fún ẹni tí a jẹ ní gbèsè.
8 He that soweth iniquitie, shall reape affliction, and the rodde of his anger shall faile.
Ẹni tí ó bá fúnrúgbìn ẹ̀ṣẹ̀, yóò ká asán: ọ̀pá ìbínú rẹ̀ yóò kùnà.
9 He that hath a good eye, he shalbe blessed: for he giueth of his bread vnto the poore.
Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún; nítorí tí ó fi nínú oúnjẹ rẹ̀ fún olùpọ́njú.
10 Cast out the scorner, and strife shall go out: so contention and reproche shall cease.
Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde; nítòótọ́ ìjà àti ẹ̀gàn yóò dẹ́kun.
11 Hee that loueth purenesse of heart for the grace of his lippes, the King shalbe his friend.
Ẹni tí ó fẹ́ ìwà funfun ti àyà, tí ó sì ń sọ̀rọ̀ iyì jáde, ọba yóò ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀.
12 The eyes of the Lord preserue knowledge: but hee ouerthroweth the wordes of the transgressour.
Ojú Olúwa pa ìmọ̀ mọ́, ó sì yí ọ̀rọ̀ olùrékọjá pò.
13 The slouthfull man saith, A lyon is without, I shall be slaine in the streete.
Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde! Yóò pa mí ní ìgboro!”
14 The mouth of strage women is as a deepe pit: he with whom the Lord is angry, shall fall therein.
Ẹnu àwọn àjèjì obìnrin, ihò jíjìn ni; ẹni tí a ń bínú sí láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ni yóò ṣubú sínú rẹ̀.
15 Foolishnesse is bounde in the heart of a childe: but the rodde of correction shall driue it away from him.
Àyà ọmọdé ni ìwà wèrè dì sí; ṣùgbọ́n pàṣán ìtọ́ni ni yóò lé e jìnnà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
16 Hee that oppresseth the poore to increase him selfe, and giueth vnto the riche, shall surely come to pouertie.
Ẹni tó ń ni tálákà lára láti ní ọrọ̀, tí ó sì ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ, yóò di aláìní bí ó ti wù kó rí. Gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
17 Incline thine eare, and heare the wordes of the wise, and apply thine heart vnto my knowledge.
Dẹtí rẹ sílẹ̀, kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n, kí o sì fi àyà rẹ sí ẹ̀kọ́ mi.
18 For it shalbe pleasant, if thou keepe them in thy bellie, and if they be directed together in thy lippes.
Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ; nígbà tí a sì pèsè wọn tán ní ètè rẹ.
19 That thy confidence may be in the Lord, I haue shewed thee this day: thou therefore take heede.
Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà ní ti Olúwa, èmi fihàn ọ́ lónìí, àní fún ọ.
20 Haue not I written vnto thee three times in counsels and knowledge,
Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradára sí ọ ní ti ìmọ̀ràn àti ní ti ẹ̀kọ́,
21 That I might shewe thee the assurance of the wordes of trueth to answere the wordes of trueth to them that sende to thee?
kí ó lè mú ọ mọ ìdájú ọ̀rọ̀ òtítọ́; kí ìwọ le máa fi ìdáhùn òtítọ́ fún àwọn tí ó rán ọ?
22 Robbe not the poore, because hee is poore, neither oppresse the afflicted in iudgement.
Má ṣe ja tálákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ tálákà: bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe ni olùpọ́njú lára ní ibodè,
23 For the Lord will defende their cause, and spoyle the soule of those that spoyle them.
nítorí Olúwa yóò gbèjà wọn, yóò sì gba ọkàn àwọn tí ń gba tiwọn náà.
24 Make no friendship with an angrie man, neither goe with the furious man,
Má ṣe bá oníbìínú ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́; má sì ṣe bá ọkùnrin onínú-fùfù rìn.
25 Least thou learne his wayes, and receiue destruction to thy soule.
Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀, ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.
26 Be not thou of them that touch the hand, nor among them that are suretie for debts.
Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀nwọ́, tàbí nínú àwọn tí ó dúró fún gbèsè.
27 If thou hast nothing to paye, why causest thou that he should take thy bed from vnder thee?
Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi san, nítorí kín ni yóò ṣe gba ẹni rẹ kúrò lábẹ́ rẹ?
28 Thou shalt not remooue the ancient bounds which thy fathers haue made.
Má ṣe yẹ ààlà ilẹ̀ ìgbàanì, tí àwọn baba rẹ ti pa.
29 Thou seest that a diligent man in his businesse standeth before Kings, and standeth not before the base sort.
Ìwọ ha rí ènìyàn tí ó ń fi àìṣe ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ rẹ̀? Òun yóò dúró níwájú àwọn ọba; òun kì yóò dúró níwájú àwọn ènìyàn lásán.

< Proverbs 22 >