< Numbers 8 >

1 And the Lord spake vnto Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Speake vnto Aaron, and say vnto him, When thou lightest the lampes, the seuen lampes shall giue light towarde the forefront of the Candlesticke.
“Bá Aaroni sọ̀rọ̀ kí o wí fún un pé. ‘Nígbà tí ó bá ń to àwọn fìtílà, àwọn fìtílà méjèèje gbọdọ̀ tan ìmọ́lẹ̀ sí àyíká níwájú ọ̀pá fìtílà.’”
3 And Aaron did so, lighting the lampes thereof towarde ye forefront of the Candlesticke, as the Lord had commanded Moses.
Aaroni sì ṣe bẹ́ẹ̀; ó to àwọn fìtílà náà tí wọ́n sì fi kojú síwájú lórí ọ̀pá fìtílà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
4 And this was the worke of the Candlesticke, euen of golde beaten out with the hammer, both the shafte, and the flowres thereof was beaten out with the hammer: according to the paterne, which the Lord had shewed Moses, so made he the Candlesticke.
Bí a ṣe ṣe ọ̀pá fìtílà náà nìyìí, a ṣe é láti ara wúrà lílù: láti ìsàlẹ̀ títí dé ibi ìtànná rẹ̀. Wọ́n ṣe ọ̀pá fìtílà náà gẹ́gẹ́ bí bátànì tí Olúwa fihan Mose.
5 And the Lord spake vnto Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
6 Take the Leuites from among the children of Israel, and purifie them.
“Yọ àwọn ọmọ Lefi kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, kí o sì wẹ̀ wọ́n mọ́.
7 And thus shalt thou doe vnto them, when thou purifiest them, Sprinckle water of purification vpon them, and let them shaue all their flesh, and wash their clothes: so they shalbe cleane.
Báyìí ni kí o ṣe wẹ̀ wọ́n mọ́. Wọ́n omi ìwẹ̀nùmọ́ sí wọn lára, mú kí wọn ó fá irun ara wọn, kí wọn ó fọ aṣọ wọn, kí wọn ó ba à lè wẹ ara wọn mọ́ nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀.
8 Then they shall take a yong bullocke with his meate offring of fine floure, mingled with oyle, and another yong bullocke shalt thou take for a sinne offring.
Jẹ́ kí wọn ó mú akọ ọ̀dọ́ màlúù pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ rẹ̀ tí í ṣe ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò, kí ìwọ náà mú akọ ọ̀dọ́ màlúù kejì fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
9 Then thou shalt bring the Leuites before the Tabernacle of the Congregation, and asseble all the Congregation of the children of Israel.
Ìwọ ó sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú àgọ́ ìpàdé, kí o sì kó gbogbo àpapọ̀ ọmọ Israẹli jọ síbẹ̀ pẹ̀lú.
10 Thou shalt bring the Leuites also before the Lord, and the children of Israel shall put their handes vpon the Leuites.
Báyìí ni kí o mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa, gbogbo ọmọ Israẹli yóò sì gbọ́wọ́ lé àwọn ọmọ Lefi lórí.
11 And Aaron shall offer the Leuites before the Lord, as a shake offring of ye childre of Israel, that they may execute the seruice of the Lord.
Aaroni yóò sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli wá, kí wọn lè máa ṣiṣẹ́ Olúwa.
12 And the Leuites shall put their handes vpon the heades of the bullockes, and make thou the one a sinne offring, and the other a burnt offring vnto the Lord, that thou mayest make an atonement for the Leuites.
“Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi bá gbé ọwọ́ wọn lé orí àwọn akọ ọmọ màlúù náà, ìwọ yóò sì fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun sí Olúwa, láti ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Lefi.
13 And thou shalt set the Leuites before Aaron and before his sonnes, and offer the as a shake offring to the Lord.
Mú kí àwọn ọmọ Lefi dúró níwájú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí ó sì gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì sí Olúwa.
14 Thus thou shalt separate the Leuites from among the children of Israel, and the Leuites shall be mine.
Báyìí ni ìwọ yóò ṣe ya ọmọ Lefi sọ́tọ̀, kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, àwọn ọmọ Lefi yóò sì jẹ́ tèmi.
15 And afterwarde shall the Leuites goe in, to serue in the Tabernacle of the Congregation, and thou shalt purifie them and offer them, as a shake offering.
“Lẹ́yìn tí ó ti wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, tí ó sì ti gbé wọn kalẹ̀ bí ẹbọ fífì nígbà náà ni kí wọn ó lọ máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
16 For they are freely giuen vnto me from among the children of Israel, for such as open any wombe: for all the first borne of the children of Israel haue I taken them vnto me.
Nítorí pé àwọn ni ó jẹ́ ti Èmi pátápátá nínú àwọn ọmọ Israẹli. Mo ti gbà wọ́n fún ara mi dípò àwọn àkọ́bí àní àkọ́bí ọkùnrin gbogbo Israẹli.
17 For all the first borne of the children of Israel are mine, both of man and of beast: since the day that I smote euery first borne in the land of Egypt, I sanctified them for my selfe.
Nítorí pé gbogbo àkọ́bí ọmọ lọ́kùnrin ní Israẹli jẹ́ tèmi, ti ènìyàn àti ti ẹranko, láti ọjọ́ tí mo ti pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ara mi.
18 And I haue taken the Leuites for all the first borne of the children of Israel,
Mo sì ti gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí ọmọ ọkùnrin nínú Israẹli.
19 And haue giuen the Leuites as a gift vnto Aaron, and to his sonnes from among the children of Israel, to do the seruice of the children of Israel in the Tabernacle of the Congregation, and to make an atonement for the children of Israel, that there be no plague among the children of Israel, when the children of Israel come neere vnto the Sanctuarie.
Nínú Israẹli, mo fi àwọn ọmọ Lefi fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn láti máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé fun àwọn ọmọ Israẹli àti láti máa ṣe ètùtù fún wọn kí àjàkálẹ̀-ààrùn má ba à kọlu àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ ibi mímọ́.”
20 Then Moses and Aaron and all the Cogregation of the children of Israel did with the Leuites, according vnto all that the Lord had commanded Moses concerning the Leuites: so did the children of Israel vnto them.
Mose, Aaroni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
21 So the Leuites were purified, and washed their clothes, and Aaron offred them as a shake offring before the Lord, and Aaron made an atonement for them, to purifie them.
Àwọn ọmọ Lefi wẹ ara wọn mọ́, wọ́n sì fọ aṣọ wọn. Aaroni sì mú wọn wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì níwájú Olúwa, Aaroni sì ṣe ètùtù fún wọn láti wẹ̀ wọ́n mọ́.
22 And after that, went the Leuites in to doe their seruice in the Tabernacle of the Congregation, before Aaron and before his sonnes: as the Lord had commanded Moses concerning the Leuites, so they did vnto them.
Lẹ́yìn èyí àwọn ọmọ Lefi lọ sínú àgọ́ ìpàdé láti lọ máa ṣiṣẹ́ wọn lábẹ́ àbojútó Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
23 And the Lord spake vnto Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
24 This also belongeth to the Leuites: from fiue and twentie yeere olde and vpwarde, they shall goe in, to execute their office in the seruice of the Tabernacle of the Congregation.
“Èyí ni ohun tó jẹ mọ́ àwọn ọmọ Lefi, láti ọmọ ọdún kẹẹdọ́gbọ̀n tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni kí ó máa kópa nínú iṣẹ́ àgọ́ ìpàdé.
25 And after the age of fiftie yeere, they shall cease from executing the office, and shall serue no more:
Ṣùgbọ́n ẹni tó bá ti pé ọmọ àádọ́ta ọdún gbọdọ̀ ṣíwọ́ nínú iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn nínú àgọ́, kí wọ́n sì má ṣiṣẹ́ mọ́.
26 But they shall minister with their brethre in the Tabernacle of the Congregation, to keepe things committed to their charge, but they shall doe no seruice: thus shalt thou doe vnto the Leuites touching their charges.
Wọ́n le máa ran àwọn arákùnrin wọn lọ́wọ́ nínú àgọ́ ìpàdé ṣùgbọ́n àwọn fúnra wọn kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Báyìí ni kí o ṣe pín iṣẹ́ fún àwọn ọmọ Lefi.”

< Numbers 8 >