< Numbers 34 >

1 And the Lord spake vnto Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Commande the children of Israel, and say vnto them, When yee come into the land of Canaan, this is the land that shall fall vnto your inheritance: that is, the land of Canaan with the coastes thereof.
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
3 And your Southquarter shalbe from the wildernesse of Zin to the borders of Edom: so that your Southquarter shall be from the salt Sea coast Eastwarde:
“‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
4 And the border shall compasse you from the South to Maaleh-akrabbim, and reach to Zin, and goe out from the South to Kadesh-barnea: thence it shall stretch to Hazar-addar, and go along to Azmon.
kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
5 And the border shall compasse from Azmon vnto the riuer of Egypt, and shall goe out to the Sea.
Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
6 And your Westquarter shall bee the great Sea: euen that border shalbe your Westcoast.
Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
7 And this shall bee your Northquarter: yee shall marke out your border from the great Sea vnto mount Hor.
Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
8 From mount Hor ye shall point out till it come vnto Hamath, and the end of the coast shall be at Zedad.
àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
9 And the coast shall reach out to Ziphron, and goe out at Hazar-enan. this shalbe your Northquarter.
tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
10 And ye shall marke out your Eastquarter from Hazar-enan to Shepham.
Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
11 And the coast shall goe downe from Shepham to Riblah, and from the Eastside of Ain: and the same border shall descend and goe out at the side of the sea of Chinneereth Eastward.
Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
12 Also that border shall goe downe to Iorden, and leaue at the salt Sea. this shalbe your land with the coastes thereof round about.
Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
13 Then Moses commanded the children of Israel, saying, This is the lande which yee shall inherite by lot, which the Lord commanded to giue vnto nine tribes and halfe the tribe.
Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
14 For the tribe of the children of Reuben, according to the housholdes of their fathers, and the tribe of the children of Gad, according to their fathers housholdes, and halfe the tribe of Manasseh, haue receiued their inheritance.
Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
15 Two tribes and an halfe tribe haue receiued their inheritance on this side of Iorden toward Iericho full East.
Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
16 Againe the Lord spake to Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
17 These are the names of the men which shall deuide ye land vnto you: Eleazar the Priest, and Ioshua the sonne of Nun.
“Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
18 And ye shall take also a prince of euerie tribe to deuide the land.
Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
19 The names also of the men are these: Of the tribe of Iudah, Caleb ye sonne of Iephunneh.
“Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
20 And of the tribe of the sonnes of Simeon, Shemuel the sonne of Ammihud.
Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
21 Of the tribe of Beniamin, Elidad the sonne of Chislon.
Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
22 Also of the tribe of the sonnes of Dan, the prince Bukki, the sonne of Iogli.
Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
23 Of the sonnes of Ioseph: of the tribe of the sonnes of Manasseh, the prince Hanniel the sonne of Ephod.
Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
24 And of the tribe of the sonnes of Ephraim, the prince Kemuel, the sonne of Shiphtan.
Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
25 Of the tribe also of the sonnes of Zebulun, the prince Elizaphan, the sonne of Parnach.
Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
26 So of the tribe of the sonnes of Issachar, the prince Paltiel the sonne of Azzan.
Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
27 Of the tribe also of the sonnes of Asher, the prince Ahihud, the sonne of Shelomi.
Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
28 And of the tribe of the sonnes of Naphtali, the prince Pedahel, the sonne of Ammihud.
Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
29 These are they, whome the Lord commanded to deuide the inheritance vnto the children of Israel, in the land of Canaan.
Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.

< Numbers 34 >