< Numbers 33 >
1 These are the iourneyes of the children of Israel, which went out of the land of Egypt according to their bands vnder the hand of Moses and Aaron.
Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
2 And Moses wrote their going out by their iourneies according to ye commandement of the Lord: so these are ye iourneies of their going out.
Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
3 Nowe they departed from Rameses the first moneth, euen the fifteenth day of the first moneth, on the morowe after the Passeouer: and the children of Israel went out with an hie hand in the sight of all the Egyptians.
Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
4 (For the Egyptians buried all their first borne, which the Lord had smitten among them: vpon their gods also the Lord did execution.)
Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
5 And the children of Israel remoued from Rameses, and pitched in Succoth.
Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
6 And they departed from Succoth, and pitched in Etham, which is in the edge of the wildernesse.
Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
7 And they remoued from Etham, and turned againe vnto Pi-hahiroth, which is before Baal-zephon, and pitched before Migdol.
Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
8 And they departed from before Hahiroth, and went through the middes of the Sea into the wildernesse, and went three dayes iourney in the wildernesse of Etham, and pitched in Marah.
Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
9 And they remoued from Marah, and came vnto Elim, and in Elim were twelue fountaines of water, and seuentie palme trees, and they pitched there.
Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
10 And they remoued from Elim, and camped by the red Sea.
Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
11 And they remoued from the red Sea, and lay in the wildernesse of Sin.
Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
12 And they tooke their iourney out of the wildernesse of Sin, and set vp their tentes in Dophkah.
Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
13 And they departed from Dophkah, and lay in Alush.
Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
14 And they remoued from Alush, and lay in Rephidim, where was no water for the people to drinke.
Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
15 And they departed from Rephidim, and pitched in the wildernesse of Sinai.
Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
16 And they remoued from the desert of Sinai, and pitched in Kibroth Hattaauah.
Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
17 And they departed from Kibroth Hattaauah, and lay at Hazeroth.
Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
18 And they departed from Hazeroth, and pitched in Rithmah.
Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
19 And they departed from Rithmah, and pitched at Rimmon Parez.
Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
20 And they departed from Rimmon Parez, and pitched in Libnah.
Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
21 And they remoued from Libnah, and pitched in Rissah.
Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
22 And they iourneyed from Rissah, and pitched in Kehelathah.
Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
23 And they went from Kehelathah, and pitched in mount Shapher.
Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
24 And they remoued from mount Shapher, and lay in Haradah.
Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
25 And they remoued from Haradah, and pitched in Makheloth.
Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
26 And they remoued from Makheloth, and lay in Tahath.
Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
27 And they departed from Tahath, and pitched in Tarah.
Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
28 And they remoued from Tarah, and pitched in Mithkah.
Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
29 And they went from Mithkah, and pitched in Hashmonah.
Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
30 And they departed from Hashmonah, and lay in Moseroth.
Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
31 And they departed from Moseroth, and pitched in Bene-iaakan.
Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
32 And they remoued from Bene-iaakan, and lay in Hor-hagidgad.
Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
33 And they went from Hor-hagidgad, and pitched in Iotbathah.
Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
34 And they remoued from Iotbathah, and lay in Ebronah.
Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
35 And they departed from Ebronah, and lay in Ezion-gaber.
Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
36 And they remoued from Ezion-gaber, and pitched in the wildernesse of Zin, which is Kadesh.
Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
37 And they remooued from Kadesh, and pitched in mount Hor, in the edge of the land of Edom.
Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
38 (And Aaron the Priest went vp into mount Hor, at the commandement of the Lord, and died there, in the fourtieth yeere after the children of Israel were come out of the lande of Egypt, in the first day of the fifth moneth.
Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
39 And Aaron was an hundreth, and three and twentie yeere olde, when hee dyed in mount Hor.
Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
40 And King Arad the Canaanite, which dwelt in the South of the land of Canaan, heard of the comming of the children of Israel)
Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
41 And they departed from mount Hor, and pitched in Zalmonah.
Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
42 And they departed from Zalmonah, and pitched in Punon.
Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
43 And they departed from Punon, and pitched in Oboth.
Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
44 And they departed from Oboth, and pitched in Iie-abarim, in the borders of Moab.
Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
45 And they departed from Iim, and pitched in Dibon-gad.
Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
46 And they remooued from Dibon-gad, and lay in Almon-diblathaim.
Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
47 And they remooued from Almon-diblathaim, and pitched in the mountaines of Abarim before Nebo.
Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
48 And they departed from the mountaines of Abarim, and pitched in the plaine of Moab, by Iorden toward Iericho.
Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
49 And they pitched by Iorden, from Bethieshimoth vnto Abel-shittim in the playne of Moab.
Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
50 And the Lord spake vnto Moses in the playne of Moab, by Iorden towarde Iericho, saying,
Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
51 Speake vnto the children of Israel, and say vnto them, When ye are come ouer Iorden to enter into the land of Canaan,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
52 Ye shall then driue out all the inhabitants of the land before you, and destroy all their pictures, and breake asunder all their images of metall, and plucke downe all their hie places.
lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
53 And ye shall possesse the lande and dwell therein: for I haue giue you ye land to possesse it.
Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
54 And ye shall inherite the land by lot according to your families: to the more yee shall giue more inheritance, and to the fewer the lesse inheritance. Where the lot shall fall to any man, that shall be his: according to the tribes of your fathers shall ye inherite.
Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
55 But if ye will not driue out the inhabitants of the land before you, then those which yee let ramaine of them, shalbe prickes in your eyes, and thornes in your sides, and shall vexe you in the land wherein ye dwell.
“‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
56 Moreouer, it shall come to passe, that I shall doe vnto you, as I thought to do vnto them.
Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”