< Numbers 25 >

1 Nowe whiles Israel abode in Shittim, the people began to commit whoredome with the daughters of Moab:
Nígbà tí àwọn Israẹli dúró ní Ṣittimu, àwọn ènìyàn sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin Moabu,
2 Which called the people vnto the sacrifice of their gods, and the people ate, and bowed downe to their gods.
tí ó pè wọ́n sí ibi ẹbọ òrìṣà wọn. Àwọn ènìyàn náà jẹun wọ́n sì foríbalẹ̀ níwájú òrìṣà wọn.
3 And Israel coupled himselfe vnto Baal Peor: wherefore the wrath of the Lord was kindled against Israel:
Báyìí ni Israẹli ṣe darapọ̀ mọ́ wọn tí wọ́n sì jọ ń sin Baali-Peori. Ìbínú Olúwa sì ru sí wọn.
4 And the Lord sayde vnto Moses, Take all the heades of the people, and hang them vp before the Lord against ye sunne, that the indignation of the Lords wrath may be turned from Israel.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú gbogbo àwọn olórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, pa wọ́n kí o sì fi wọ́n kọ́ sórí igi ní gbangba nínú oòrùn níwájú Olúwa, kí ìbínú Olúwa lè kúrò ní ọ̀dọ̀ Israẹli.”
5 Then Moses sayd vnto the Iudges of Israel, Euery one slay his men that were ioyned vnto Baal Peor.
Mose sọ fún àwọn onídàájọ́ Israẹli, “Ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ pa arákùnrin rẹ̀ èyí tí ó darapọ̀ ní fífi orí balẹ̀ fún Baali-Peori.”
6 And behold, one of the children of Israel came and brought vnto his brethren a Midianitish woman in the sight of Moses, and in the sight of all the Congregation of the children of Israel, who wept before the doore of the Tabernacle of the Congregation.
Nítòótọ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin Israẹli sì mú obìnrin Midiani wá síwájú ojú Mose àti gbogbo ìjọ ti Israẹli wọ́n sì ń sọkún ní àbáwọlé àgọ́ ìpàdé.
7 And when Phinehas the sonne of Eleazar the sonne of Aaron the Priest sawe it, hee rose vp from the middes of the Congregation, and tooke a speare in his hand,
Nígbà tí Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni, àlùfáà, rí èyí, ó fi ìjọ sílẹ̀, pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ní ọwọ́ rẹ̀.
8 And followed ye man of Israel into the tent, and thrust them both through: to wit, the man of Israel, and the woman, through her belly: so the plague ceased from the children of Israel.
Ó sì tẹ̀lé arákùnrin Israẹli yìí lọ sínú àgọ́. Ó sì fi ọ̀kọ̀ gún àwọn méjèèjì ní àgúnyọ láti ara ọkùnrin Israẹli àti sí ara obìnrin náà. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn lórí àwọn ọmọ Israẹli sì dúró;
9 And there died in that plague, foure and twentie thousand.
ṣùgbọ́n gbogbo àwọn tí ó kú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn náà jẹ́ ẹgbàá méjìlá.
10 Then the Lord spake vnto Moses, saying,
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
11 Phinehas the sonne of Eleazar, the sonne of Aaron the Priest, hath turned mine anger away from the children of Israel, while hee was zealous for my sake among them: therefore I haue not consumed the children of Israel in my ielousie.
“Finehasi ọmọ Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà, ti yí ìbínú mi padà kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí tí ó ní ìtara bí èmi náà ti ní ìtara fún iyì mi láàrín wọn, kí ó lè jẹ́ pé èmi ló pa wọ́n run nínú ìtara mi sí wọn.
12 Wherefore say to him, Beholde, I giue vnto him my couenant of peace,
Nítorí náà sọ fún un pé èmi ṣe májẹ̀mú àlàáfíà mi pẹ̀lú rẹ̀.
13 And he shall haue it, and his seede after him, euen the couenant of the priestes office for euer, because he was zealous for his God, and hath made an atonement for the children of Israel.
Òun àti irú-ọmọ rẹ̀ yóò ní májẹ̀mú láéláé fún iṣẹ́ àlùfáà, nítorí pé ó ní ìtara fún Ọlọ́run rẹ̀ láti fi yẹ́ Ọlọ́run sí, ó sì ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Israẹli.”
14 And the name of the Israelite thus slayne, which was killed with the Midianitish woman, was Zimri the sonne of Salu, prince of the familie of the Simeonites.
Orúkọ ọmọ Israẹli tí a pa pẹ̀lú obìnrin Midiani náà ni Simri, ọmọ Salu, olórí ilé kan nínú àwọn ọmọ Simeoni.
15 And the name of the Midianitish woman, that was slayne, was Cozbi the daughter of Zur, who was head ouer the people of his fathers house in Midian.
Orúkọ ọmọbìnrin Midiani náà tí a pa ní Kosbi ọmọbìnrin Suri, tí ṣe olóyè àwọn ẹ̀yà kan nínú ìdílé kan ní Midiani.
16 Againe ye Lord spake vnto Moses, saying,
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
17 Vexe the Midianites, and smite them:
“Ka àwọn ará Midiani sí ọ̀tá, kí o sì pa wọ́n,
18 For they trouble you with their wiles, wherewith they haue beguiled you as concerning Peor, and as concerning their sister Cozbi ye daughter of a prince of Midian, which was slayne in the day of the plague because of Peor.
nítorí pé wọ́n ṣe sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá nígbà tí wọ́n tàn yín nípa ìṣẹ̀lẹ̀ Peori, àti arábìnrin wọn Kosbi ọmọbìnrin ìjòyè Midiani kan, obìnrin tí a pa nígbà tí àjàkálẹ̀-ààrùn ṣẹlẹ̀ nítorí Peori.”

< Numbers 25 >