< Numbers 13 >
1 And the Lord spake vnto Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Sende thou men out to search the lande of Canaan which I giue vnto the children of Israel: of euery tribe of their fathers shall ye sende a man, such as are all rulers among them.
“Rán ènìyàn díẹ̀ láti lọ yẹ ilẹ̀ Kenaani wò èyí tí mo ti fún àwọn ọmọ Israẹli. Rán ẹnìkọ̀ọ̀kan, tí ó jẹ́ olórí láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.”
3 Then Moses sent them out of the wildernesse of Paran at the commandement of the Lord: all those men were heades of the children of Israel.
Mose sì rán wọn jáde láti aginjù Parani gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa. Gbogbo wọn jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Israẹli.
4 Also their names are these: of the tribe of Reuben, Shammua the sonne of Zaccur:
Orúkọ wọn nìwọ̀nyí: láti inú ẹ̀yà Reubeni, Ṣammua ọmọ Sakkuri;
5 Of the tribe of Simeon, Shaphat the sonne of Hori:
láti inú ẹ̀yà Simeoni, Ṣafati ọmọ Hori;
6 Of the tribe of Iudah, Caleb the sonne of Iephunneh:
láti inú ẹ̀yà Juda, Kalebu ọmọ Jefunne;
7 Of the tribe of Issachar, Igal the sonne of Ioseph:
láti inú ẹ̀yà Isakari, Igali ọmọ Josẹfu;
8 Of the tribe of Ephraim, Oshea the sone of Nun:
láti inú ẹ̀yà Efraimu, Hosea ọmọ Nuni;
9 Of the tribe of Beniamin, Palti the sonne of Raphu:
láti inú ẹ̀yà Benjamini, Palti ọmọ Rafu;
10 Of the tribe of Zebulun, Gaddiel the sone of Sodi:
láti inú ẹ̀yà Sebuluni, Daddieli ọmọ Sodi;
11 Of the tribe of Ioseph, to wit, of the tribe of Manasseh, Gaddi the sonne of Susi:
láti inú ẹ̀yà Manase (ẹ̀yà Josẹfu), Gaddi ọmọ Susi;
12 Of the tribe of Dan, Ammiel the sonne of Gemalli:
láti inú ẹ̀yà Dani, Ammieli ọmọ Gemalli;
13 Of the tribe of Asher, Sethur the sonne of Michael:
láti inú ẹ̀yà Aṣeri, Seturu ọmọ Mikaeli.
14 Of the tribe of Naphtali, Nahbi the sonne of Vophsi:
láti inú ẹ̀yà Naftali, Nabi ọmọ Fofsi;
15 Of the tribe of Gad, Geuel the sonne of Machi.
láti inú ẹ̀yà Gadi, Geueli ọmọ Maki.
16 These are the names of the men, which Moses sent to spie out the lande: and Moses called ye name of Oshea the sonne of Nun, Iehoshua.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ènìyàn tí Mose rán láti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò. (Hosea ọmọ Nuni ni Mose sọ ní Joṣua.)
17 So Moses sent them to spie out the lande of Canaan, and said vnto them, Go vp this way toward the South, and go vp into the moutaines,
Nígbà tí Mose rán wọn lọ láti yẹ ilẹ̀ Kenaani wò, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ gba ọ̀nà gúúsù lọ títí dé àwọn ìlú olókè.
18 And consider the land what it is, and the people that dwel therein, whether they be strong or weake, either fewe or many,
Ẹ wò ó bí ilẹ̀ náà ti rí, bóyá àwọn tó ń gbé ilẹ̀ náà jẹ́ alágbára tàbí aláìlágbára, bóyá wọ́n pọ̀ tàbí wọn kéré.
19 Also what the lande is that they dwell in, whether it be good or bad: and what cities they be, that they dwell in, whether they dwell in tents, or in walled townes:
Irú ilẹ̀ wo ni wọ́n gbé? Ṣé ilẹ̀ tó dára ni àbí èyí tí kò dára? Báwo ni ìlú wọn ti rí? Ṣé ìlú olódi ni àbí èyí tí kò ní odi?
20 And what the land is: whether it be fat or leane, whether there be trees therein, or not. And be of good courage, and bring of the fruite of the lande (for then was the time of the first ripe grapes)
Báwo ni ilẹ̀ náà ti rí? Ṣé ilẹ̀ ọlọ́ràá ni tàbí aṣálẹ̀? Ṣé igi wà níbẹ̀ àbí kò sí? E sa ipá yín láti rí i pé ẹ mú díẹ̀ nínú èso ilẹ̀ náà wá.” (Ìgbà náà sì jẹ́ àkókò àkọ́pọ́n èso àjàrà gireepu.)
21 So they went vp, and searched out the lande, from the wildernesse of Zin vnto Rehob, to go to Hamath,
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ láti yẹ ilẹ̀ náà wò, wọ́n lọ láti aginjù Sini títí dé Rehobu lọ́nà Lebo-Hamati.
22 And they ascended toward the South, and came vnto Hebron, where were Ahiman, Sheshai and Talmai, the sonnes of Anak. And Hebron was built seuen yeere before Zoan in Egypt.
Wọ́n gba gúúsù lọ sí Hebroni níbi tí Ahimani, Ṣeṣai àti Talmai tí í ṣe irú-ọmọ Anaki ń gbé. (A ti kọ́ Hebroni ní ọdún méje ṣáájú Ṣoani ní Ejibiti.)
23 Then they came to the riuer of Eshcol, and cut downe thence a branch with one cluster of grapes, and they bare it vpon a barre betweene two, and brought of the pomegranates and of the figges.
Nígbà tí wọ́n dé àfonífojì Eṣkolu, wọ́n gé ẹ̀ka kan tó ní ìdì èso àjàrà gireepu kan. Àwọn méjì sì fi ọ̀pá kan gbé e; wọ́n tún mú èso pomegiranate àti èso ọ̀pọ̀tọ́ pẹ̀lú.
24 That place was called the riuer Eshcol, because of the cluster of grapes, which the children of Israel cut downe thence.
Wọ́n sì sọ ibẹ̀ ní àfonífojì Eṣkolu nítorí ìdì èso gireepu tí àwọn ọmọ Israẹli gé níbẹ̀.
25 Then after fourtie dayes, they turned againe from searching of the land.
Wọ́n padà sílé lẹ́yìn ogójì ọjọ́ tí wọ́n ti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò.
26 And they went and came to Moses and to Aaron and vnto al the Congregation of the children of Israel, in the wildernesse of Paran, to Kadesh, and brought to the, and to all the Congregation tydings, and shewed them the fruite of the lande.
Wọ́n padà wá bá Mose àti Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní ijù Kadeṣi Parani. Wọ́n mú ìròyìn wá fún wọn àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn, wọ́n fi èso ilẹ̀ náà hàn wọ́n.
27 And they tolde him, and saide, We came vnto the land whither thou hast sent vs, and surely it floweth with milke and honie: and here is of the fruite of it.
Wọ́n sì fún Mose ní ìròyìn báyìí, “A lọ sí ilẹ̀ ibi tí o rán wa, lóòtítọ́ ló sì ń sàn fún wàrà àti fún oyin! Èso ibẹ̀ nìyìí.
28 Neuerthelesse the people be strong that dwell in the land, and the cities are walled and exceeding great: and moreouer, we sawe the sonnes of Anak there.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tó ń gbé níbẹ̀ lágbára, àwọn ìlú náà jẹ́ ìlú olódi bẹ́ẹ̀ ni ó sì tóbi púpọ̀. A tilẹ̀ rí àwọn irú-ọmọ Anaki níbẹ̀.
29 The Amalekites dwell in the South countrey, and the Hittites, and the Iebusites, and the Amorites dwell in the mountaines, and the Canaanites dwell by the sea, and by the coast of Iorden.
Àwọn Amaleki ń gbé ní ìhà gúúsù; àwọn ará Hiti, àwọn ará Jebusi àti àwọn ará Amori ni wọ́n ń gbé ní orí òkè ilẹ̀ náà, àwọn ará Kenaani sì ń gbé ẹ̀bá òkun àti ní etí bèbè Jordani.”
30 Then Caleb stilled the people before Moses, and saide, Let vs go vp at once, and possesse it: for vndoubtedly we shall ouercome it.
Kalebu sì pa àwọn ènìyàn náà lẹ́nu mọ́ níwájú Mose, ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á gòkè lọ lẹ́ẹ̀kan náà láti lọ gba ilẹ̀ náà, nítorí pé àwa le è gbà á.”
31 But the men, that went vp with him, saide, we be not able to goe vp against the people: for they are stronger then we.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ gòkè lọ yẹ ilẹ̀ wò sọ pé, “Àwa kò le gòkè lọ bá àwọn ènìyàn wọ̀nyí nítorí pé wọ́n lágbára jù wá lọ.”
32 So they brought vp an euill report of the land which they had searched for the children of Israel, saying, The lande which we haue gone through to search it out, is a land that eateth vp the inhabitants thereof: for all the people that we sawe in it, are men of great stature.
Báyìí ni wọ́n ṣe mú ìròyìn búburú ti ilẹ̀ náà, tí wọ́n lọ yọ́wò wá fún àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ tí a lọ yẹ̀ wò jẹ́ ilẹ̀ tí ń run àwọn olùgbé ibẹ̀. Gbogbo àwọn ènìyàn tí a rí níbẹ̀ jẹ́ ènìyàn tó fìrìgbọ̀n tó sì síngbọnlẹ̀.
33 For there we sawe gyants, the sonnes of Anak, which come of the gyants, so that we seemed in our sight like grashoppers: and so wee were in their sight.
A sì tún rí àwọn òmíràn (irú àwọn ọmọ Anaki) àwa sì rí bí i kòkòrò tata ní ojú ara wa, bẹ́ẹ̀ ni àwa náà sì rí ní ojú wọn.”