< Leviticus 15 >

1 Moreouer the Lord spake vnto Moses, and to Aaron, saying,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
2 Speake vnto the children of Israel, and say vnto them, Whosoeuer hath an issue from his flesh, is vncleane, because of his issue.
“Ẹ bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí ẹ wí fún wọn pé, ‘Bí ìsunjáde bá ń jáde lára ọkùnrin kan lójú ara, ìsunjáde náà jẹ́ àìmọ́.
3 And this shalbe his vncleannes in his issue: when his flesh auoydeth his issue, or if his flesh be stopped from his issue, this is his vncleannes.
Yálà ó ń jáde léraléra tàbí ó dúró, èyí yóò sọ ọ́ di aláìmọ́. Báyìí ni ìsunjáde rẹ̀ ṣe le è sọ ọ́ di aláìmọ́:
4 Euery bed whereon he lyeth that hath the issue, shall be vncleane, and euery thing whereon he sitteth, shalbe vncleane.
“‘Gbogbo ibùsùn tí irú ẹni tí ó ní ìsunjáde náà bá sùn di àìmọ́.
5 Whosoeuer also toucheth his bed, shall wash his clothes, and wash himselfe in water, and shall be vncleane vntill the euen.
Bí ẹnikẹ́ni bá fi ara kan ibùsùn rẹ̀, ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
6 And he that sitteth on any thing, whereon he sate that hath the issue, shall wash his clothes, and wash himselfe in water, and shalbe vncleane vntill the euen.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá jókòó lórí ohunkóhun tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde bá jókòó le gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, kí ó sì wà láìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
7 Also he that toucheth the flesh of him that hath the issue, shall wash his clothes, and wash himselfe in water, and shalbe vncleane vntil the euen.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin náà tí ó ní ìsunjáde gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
8 If he also, that hath the issue, spit vpon him that is cleane, he shall wash his clothes, and wash himselfe in water, and shalbe vncleane vntill the euen.
“‘Bí ẹni tí ó ní ìsunjáde bá tu itọ́ sí ẹni tí ó mọ́ lára, ẹni tí ó mọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
9 And what saddle soeuer he rideth vpon, that hath the issue, shalbe vncleane,
“‘Gàárì ẹranko tí ẹni náà bá gùn yóò di àìmọ́.
10 And whosoeuer toucheth any thing that was vnder him, shall be vncleane vnto the euen: and he that beareth those things, shall wash his clothes, and wash himselfe in water, and shall be vncleane vntill the euen.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó wà lábẹ́ ọkùnrin náà di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́. Ẹnikẹ́ni tí ó bá mú irú nǹkan bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó wẹ ara rẹ̀. Yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
11 Likewise whomesoeuer hee toucheth that hath the issue (and hath not washed his handes in water) shall wash his clothes and wash himselfe in water, and shalbe vncleane vntill the euen.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde ní ara rẹ̀ bá fi ara kàn láìfi omi fọ ọwọ́ rẹ̀, gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
12 And the vessel of earth that he toucheth, which hath the issue, shalbe broken: and euery vessel of wood shalbe rinsed in water.
“‘Ìkòkò amọ̀ tí ọkùnrin náà bá fọwọ́ kàn ni kí ẹ fọ́, gbogbo ohun èlò igi tí ó fọwọ́ kàn ni kí ẹ fi omi sàn.
13 But if he that hath an issue, be cleansed of his issue, then shall he count him seuen dayes for his cleansing, and wash his clothes, and wash his flesh in pure water: so shall he be cleane.
“‘Ẹnikẹ́ni tí a bá wẹ̀nù kúrò nínú ìsunjáde rẹ̀ gbọdọ̀ ka ọjọ́ méje fún àwọn ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́: kí ó fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì di mímọ́.
14 Then the eight day he shall take vnto him two Turtle doues or two yong pigeons, and come before the Lord at the doore of the Tabernacle of the Congregation, and shall giue them vnto the Priest.
Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì, kí ó sì wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé níwájú Olúwa, kí ó sì kó wọn fún àlùfáà.
15 And the Priest shall make of the one of them a sinne offring, and of the other a burnt offering: so the Priest shall make an atonement for him before the Lord, for his issue.
Kí àlùfáà fi wọ́n rú ẹbọ: ọ̀kan fún ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ọrẹ ẹbọ sísun níwájú Olúwa ní ipò ọkùnrin náà nítorí ìsunjáde rẹ̀.
16 Also if any mans issue of seede depart from him, he shall wash all his flesh in water, and be vncleane vntill the euen.
“‘Bí nǹkan ọkùnrin kan bá tú jáde, kí ó wẹ gbogbo ara rẹ̀, kí ó wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
17 And euery garment, and euery skinne whereupon shalbe issue of seede, shall be euen washed with water, and be vncleane vnto the euen.
Yálà àwọ̀ tàbí aṣọ tí nǹkan ọkùnrin bá dà sí lórí ni kí ẹ fọ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ di ìrọ̀lẹ́.
18 If he that hath an issue of seede, do lie with a woman, they shall both wash themselues with water, and be vncleane vntill the euen.
Bí ọkùnrin kan bá bá obìnrin lòpọ̀ tí nǹkan ọkùnrin sì tú jáde lára rẹ̀. Àwọn méjèèjì gbọdọ̀ fi omi wẹ̀, kí wọ́n sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
19 Also when a woman shall haue an issue, and her issue in her flesh shalbe blood, she shalbe put apart seuen dayes: and whosoeuer toucheth her, shalbe vncleane vnto the euen.
“‘Bí obìnrin bá ń ṣe nǹkan oṣù rẹ̀, obìnrin yìí wà ní àìmọ́ títí di ọjọ́ méje. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
20 And whatsoeuer she lieth vpon in her separation, shalbe vncleane, and euery thing that she sitteth vpon, shalbe vncleane.
“‘Gbogbo ohun tí ó bá sùn lé ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ di àìmọ́.
21 Whosoeuer also toucheth her bedde, shall wash his clothes, and wash himselfe with water, and shalbe vncleane vnto the euen.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ibùsùn rẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
22 And whosoeuer toucheth any thing that she sate vpon, shall wash his clothes, and wash him selfe in water, and shalbe vncleane vnto the euen:
Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó bá jókòó lé gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
23 So that whether he touche her bed, or any thing whereon shee hath sit, he shalbe vncleane vnto the euen.
Ìbá à ṣe ibùsùn tàbí ohunkóhun tí ó jókòó lé. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
24 And if a man lye with her, and the flowers of her separation touch him, he shalbe vncleane seuen dayes, and all the whole bed whereon he lieth, shalbe vncleane.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá a lòpọ̀, tí nǹkan oṣù rẹ̀ sì kàn án lára, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje, gbogbo ibùsùn tí ọkùnrin náà bá sùn yóò jẹ́ aláìmọ́.
25 Also when a womans issue of blood runneth long time besides the time of her floures, or when she hath an issue, longer then her floures, all the dayes of the issue of her vncleannesse shee shalbe vncleane, as in the time of her floures.
“‘Bí obìnrin bá ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún ọjọ́ púpọ̀ yálà sí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tàbí tí nǹkan oṣù rẹ̀ bá kọjá ìgbà tí ó yẹ. Gbogbo ìgbà tí ó bá fi ń ní ìsun ẹ̀jẹ̀ náà ni yóò fi wà ní àìmọ́ gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
26 Euery bed whereon shee lyeth (as long as her issue lasteth) shalbe to her as her bed of her separation: and whatsoeuer she sitteth vpon, shalbe vncleane, as her vncleannes whe she is put apart.
Ibùsùn tí ó wù kí ó sùn sí ní gbogbo ìgbà tí ẹ̀jẹ̀ náà ń wá yóò jẹ́ àìmọ́ bí ibùsùn rẹ̀ ṣe jẹ́ ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀. Gbogbo ohun tí ó bá jókòó lé yóò wà ní àìmọ́, gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
27 And whosoeuer toucheth these things, shall be vncleane, and shall wash his clothes, and wash him selfe in water, and shalbe vncleane vnto the euen.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn wọ́n yóò wà ní àìmọ́. Ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀ kí ó sì wà ní àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
28 But if she be clensed of her issue, then shee shall count her seuen dayes, and after, shee shall be cleane.
“‘Nígbà tí ó bá di mímọ́ kúrò nínú ìsun rẹ̀, kí ó ka ọjọ́ méje lẹ́yìn náà, a ó kà á sí mímọ́.
29 And in the eight day shee shall take vnto her two Turtles or two yong pigeons, and bring them vnto the Priest at the doore of the Tabernacle of the Congregation.
Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé wá síwájú àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
30 And the Priest shall make of ye one a sinne offring, and of the other a burnt offring, and the Priest shall make an atonement for her before the Lord, for the issue of her vncleannes.
Kí àlùfáà fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún un, níwájú Olúwa fún àìmọ́ ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
31 Thus shall yee separate the children of Israel from their vncleannes, that they dye not in their vncleannesse, if they defile my Tabernacle that is among them.
“‘Ẹ ya ará Israẹli sọ́tọ̀ kúrò nínú ohun tí ó ń sọ wọ́n di aláìmọ́, kí wọ́n má bá a kú nínú àìmọ́ wọn nípa bíba ibùgbé mímọ́ mi jẹ́, èyí tí ó wà láàrín wọn.’”
32 This is the lawe of him that hath an issue, and of him from whome goeth an issue of seede whereby he is defiled:
Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ọkùnrin tí ó ni ìsunjáde fún ẹnikẹ́ni tí a sọ di àìmọ́ nípa ìsunjáde nǹkan ọkùnrin rẹ̀.
33 Also of her that is sicke of her floures, and of him that hath a running issue, whether it bee man or woman, and of him that lyeth with her which is vncleane.
Fún obìnrin ní nǹkan oṣù rẹ̀, fún ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ní ìsunjáde, àti fún ọkùnrin tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin tí ó jẹ́ aláìmọ́.

< Leviticus 15 >