< Joshua 18 >

1 And the whole Congregation of the children of Israel, came together at Shiloh: for they set vp the Tabernacle of the Congregation there, after the land was subiect vnto them.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli péjọ ní Ṣilo, wọ́n si kọ́ àgọ́ ìpàdé ní ibẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ náà sì wà ní abẹ́ àkóso wọn,
2 Nowe there remained among the children of Israel seuen tribes, to whom they had not deuided their inheritance.
ṣùgbọ́n ó ku ẹ̀yà méje nínú àwọn ọmọ Israẹli tí kò tí ì gba ogún ìní wọn.
3 Therefore Ioshua said vnto the children of Israel, Howe long are ye so slacke to enter and possesse the land which the Lord God of your fathers hath giuen you?
Báyìí ni Joṣua sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe dúró pẹ́ tó, kí ẹ tó gba ilẹ̀ ìní tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti fi fún yín?
4 Giue from among you for euery tribe three men, that I may sende them, and that they may rise, and walke through the land, and distribute it according to their inheritance, and returne to me.
Ẹ yan àwọn ọkùnrin mẹ́ta nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Èmi yóò rán wọn jáde láti lọ bojú wo ilẹ̀ náà káàkiri, wọn yóò sì ṣe àpèjúwe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìní ẹni kọ̀ọ̀kan. Nígbà náà ni wọn yóò padà tọ̀ mí wá.
5 And that they may deuide it vnto them into seuen parts, (Iudah shall abide in his coast at the South, and the house of Ioseph shall stand in their coastes at the North)
Ẹ̀yin yóò sì pín ilẹ̀ náà sí ọ̀nà méje kí Juda dúró sí ilẹ̀ rẹ̀ ni ìhà gúúsù àti ilé Josẹfu ní ilẹ̀ rẹ̀ ní ìhà àríwá.
6 Ye shall describe the land therefore into seuen partes, and shall bring them hither to me, and I will cast lottes for you here before the Lord our God.
Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá kọ àpèjúwe ọ̀nà méjèèje ilẹ̀ náà, ẹ mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi ní ibí, èmi ó sì ṣẹ́ kèké fún yín ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
7 But the Leuites shall haue no part among you: for the Priesthood of the Lord is their inheritance: also Gad and Reuben and halfe the tribe of Manasseh haue receiued their inheritance beyond Iorden Eastward, which Moses the seruant of the Lord gaue them.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi kò ní ìpín ní àárín yín, nítorí iṣẹ́ àlùfáà. Olúwa ni ìní wọ́n. Gadi, Reubeni àti ìdajì ẹ̀yà Manase, ti gba ìní wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani. Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.”
8 Then the men arose, and went their way: and Ioshua charged them that went to describe the land, saying, Depart, and goe through the land, and describe it, and returne to me, that I may here cast lottes for you before the Lord in Shiloh.
Bí àwọn ọkùnrin náà ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn láti fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà, Joṣua pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà káàkiri, kí ẹ sì kọ àpèjúwe rẹ̀. Lẹ́yìn náà kí ẹ padà tọ̀ mí wá, kí èmi kí ò lè ṣẹ́ kèké fún yin ní ibí ní Ṣilo ní iwájú Olúwa.”
9 So the men departed, and passed through the lande, and described it by cities into seuen partes in a booke, and returned to Ioshua into the campe at Shiloh.
Báyìí ni àwọn ọkùnrin náà lọ, wọ́n sì la ilẹ̀ náà já. Wọ́n sì kọ àpèjúwe rẹ̀ sí orí ìwé kíká ní ìlú, ní ọ̀nà méje, wọ́n sì padà tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Ṣilo.
10 Then Ioshua cast lottes for them in Shiloh before the Lord, and there Ioshua deuided the land vnto the children of Israel, according to their portions:
Joṣua sì ṣẹ́ gègé fún wọn ní Ṣilo ní iwájú Olúwa, Joṣua sì pín ilẹ̀ náà fún àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn ní ibẹ̀.
11 And the lot of the tribe of the children of Beniamin came foorth according to their families, and the cost of their lot lay betweene the children of Iudah, and the children of Ioseph.
Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Benjamini, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàrín ti ẹ̀yà Juda àti Josẹfu.
12 And their coast on the Northside was from Iorden, and the border went vp to the side of Iericho on the Northpart, and went vp through the mountaines Westward, and the endes thereof are in the wildernesse of Beth-auen:
Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jordani, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jeriko ní ìhà àríwá, ó sì forí lé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí aginjù Beti-Afeni.
13 And this border goeth along from thence to Luz, euen to the Southside of Luz (the same is Beth-el) and this border descendeth to Atroth-addar, neere the mount, that lyeth on the Southside of Beth-horon the nether.
Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúúsù ní ọ̀nà Lusi (tí í ṣe Beteli) ó sì dé Atarotu-Addari, ní orí òkè tí ó wà ní gúúsù Beti-Horoni.
14 So the border turneth, and compasseth the corner of the Sea Southward, from the mount that lyeth before Beth-horon Southward: and the endes thereof are at Kiriath-baal (which is Kiriath-iearim) a citie of the children of Iudah: this is the Westquarter.
Láti òkè tí ó kọjú sí Beti-Horoni ní gúúsù ààlà náà yà sí gúúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Baali (tí í ṣe Kiriati-Jearimu), ìlú àwọn ènìyàn Juda. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.
15 And the Southquarter is from the ende of Kiriath-iearim, and this border goeth out Westward, and commeth to the fountaine of waters of Nephtoah.
Ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jearimu ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nefitoa.
16 And this border descendeth at the ende of the mountaine, that lyeth before the valley of Ben-hinnom, which is in the valley of the gyants Northward, and descendeth into the valley of Hinnom by the side of Iebusi Southwarde, and goeth downe to En-rogel,
Ààlà náà lọ sí ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè tí ó kọjú sí àfonífojì Beni-Hinnomu, àríwá àfonífojì Refaimu. O sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí àfonífojì Hinnomu sí apá gúúsù gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè ìlú Jebusi, ó sì lọ bẹ́ẹ̀ títí dé En-Rogeli.
17 And compasseth from the North, and goeth foorth to En-shemesh, and stretcheth to Geliloth, which is toward the going vp vnto Adummim, and goeth downe to the stone of Bohan the sonne of Reuben.
Nígbà náà ni ó yípo sí ìhà àríwá, ó sì lọ sí Ẹni-Ṣemeṣi, ó tẹ̀síwájú dé Geliloti tí ó kọjú sí òkè Adummimu, ó sì sọ̀kalẹ̀ sí ibi Òkúta Bohani ọmọ Reubeni.
18 So it goeth along to the side ouer against the plaine Northward, and goeth downe into the plaine.
Ó tẹ̀síwájú títí dé gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Araba, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí aginjù.
19 After, this border goeth along to the side of Beth-hoglah Northward: and the endes thereof, that is, of the border, reach to the point of the salt Sea Northward, and to the ende of Iorden Southward: this is the Southcoast.
Nígbà náà ni ó lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Hogla, ó sì jáde ní àríwá etí bèbè Òkun Iyọ̀, ní ẹnu odò Jordani ní gúúsù. Èyí ni ààlà ti gúúsù.
20 Also Iorden is the border of it on the Eastside: this is the inheritance of the children of Beniamin by the coastes thereof rounde about according to their families.
Odò Jordani sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn. Ìwọ̀nyí ní àwọn ààlà ti ó sàmì sí ìní àwọn ìdílé Benjamini ní gbogbo àwọn àyíká wọn.
21 Nowe the cities of the tribe of the children of Beniamin according to their families, are Iericho, and Beth-hoglah, and the valley of Keziz,
Ẹ̀yà Benjamini ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí: Jeriko, Beti-Hogla, Emeki-Keṣiṣi,
22 And Beth-arabah, and Zemaraim, and Beth-el,
Beti-Araba, Semaraimu, Beteli,
23 And Auim, and Parah, and Ophrah,
Affimu, Para, Ofira
24 And Chephar, Ammonai, and Ophni, and Gaba: twelue cities with their villages.
Kefari, Ammoni, Ofini àti Geba; àwọn ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
25 Gibeon, and Ramah, and Beeroth,
Gibeoni, Rama, Beeroti,
26 And Mizpeh, and Chephirah, and Mozah,
Mispa, Kefira, Mosa,
27 And Rekem, and Irpeel, and Taralah,
Rekemu, Irpeeli, Tarala,
28 And Zela, Eleph, and Iebusi, (which is Ierusalem) Gibeath, and Kiriath: fourteene cities with their villages: this is the inheritance of the children of Beniamin according to their families.
Ṣela, Haelefi, ìlú Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu), Gibeah àti Kiriati, àwọn ìlú mẹ́rìnlá àti ìletò wọn. Èyí ni ìní Benjamini fún ìdílé rẹ̀.

< Joshua 18 >