< Job 30 >
1 Bvt now they that are yonger then I, mocke me: yea, they whose fathers I haue refused to set with the dogges of my flockes.
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà baba ẹni tí èmi kẹ́gàn láti tò pẹ̀lú àwọn ajá nínú agbo ẹran mi.
2 For whereto shoulde the strength of their handes haue serued mee, seeing age perished in them?
Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sí mi, níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?
3 For pouertie and famine they were solitary, fleeing into the wildernes, which is darke, desolate and waste.
Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyàn wọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹ ní ibi ìkọ̀sílẹ̀ ní òru.
4 They cut vp nettels by the bushes, and the iuniper rootes was their meate.
Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀bá igbó; gbogbo igikígi ni oúnjẹ jíjẹ wọn.
5 They were chased forth from among men: they shouted at them, as at a theefe.
A lé wọn kúrò láàrín ènìyàn, àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.
6 Therfore they dwelt in the clefts of riuers, in the holes of the earth and rockes.
A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkúta àfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.
7 They roared among the bushes, and vnder the thistles they gathered themselues.
Wọ́n ń dún ní àárín igbó wọ́n kó ara wọn jọ pọ̀ ní abẹ́ ẹ̀gún neteli.
8 They were the children of fooles and the children of villaines, which were more vile then the earth.
Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àní àwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.
9 And now am I their song, and I am their talke.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àní èmi di ẹni ìṣọ̀rọ̀ sí láàrín wọn.
10 They abhorre me, and flee farre from mee, and spare not to spit in my face.
Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnà sí mi, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sí mi lójú.
11 Because that God hath loosed my corde and humbled mee, they haue loosed the bridle before me.
Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi, ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìdẹ̀kùn níwájú mi.
12 The youth rise vp at my right hand: they haue pusht my feete, and haue trode on me as on the paths of their destruction.
Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apá ọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mi kúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dè mí.
13 They haue destroyed my paths: they tooke pleasure at my calamitie, they had none helpe.
Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sì sọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
14 They came as a great breach of waters, and vnder this calamitie they come on heapes.
Wọ́n ya sí mi bí i omi tí ó ya gbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n rọ́ wá.
15 Feare is turned vpon mee: and they pursue my soule as the winde, and mine health passeth away as a cloude.
Ẹ̀rù ńlá bà mí; wọ́n lépa ọkàn mi bí ẹ̀fúùfù, àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.
16 Therefore my soule is nowe powred out vpon me, and the dayes of affliction haue taken holde on me.
“Àti nísinsin yìí, ayé mi n yòrò lọ díẹ̀díẹ̀; ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mímú.
17 It pearceth my bones in the night, and my sinewes take no rest.
Òru gún mi nínú egungun mi, èyí tí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.
18 For the great vehemencie is my garment changed, which compasseth me about as the colar of my coate.
Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi, ó sì lẹ̀ mọ́ mi ní ara yíká bí aṣọ ìlekè mi.
19 He hath cast me into the myre, and I am become like ashes and dust.
Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀, èmi sì dàbí eruku àti eérú.
20 Whe I cry vnto thee, thou doest not heare me, neither regardest me, when I stand vp.
“Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.
21 Thou turnest thy selfe cruelly against me, and art enemie vnto mee with the strength of thine hand.
Ìwọ padà di ẹni ìkà sí mi; ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.
22 Thou takest me vp and causest mee to ride vpon the winde, and makest my strength to faile.
Ìwọ gbé mi sókè sí inú ẹ̀fúùfù, ìwọ mú mi fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátápátá.
23 Surely I knowe that thou wilt bring mee to death, and to the house appoynted for all the liuing.
Èmi sá à mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọ sínú ikú, sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.
24 Doubtles none can stretch his hand vnto the graue, though they cry in his destruction.
“Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóò ha nawọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubú rẹ̀, tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.
25 Did not I weepe with him that was in trouble? was not my soule in heauinesse for the poore?
Èmi kò ha sọkún bí fún ẹni tí ó wà nínú ìṣòro? Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún tálákà bí?
26 Yet when I looked for good, euill came vnto me: and when I waited for light, there came darkenesse.
Nígbà tí mo fojú ṣọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé; nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.
27 My bowels did boyle without rest: for the dayes of affliction are come vpon me.
Ikùn mí n ru kò sì sinmi, ọjọ́ ìpọ́njú ti dé bá mi.
28 I went mourning without sunne: I stood vp in the congregation and cryed.
Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú oòrùn; èmi dìde dúró ní àwùjọ mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́.
29 I am a brother to the dragons, and a companion to the ostriches.
Èmi ti di arákùnrin ìkookò, èmi di ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.
30 My skinne is blacke vpon me, and my bones are burnt with heate.
Àwọ̀ mi di dúdú ní ara mi; egungun mi sì jórun fún ooru.
31 Therefore mine harpe is turned to mourning, and mine organs into the voyce of them that weepe.
Ohun èlò orin mi pẹ̀lú sì di ti ọ̀fọ̀, àti ìpè orin mi sì di ohùn àwọn tí ń sọkún.