< Jeremiah 1 >

1 The wordes of Ieremiah the sonne of Hilkiah one of the Priests that were at Anathoth in the lande of Beniamin.
Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini.
2 To whom the worde of the Lord came in the dayes of Iosiah the sonne of Amon King of Iudah in the thirteenth yeere of his reigne:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda,
3 And also in the dayes of Iehoiakim the sonne of Iosiah King of Iudah vnto the ende of the eleuenth yeere of Zedekiah, the sonne of Iosiah King of Iudah, euen vnto the carying away of Ierusalem captiue in the fift moneth.
àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.
4 Then the worde of the Lord came vnto me, saying,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,
5 Before I formed thee in the wombe, I knewe thee, and before thou camest out of the wombe, I sanctified thee, and ordeined thee to be a Prophet vnto the nations.
“Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n, kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀. Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.”
6 Then said I, Oh, Lord God, behold, I can not speake, for I am a childe.
Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”
7 But the Lord said vnto me, Say not, I am a childe: for thou shalt goe to all that I shall send thee, and whatsoeuer I command thee, shalt thou speake.
Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.”
8 Be not afraide of their faces: for I am with thee to deliuer thee, saith the Lord.
Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.
9 Then the Lord stretched out his hand and touched my mouth, and the Lord said vnto me, Beholde, I haue put my wordes in thy mouth.
Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ.
10 Beholde, this day haue I set thee ouer the nations and ouer the kingdomes to plucke vp, and to roote out, and to destroye and throwe downe, to builde, and to plant.
Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.
11 After this the worde of the Lord came vnto me, saying, Ieremiah, what seest thou? And I said, I see a rod of an almonde tree.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé: “Kí ni o rí Jeremiah?” Mo sì dáhùn wí pé, “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”
12 Then saide the Lord vnto me, Thou hast seene aright: for I will hasten my worde to performe it.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”
13 Againe the worde of the Lord came vnto me the second time, saying, What seest thou? And I saide, I see a seething pot looking out of the North.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.
14 Then saide the Lord vnto me, Out of the North shall a plague be spred vpon all the inhabitants of the land.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà.
15 For loe, I will call all the families of the kingdomes of the North, saith the Lord, and they shall come, and euery one shall set his throne in the entring of the gates of Ierusalem, and on all the walles thereof rounde about, and in all the cities of Iudah.
Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọba wọn yóò wá gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn ìlú Juda.
16 And I will declare vnto them my iudgements touching all the wickednesse of them that haue forsaken me, and haue burnt incense vnto other gods, and worshipped the workes of their owne handes.
Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀, nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.
17 Thou therefore trusse vp thy loynes, and arise and speake vnto them all that I commaund thee: be not afraide of their faces, lest I destroy thee before them.
“Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn.
18 For I, beholde, I this day haue made thee a defenced citie, and an yron pillar and walles of brasse against the whole lande, against the Kings of Iudah, and against the princes thereof, against the Priestes thereof and against the people of the lande.
Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
19 For they shall fight against thee, but they shall not preuaile against thee: for I am with thee to deliuer thee, sayth the Lord.
Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.

< Jeremiah 1 >