< Jeremiah 5 >
1 Run to and from by the streetes of Ierusalem, and beholde nowe, and knowe, and inquire in the open places thereof, if ye can finde a man, or if there be any that executeth iudgement, and seeketh the trueth, and I will spare it.
“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
2 For though they say, The Lord liueth, yet doe they sweare falsely.
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3 O Lord, are not thine eyes vpon the trueth? thou hast striken them, but they haue not sorowed: thou hast consumed them, but they haue refused to receiue correction: they haue made their faces harder then a stone, and haue refused to returne.
Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4 Therefore I saide, Surely they are poore, they are foolish, for they know not the way of the Lord, nor the iudgement of their God.
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
5 I will get me vnto the great men, and will speake vnto them: for they haue knowen the way of the Lord, and the iudgement of their God: but these haue altogether broken the yoke, and burst the bondes.
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
6 Wherefore a lyon out of the forest shall slay them, and a wolfe of the wildernesse shall destroy them: a leopard shall watch ouer their cities: euery one that goeth out thence, shall be torne in pieces, because their trespasses are many, and their rebellions are increased.
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
7 Howe should I spare thee for this? thy children haue forsaken me, and sworne by them that are no gods: though I fed them to the full, yet they committed adulterie, and assembled them selues by companies in the harlots houses.
“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
8 They rose vp in the morning like fed horses: for euery man neyed after his neighbours wife.
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
9 Shall I not visite for these things, saith the Lord? Shall not my soule be auenged on such a nation as this?
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
10 Clime vp vpon their walles, and destroy them, but make not a full ende: take away their batilments, for they are not the Lords.
“Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 For the house of Israel, and the house of Iudah haue grieuously trespassed against me, saith the Lord.
Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
12 They haue denied the Lord, and saide, It is not he, neither shall the plague come vpon vs, neither shall we see sworde nor famine.
Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 And the Prophetes shall be as winde, and the worde is not in them: thus shall it come vnto them.
Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
14 Wherefore thus saith the Lord God of hostes, Because ye speake such wordes, beholde, I will put my wordes into thy mouth, like a fire, and this people shall be as wood, and it shall deuoure them.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Loe, I will bring a nation vpon you from farre, O house of Israel, saith the Lord, which is a mightie nation, and an ancient nation, a nation whose language thou knowest not, neither vnderstandest what they say.
Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 Whose quiuer is as an open sepulchre: they are all very strong.
Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 And they shall eate thine haruest and thy bread: they shall deuoure thy sonnes and thy daughters: they shall eate vp thy sheepe and thy bullocks: they shall eate thy vines and thy figge trees: they shall destroy with the sworde thy fenced cities, wherein thou didest trust.
Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
18 Neuerthelesse at those dayes, sayth the Lord, I will not make a full ende of you.
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
19 And when ye shall say, Wherefore doeth the Lord our God doe these things vnto vs? then shalt thou answere them, Like as ye haue forsaken me and serued strange gods in your land, so shall ye serue strangers in a land that is not yours.
Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
20 Declare this in the house of Iaakob, and publish it in Iudah, saying,
“Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
21 Heare nowe this, O foolish people, and without vnderstanding, which haue eyes and see not, which haue eares and heare not.
Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
22 Feare ye not me, saith the Lord? or will ye not be afraide at my presence, which haue placed the sand for the bounds of the sea by the perpetuall decree that it cannot passe it, and though the waues thereof rage, yet can they not preuaile, though they roare, yet can they not passe ouer it?
Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
23 But this people hath an vnfaithfull and rebellious heart: they are departed and gone.
Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24 For they say not in their heart, Let vs nowe feare the Lord our God, that giueth raine both early and late in due season: hee reserueth vnto vs the appointed weekes of the haruest.
Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
25 Yet your iniquities haue turned away these things, and your sinnes haue hindred good things from you.
Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
26 For among my people are founde wicked persons, that lay waite as hee that setteth snares: they haue made a pit, to catch men.
“Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
27 As a cage is full of birdes, so are their houses full of deceite: thereby they are become great and waxen riche.
Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
28 They are waxen fat and shining: they doe ouerpasse the deedes of the wicked: they execute no iudgement, no not the iudgement of the fatherlesse: yet they prosper, though they execute no iudgement for the poore.
wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
29 Shall I not visite for these things, sayth the Lord? or shall not my soule be auenged on such a nation as this?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
30 An horrible and filthie thing is committed in the land.
“Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
31 The Prophets prophesie lies, and ye Priests receiue giftes in their handes, and my people delite therein. What will ye then doe in the ende thereof?
Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?