< Jeremiah 37 >
1 And King Zedekiah the sonne of Iosiah reigned for Coniah the sonne of Iehoiakim, whome Nebuchad-nezzar King of Babel made King in the land of Iudah.
Sedekiah ọmọ Josiah sì jẹ ọba ní ipò Jehoiakini ọmọ Jehoiakimu ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli fi jẹ ọba ní ilẹ̀ Juda.
2 But neither he, nor his seruants, nor the people of the land would obey the wordes of the Lord, which he spake by the ministerie of the Prophet Ieremiah.
Ṣùgbọ́n àti òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kò fetísí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípa wòlíì Jeremiah.
3 And Zedekiah the King sent Iehucal the sonne of Shelemiah, and Zephaniah the sonne of Maaseiah the Priest to the Prophet Ieremiah, saying, Pray now vnto the Lord our God for vs.
Sedekiah ọba sì rán Jehukali ọmọ Ṣelemiah àti Sefaniah ọmọ Maaseiah sí Jeremiah wòlíì wí pé, “Jọ̀wọ́ gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
4 (Now Ieremiah went in and out among the people: for they had not put him into the prison.
Nígbà yìí Jeremiah sì ń wọlé, ó sì ń jáde láàrín àwọn ènìyàn nítorí wọ́n ti fi sínú túbú.
5 Then Pharaohs hoste was come out of Egypt: and when the Caldeans that besieged Ierusalem, heard tidings of them, they departed from Ierusalem)
Àwọn ọmọ-ogun Farao ti jáde kúrò nílẹ̀ Ejibiti àti nígbà tí àwọn ará Babeli tó ń ṣàtìpó ní Jerusalẹmu gbọ́ ìròyìn nípa wọn, wọ́n kúrò ní Jerusalẹmu.
6 Then came the worde of the Lord vnto the Prophet Ieremiah, saying,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì Ọlọ́run wá:
7 Thus sayth the Lord God of Israel, Thus shall ye say to the King of Iudah, that sent you vnto me to inquire of me, Behold, Pharaohs hoste, which is come forth to helpe you, shall returne to Egypt into their owne land.
“Èyí ni, ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ fún ọba àwọn Juda tó rán ọ láti wádìí nípa mi. ‘Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáde láti kún ọ lọ́wọ́ yóò padà sílẹ̀ wọn sí Ejibiti.
8 And the Caldeans shall come againe, and fight against this citie, and take it and burne it with fire.
Nígbà náà ni àwọn ará Babeli yóò padà láti gbógun ti ìlú. Wọn yóò mú wọn nígbèkùn, wọn yóò sì fi iná jó ìlú náà kanlẹ̀.’
9 Thus sayth the Lord, Deceiue not your selues, saying, The Caldeans shall surely depart from vs: for they shall not depart.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹ má ṣe tan ara yín jẹ ní èrò wí pé, ‘Àwọn ará Babeli yóò fi wá sílẹ̀ pẹ̀lú ìdánilójú.’ Wọn kò ní ṣe bẹ́ẹ̀.
10 For though ye had smitten the whole hoste of the Caldeans that fight against you, and there remained but wounded men among them, yet should euery man rise vp in his tent, and burne this citie with fire.
Kódà tó bá ṣe pé wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọmọ-ogun Babeli tí ń gbóguntì yín àti àwọn tí ìjàǹbá ṣe, tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ibùdó wọn; wọn yóò jáde láti jó ìlú náà kanlẹ̀.”
11 When the hoste of the Caldeans was broken vp from Ierusalem, because of Pharaohs armie,
Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ-ogun Babeli ti kúrò ní Jerusalẹmu nítorí àwọn ọmọ-ogun Farao.
12 Then Ieremiah went out of Ierusalem to goe into the land of Beniamin, separating himselfe thence from among the people.
Jeremiah múra láti fi ìlú náà sílẹ̀, láti lọ sí olú ìlú Benjamini láti gba ẹ̀tọ́ rẹ̀ nínú ohun ìní láàrín àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀.
13 And when hee was in the gate of Beniamin, there was a chiefe officer, whose name was Iriiah, the sonne of Shelemiah, the sonne of Hananiah, and he tooke Ieremiah the Prophet, saying, Thou fleest to the Caldeans.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ẹnu ibodè Benjamini, olórí àwọn olùṣọ́ tí orúkọ rẹ ń jẹ́ Irijah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Hananiah mú un, ó wí pé, “Ìwọ ń fi ara mọ́ àwọn ará Babeli.”
14 Then sayde Ieremiah, That is false, I flee not to the Caldeans: but he would not heare him: so Iriiah tooke Ieremiah, and brought him to the princes.
Jeremiah sọ wí pé, “Èyí kì í ṣe òtítọ́! Èmi kò yapa sí àwọn ará Babeli.” Ṣùgbọ́n Irijah ko gbọ́ tirẹ̀, dípò èyí a mú Jeremiah, ó sì mú un lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ìjòyè.
15 Wherefore the princes were angry with Ieremiah, and smote him, and layde him in prison in the house of Iehonathan the scribe: for they had made that the prison.
Nítorí náà ni àwọn ìjòyè ṣe bínú sí Jeremiah, wọ́n jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n tún fi sí túbú nílé Jonatani akọ̀wé nítorí wọ́n ti fi èyí ṣe ilé túbú.
16 When Ieremiah was entred into the dungeon, and into the prisons, and had remained there a long time,
Wọ́n fi Jeremiah sínú túbú tí ó ṣókùnkùn biribiri; níbi tí ó wà fún ìgbà pípẹ́.
17 Then Zedekiah the King sent, and tooke him out, and the King asked him secretly in his house, and said, Is there any worde from the Lord? And Ieremiah sayd, Yea: for, sayd he, thou shalt be deliuered into the hand of the King of Babel.
Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ sí i, tí ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n mú wá sí ààfin níbi tí ó ti bi í ní ìkọ̀kọ̀ pé, “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ kan wà láti ọ̀dọ̀ Olúwa?” Jeremiah fèsì pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, wọn ó fi ọ́ lé ọwọ́ ọba Babeli.”
18 Moreouer, Ieremiah sayd vnto King Zedekiah, What haue I offended against thee, or against thy seruants, or against this people, that ye haue put me in prison?
Nígbà náà, Jeremiah sọ fún ọba Sedekiah pé, “Irú ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ yín, àwọn ìjòyè yín pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ẹ fi sọ mí sínú túbú?
19 Where are nowe your prophets, which prophecied vnto you, saying, The King of Babel shall not come against you, nor against this land?
Níbo ni àwọn wòlíì yín tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín wí pé ọba Babeli kò ní gbóguntì yín wá?
20 Therefore heare nowe, I pray thee, O my lorde the King: let my prayer be accepted before thee, that thou cause mee not to returne to the house of Iehonathan the scribe, least I die there.
Ṣùgbọ́n ní báyìí, olúwa mi ọba, èmí bẹ̀ ọ. Jẹ́ kí n mú ẹ̀dùn ọkàn mi tọ̀ ọ́ wá; má ṣe rán mi padà sí ilé Jonatani akọ̀wé, àfi kí n kú síbẹ̀.”
21 Then Zedekiah the King commanded, that they should put Ieremiah in the court of the prison, and that they should giue him dayly a piece of bread out of the bakers streete vntill all the bread in the citie were eaten vp. Thus Ieremiah remained in the court of the prison.
Ọba Sedekiah wá pàṣẹ pé kí wọ́n fi Jeremiah sínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́, àti kí wọn sì fún ní àkàrà ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan títí tí àkàrà tó wà ní ìlú yóò fi tán; bẹ́ẹ̀ ni Jeremiah wà nínú àgbàlá náà.