< Jeremiah 32 >

1 The worde that came vnto Ieremiah from the Lord, in the tenth yere of Zedekiah king of Iudah, which was the eightenth yeere of Nebuchad-nezzar.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
2 For then the King of Babels hoste besieged Ierusalem: And Ieremiah the Prophet was shutte vp in the court of the prison, which was in the King of Iudahs house.
Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
3 For Zedekiah King of Iudah had shut him vp, saying, Wherefore doest thou prophesie, and say, Thus saith the Lord, Beholde, I will giue this citie into the handes of the King of Babel, and he shall take it?
Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
4 And Zedekiah the King of Iudah shall not escape out of the hande of the Caldeans, but shall surely be deliuered into the handes of the King of Babel, and shall speake with him mouth to mouth, and his eyes shall beholde his face,
Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
5 And he shall lead Zedekiah to Babel, and there shall he be, vntil I visit him, saith ye Lord: though ye fight with the Caldeans, ye shall not prosper.
Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
6 And Ieremiah said, The word of the Lord came vnto me, saying,
Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
7 Beholde, Hanameel, the sonne of Shallum thine vncle, shall come vnto thee and say, Bye vnto thee my fielde, that is in Anathoth: for the title by kindred appertaineth vnto thee to bye it.
Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
8 So Hanameel, mine vncles sonne, came to mee in the court of the prison, according to the word of the Lord, and said vnto me, Bye my field, I pray thee, that is in Anathoth, which is in the countrey of Beniamin: for the right of the possession is thine, and the purchase belongeth vnto thee: bye it for thee. Then I knewe that this was the worde of the Lord.
“Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
9 And I bought the field of Hanameel, mine vncles sonne, that was in Anathoth, and weighed him the siluer, euen seuen shekels, and tenne pieces of siluer.
Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
10 And I writ it in the booke and signed it, and tooke witnesses, and weighed him the siluer in the balances.
Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
11 So I tooke the booke of the possession, being sealed according to the Lawe, and custome, with the booke that was open,
Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
12 And I gaue the booke of the possession vnto Baruch the sonne of Neriah, the sonne of Maaseiah, in the sight of Hanameel mine vncles sonne, and in the presence of the witnesses, written in the booke of the possession, before al the Iewes that sate in the court of the prison.
Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
13 And I charged Baruch before them, saying,
“Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
14 Thus saith the Lord of hostes, the God of Israel, Take the writings, euen this booke of the possession, both that is sealed, and this booke that is open, and put them in an earthen vessell, that they may continue a long time.
èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
15 For the Lord of hostes, the God of Israel saith thus, Houses and fieldes, and vineyardes shall be possessed againe in this land.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
16 Now when I had deliuered the booke of the possession vnto Baruch, the sonne of Neriah, I prayed vnto the Lord, saying,
“Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
17 Ah Lord God, beholde, thou hast made the heauen and the earth by thy great power, and by thy stretched out arme, and there is nothing hard vnto thee.
“Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
18 Thou shewest mercie vnto thousands, and recompensest the iniquitie of the fathers into the bosome of their children after them: O God the great and mightie, whose Name is ye Lord of hostes,
O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
19 Great in counsell, and mightie in worke, (for thine eyes are open vpon all the wayes of ye sonnes of men, to giue to euery one according to his wayes, and according to the fruite of his workes)
Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
20 Which hast set signes and wonders in the land of Egypt vnto this day, and in Israel, and among all men, and hast made thee a Name, as appeareth this day,
O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
21 And hast brought thy people Israel out of the land of Egypt with signes, and with wonders, and with a strong hand, with a stretched out arme, and with great terrour,
O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
22 And hast giuen them this land, which thou diddest sweare to their fathers to giue them, euen a land, that floweth with milke and hony,
Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
23 And they came in, and possessed it, but they obeyed not thy voyce, neither walked in thy Law: all that thou commaundedst them to doe, they haue not done: therefore thou hast caused this whole plague to come vpon them.
Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
24 Beholde, the mounts, they are come into the citie to take it, and the citie is giuen into the hande of the Caldeans, that fight against it by meanes of the sword, and of the famine, and of the pestilence, and what thou hast spoken, is come to passe, and beholde, thou seest it.
“Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
25 And thou hast sayd vnto me, O Lord God, Bye vnto thee the fielde for siluer, and take witnesses: for the citie shall be giuen into the hand of the Caldeans.
Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
26 Then came the worde of the Lord vnto Ieremiah, saying,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
27 Beholde, I am the LORD GOD of all flesh: is there any thing too hard for me?
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
28 Therefore thus saith the Lord, Beholde, I wil giue this citie into the hand of the Caldeans, and into the hand of Nebuchad-nezzar, King of Babel, and he shall take it.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
29 And the Caldeans shall come and fight against this citie, and set fire on this citie and burne it, with the houses, vpon whose rouses they haue offred incense vnto Baal, and powred drinke offrings vnto other gods, to prouoke me vnto anger.
Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
30 For the children of Israel, and the children of Iudah haue surely done euill before me from their youth: for the children of Israel haue surely prouoked me to anger with the workes of their hands, saith the Lord.
“Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
31 Therefore this citie hath bene vnto me as a prouocation of mine anger, and of my wrath, from the day, that they built it, euen vnto this day, that I should remoue it out of my sight,
Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
32 Because of all the euill of the children of Israel, and of the children of Iudah, which they haue done to prouoke mee to anger, euen they, their Kings, their Princes, their Priests, and their Prophets, and the men of Iudah, and the inhabitants of Ierusalem.
Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
33 And they haue turned vnto me the backe and not the face: though I taught them rising vp earely, and instructing them, yet they were not obedient to receiue doctrine,
Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
34 But they set their abominations in ye house (whereupon my Name was called) to defile it,
Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
35 And they built the hie places of Baal, which are in the valley of Ben-hinnom, to cause their sonnes and their daughters to passe through the fire vnto Molech, which I commanded them not, neither came it into my minde, that they should doe such abomination, to cause Iudah to sinne.
Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
36 And nowe therefore, thus hath the Lord God of Israel spoken, concerning this citie, whereof ye say, It shalbe deliuered into the hand of the King of Babel by the sword, and by the famine, and by the pestilence,
“Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
37 Beholde, I will gather them out of all countreys, wherein I haue scattered them in mine anger, and in my wrath, and in great indignation, and I wil bring them againe vnto this place, and I will cause them to dwell safely.
Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
38 And they shall be my people, and I will be their God.
Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
39 And I wil giue them one heart and one way that they may feare me for euer for ye wealth of them, and of their children after them.
Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
40 And I wil make an euerlasting couenant with them, that I wil neuer turne away from them to doe them good, but I wil put my feare in their hearts, that they shall not depart from me.
Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
41 Yea, I wil delite in them to do them good, and I wil plant them in this land assuredly with my whole heart, and with all my soule.
Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
42 For thus sayth the Lord, Like as I haue brought all this great plague vpon this people, so wil I bring vpon them all the good that I haue promised them.
“Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
43 And the fields shalbe possessed in this land, whereof ye say, It is desolate without man or beast, and shalbe giuen into the hand of the Caldeans.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
44 Men shall buy fields for siluer, and make writings and seale them, and take witnesses in the land of Beniamin, and round about Ierusalem, and in the cities of Iudah, and in the cities of the mountaines, and in the cities of the plaine, and in the cities of the South: for I wil cause their captiuitie to returne, saith the Lord.
Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”

< Jeremiah 32 >