< Jeremiah 25 >

1 The word that came to Ieremiah, concerning all the people of Iudah in the fourth yeere of Iehoiakim the sonne of Iosiah King of Iudah that was in the first yeere of Nebuchad-nezzar King of Babel:
Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
2 The which Ieremiah the Prophet spake vnto all the people of Iudah, and to all the inhabitants of Ierusalem, saying,
Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
3 From the thirteenth yeere of Iosiah the sonne of Amon King of Iudah, euen vnto this day (that is the three and twentieth yeere) the word of the Lord hath come vnto mee, and I haue spoken vnto you rising earely and speaking, but ye woulde not heare.
Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
4 And the Lord hath sent vnto you all his seruantes the Prophets, rising early and sending them, but yee would not heare, nor encline your eares to obey.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
5 They sayde, Turne againe now euery one from his euill way, and from the wickednes of your inuentions, and ye shall dwell in the lande that the Lord hath giuen vnto you, and to your fathers for euer and euer.
Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
6 And go not after other gods to serue them and to worshippe them, and prouoke me not to anger with the workes of your hands, and I will not punish you.
Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
7 Neuerthelesse ye would not heare me, saith the Lord, but haue prouoked mee to anger with the workes of your hands to your owne hurt.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
8 Therefore thus saith the Lord of hostes, Because ye haue not heard my wordes,
Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
9 Beholde, I will send and take to mee all the families of the North, saith the Lord, and Nebuchad-nezzar the King of Babel my seruant, and will bring them against this lande, and against the inhabitantes thereof, and against all these nations rounde about, and will destroy them, and make them an astonishment and an hissing, and a continuall desolation.
Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
10 Moreouer I will take from them the voyce of mirth and the voyce of gladnesse, the voyce of the bridegrome and the voyce of the bride, the noise of the milstones, and the light of the candle.
Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
11 And this whole land shalbe desolate, and an astonishment, and these nations shall serue the King of Babel seuentie yeeres.
Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
12 And when the seuentie yeres are accomplished, I will visite the King of Babel and that nation, saith the Lord, for their iniquities, euen the land of the Caldeans, and will make it a perpetuall desolation,
“Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
13 And I will bring vpon that lande all my wordes which I haue pronounced against it, euen all that is written in this booke, which Ieremiah hath prophecied against all nations.
Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
14 For many nations, and great Kings shall euen serue themselues of them: thus will I recompense them according to their deedes, and according to the workes of their owne handes.
Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
15 For thus hath the Lord God of Israel spoken vnto me, Take the cuppe of wine of this mine indignation at mine hand, and cause all the nations, to whome I sende thee, to drinke it.
Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
16 And they shall drinke, and be moued and be mad, because of the sworde that I will sende among them.
Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
17 Then tooke I the cup at the Lordes hand, and made all people to drinke, vnto whome the Lord had sent me:
Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
18 Euen Ierusalem, and the cities of Iudah, and the Kings thereof, and the princes thereof, to make them desolate, an astonishment, an hissing, and a curse, as appeareth this day:
Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
19 Pharaoh also, King of Egypt, and his seruants, and his princes, and all his people:
Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
20 And all sortes of people, and all the Kings of the lande of Vz: and all the Kings of the lande of the Philistims, and Ashkelon, and Azzah, and Ekron, and the remnant of Ashdod:
Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
21 Edom, and Moab, and the Ammonites,
Edomu, Moabu àti Ammoni;
22 And all the Kings of Tyrus, and all the kings of Zidon, and the Kings of the Yles, that are beyonde the Sea,
gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
23 And Dedan, and Tema, and Buz, and all that dwell in the vttermost corners,
Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
24 And all the Kings of Arabia, and all the Kings of Arabia, that dwell in the desert,
Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
25 And all the Kings of Zimri, and all the Kings of Elam, and all the Kings of the Medes,
Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
26 And all the Kings of the North, farre and neere one to another, and all the kingdomes of the worlde, which are vpon the earth, and the king of Sheshach shall drinke after them.
Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
27 Therefore say thou vnto them, Thus saith the Lord of hostes, the God of Israel, Drinke and bee drunken, and spewe and fall, and rise no more, because of the sworde, which I will sende among you.
“Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
28 But if they refuse to take the cuppe at thine hande to drinke, then tell them, Thus saith the Lord of hostes, Ye shall certainely drinke.
Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
29 For loe, I beginne to plague the citie, where my Name is called vpon, and shoulde you goe free? Ye shall not goe quite: for I will call for a sword vpon al the inhabitants of the earth, saith the Lord of hostes.
Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
30 Therefore prophecie thou against them al these words, and say vnto them, The Lord shall roare from aboue, and thrust out his voyce from his holy habitation: he shall roare vpon his habitation, and crie aloude, as they that presse the grapes, against all the inhabitants of the earth.
“Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
31 The sounde shall come to the endes of the earth: for the Lord hath a controuersie with the nations, and will enter into iudgement with all flesh, and he will giue them that are wicked, to the sworde, saith the Lord.
Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
32 Thus saith the Lord of hostes, Behold, a plague shall goe foorth from nation to nation, and a great whirlewinde shalbe raised vp from the coastes of the earth,
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
33 And the slaine of the Lord shall be at that day, from one ende of the earth, euen vnto the other ende of the earth: they shall not bee mourned, neither gathered nor buried, but shalbe as the dongue vpon the grounde.
Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
34 Howle, ye shepherdes, and crie, and wallowe your selues in the ashes, ye principall of the flocke: for your dayes of slaughter are accomplished, and of your dispersion, and ye shall fall like precious vessels.
Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
35 And the flight shall faile from the shepherdes, and the escaping from the principall of the flocke.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
36 A voyce of the crye of the shepherdes, and an howling of the principall of the flocke shalbe heard: for the Lord hath destroyed their pasture.
Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
37 And the best pastures are destroyed because of the wrath and indignation of the Lord.
Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
38 He hath forsaken his couert, as the lyon: for their land is waste, because of the wrath of the oppressor, and because of ye wrath of his indignatio.
Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.

< Jeremiah 25 >