< Isaiah 3 >

1 For lo, the Lord God of hostes will take away from Ierusalem and from Iudah the stay and the strength: euen all the staye of bread, and all the stay of water,
Kíyèsi i, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
2 The strong man, and the man of warre, the iudge and the prophet, the prudent and the aged,
Àwọn akíkanjú àti jagunjagun, adájọ́ àti wòlíì, aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
3 The captaine of fiftie, and the honourable, and the counseller, and the cunning artificer, and the eloquent man.
balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga; olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́ àti ògbójú oníṣègùn.
4 And I will appoint children to bee their princes, and babes shall rule ouer them.
“Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn, ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì máa jẹ ọba lórí i wọn.”
5 The people shalbe oppressed one of another, and euery one by his neighbour: the children shall presume against the ancient, and the vile against the honourable.
Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n ọmọnìkejì, wọn lójú ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò sí aládùúgbò rẹ̀. Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
6 When euery one shall take holde of his brother of the house of his father, and say, Thou hast clothing: thou shalt bee our prince, and let this fall be vnder thine hand.
Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin rẹ̀ mú, nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé, “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa, sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
7 In that day hee shall sweare, saying, I cannot bee an helper: for there is no bread in mine house, nor clothing: therefore make me no prince of the people.
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé, “Èmi kò ní àtúnṣe kan. Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé, ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
8 Doubtlesse Ierusalem is fallen, and Iudah is fallen downe, because their tongue and workes are against the Lord, to prouoke the eyes of his glory.
Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n Juda ń ṣubú lọ, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa, láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
9 The triall of their countenance testifieth against them, yea, they declare their sinnes as Sodom, they hide them not. Wo be vnto their soules: for they haue rewarded euil vnto themselues.
Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn, wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu; wọn ò fi pamọ́! Ègbé ni fún wọn! Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
10 Say ye, Surely it shalbe well with the iust: for they shall eate the fruite of their workes.
Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn, nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
11 Woe be to the wicked, it shalbe euill with him: for the reward of his handes shalbe giuen him.
Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn, a ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
12 Children are extortioners of my people, and women haue rule ouer them: O my people, they that leade thee, cause thee to erre, and destroy the way of thy paths.
Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí. Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà, wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
13 The Lord standeth vp to pleade, yea, hee standeth to iudge the people.
Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́ Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
14 The Lord shall enter into iudgement with the Ancients of his people and the princes thereof: for ye haue eaten vp the vineyarde: the spoyle of the poore is in your houses.
Olúwa dojú ẹjọ́ kọ àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀. “Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi, ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
15 What haue ye to do, that ye beate my people to pieces, and grinde the faces of the poore, saith the Lord, euen the Lord of hoasts?
Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?” ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
16 The Lord also saith, Because the daughters of Zion are hautie, and walke with stretched out neckes, and with wandering eyes, walking and minsing as they goe, and making a tinkeling with their feete,
Olúwa wí pé, “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga, wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn, tí wọn ń fojú pe ọkùnrin, tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
17 Therefore shall the Lord make the heades of the daughters of Zion balde, and the Lord shall discouer their secrete partes.
Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni, Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
18 In that day shall the Lord take away the ornament of the slippers, and the calles, and the round tyres,
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá
19 The sweete balles, and the brasselets, and the bonnets,
gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,
20 The tyres of the head, and the sloppes, and the head bandes, and the tablets, and the earings,
gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn,
21 The rings and the mufflers,
òrùka ọwọ́ àti ti imú,
22 The costly apparell and the vailes, and the wimples, and the crisping pinnes,
àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́,
23 And the glasses and the fine linen, and the hoodes, and the launes.
dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
24 And in steade of sweete sauour, there shall be stinke, and in steade of a girdle, a rent, and in steade of dressing of the heare, baldnesse, and in steade of a stomacher, a girding of sackecloth, and burning in steade of beautie.
Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá, okùn ni yóò wà dípò àmùrè, orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
25 Thy men shall fall by the sworde, and thy strength in the battell.
Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú, àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
26 Then shall her gates mourne and lament, and she, being desolate, shall sit vpon the ground.
Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀, nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.

< Isaiah 3 >