< Isaiah 23 >
1 The burden of Tyrus. Howle, yee shippes of Tarshish: for it is destroied, so that there is none house: none shall come from the lande of Chittim: it is reueiled vnto them.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Tire. Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi! Nítorí a ti pa Tire run láìsí ilé tàbí èbúté. Láti ilẹ̀ Saipurọsi ni ọ̀rọ̀ ti wá sọ́dọ̀ wọn.
2 Be still, yee that dwell in the yles: the marchantes of Zidon, and such as passe ouer the sea, haue replenished thee.
Dákẹ́ jẹ́ẹ́, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù àti ẹ̀yin oníṣòwò ti Sidoni, ẹ̀yin tí àwọn a wẹ Òkun ti sọ dọlọ́rọ̀.
3 The seede of Nilus growing by the abundance of waters, and the haruest of the riuer was her reuenues, and she was a marte of the nations.
Láti orí àwọn omi ńlá ni irúgbìn ìyẹ̀fun ti ilẹ̀ Ṣihori ti wá; ìkórè ti odò Naili ni owóòná Tire, òun sì ti di ibùjókòó ọjà fún àwọn orílẹ̀-èdè.
4 Be ashamed, thou Zidon: for the sea hath spoken, euen the strength of the sea, saying, I haue not trauailed, nor brought forth children, neither nourished yong men, nor brought vp virgins.
Kí ojú kí ó tì ọ́, ìwọ Sidoni àti ìwọ àní ìwọ ilé ààbò ti Òkun, nítorí Òkun ti sọ̀rọ̀. “Èmi kò tí ì wà ní ipò ìrọbí tàbí ìbímọ rí Èmi kò tí ì wo àwọn ọmọkùnrin tàbí kí n tọ́ àwọn ọmọbìnrin dàgbà rí.”
5 When the fame commeth to the Egyptians, they shall be sorie, concerning the rumour of Tyrus.
Nígbà tí ọ̀rọ̀ bá dé Ejibiti, wọn yóò wà ní ìpayínkeke nípa ìròyìn láti Tire.
6 Goe you ouer to Tarshish: howle, yee that dwell in the yles.
Kọjá wá sí Tarṣiṣi; pohùnréré, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù.
7 Is not this that your glorious citie? her antiquitie is of ancient daies: her owne feete shall leade her afarre off to be a soiourner.
Ǹjẹ́ èyí náà ni ìlú àríyá yín, ògbólógbòó ìlú náà, èyí tí ẹsẹ̀ rẹ̀ ti sìn ín lọ láti lọ tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí ó jìnnà réré.
8 Who hath decreed this against Tyrus (that crowneth men) whose marchantes are princes? whose chapmen are the nobles of the worlde?
Ta ló gbèrò èyí sí Tire, ìlú aládé, àwọn oníṣòwò ẹni tí ó jẹ́ ọmọ-aládé tí àwọn oníṣòwò wọ́n jẹ́ ìlúmọ̀míká ní orílẹ̀ ayé?
9 The Lord of hostes hath decreed this, to staine the pride of all glorie, and to bring to contempt all them that be glorious in the earth.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti ṣètò rẹ̀, láti tẹrí ìgbéraga àti ògo rẹ ba àti láti rẹ gbogbo àwọn ọlọ́lá ilé ayé sílẹ̀.
10 Passe through thy lande like a flood to the daughter of Tarshish: there is no more strength.
Tu ilẹ̀ rẹ gẹ́gẹ́ bí i ti ipadò odò Ejibiti, ìwọ ọmọbìnrin Tarṣiṣi, nítorí ìwọ kò ní èbúté mọ́.
11 He stretched out his hand vpon the sea: he shooke the kingdomes: the Lord hath giuen a commandement concerning the place of marchandise, to destroy the power thereof.
Olúwa ti na ọwọ́ rẹ̀ jáde sí orí Òkun ó sì mú kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì. Ó ti pa àṣẹ kan tí ó kan Kenaani pé kí a pa ilé ààbò rẹ̀ run.
12 And he saide, Thou shalt no more reioyce when thou art oppressed: O virgin daughter of Zidon: rise vp, goe ouer vnto Chittim: yet there thou shalt haue no rest.
Ó wí pé, “Kò sí àríyá fún ọ mọ́, ìwọ wúńdíá ti Sidoni, tí a ti tẹ̀ mọ́lẹ̀ báyìí! “Gbéra, rékọjá lọ sí Saipurọsi, níbẹ̀ pẹ̀lú o kì yóò ní ìsinmi.”
13 Behold the lande of the Caldeans: this was no people: Asshur founded it by the inhabitantes of the wildernesse: they set vp the towers thereof: they raised the palaces thereof and hee brought it to ruine.
Bojú wo ilẹ̀ àwọn ará Babeli, àwọn ènìyàn tí kò jámọ́ nǹkan kan báyìí. Àwọn Asiria ti sọ ọ́ di ibùgbé àwọn ohun ẹranko aginjù; wọn ti gbé ilé ìṣọ́ ìtẹ̀gùn wọn sókè, wọ́n ti tú odi rẹ̀ sí ìhòhò wọ́n sì ti sọ ọ́ di ààtàn.
14 Howle yee shippes of Tarshish, for your strength is destroyed.
Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi; wọ́n ti pa odi rẹ̀ run!
15 And in that day shall Tyrus bee forgotten seuentie yeeres, (according to the yeeres of one King) at the ende of seuentie yeeres shall Tyrus sing as an harlot.
Ní àkókò náà a ó gbàgbé Tire fún àádọ́rin ọdún, ọjọ́ ayé ọba kan. Ṣùgbọ́n ní òpin àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, yóò ṣẹlẹ̀ sí Tire gẹ́gẹ́ bí orin àgbèrè:
16 Take an harpe and go about the citie: (thou harlot thou hast beene forgotten) make sweete melodie, sing moe songes that thou maiest be remembred.
“Mú dùùrù kan, rìn kọjá láàrín ìlú, ìwọ àgbèrè tí a ti gbàgbé; lu dùùrù dáradára, kọ ọ̀pọ̀ orin, kí a lè ba à rántí rẹ.”
17 And at the ende of seuentie yeres shall the Lord visite Tyrus, and shee shall returne to her wages, and shall commit fornication with all the kingdomes of the earth, that are in the world.
Ní òpin àádọ́rin ọdún náà, Olúwa yóò bá Tire jà. Òun yóò sì padà sí àyálò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí panṣágà, yóò sì máa ṣe òwò rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ ọba tí ó wà ní ilẹ̀ ayé.
18 Yet her occupying and her wages shall bee holy vnto the Lord: it shall not be laied vp nor kept in store, but her marchandise shalbe for them that dwell before the Lord, to eate sufficiently, and to haue durable clothing.
Síbẹ̀síbẹ̀ èrè rẹ̀ àti owó iṣẹ́ rẹ̀ ni a ó yà sọ́tọ̀ fún Olúwa; a kò ní kó wọn pamọ́ tàbí kí a há wọn mọ́wọ́. Ère rẹ̀ ni a ó fi fún àwọn tí ó ń gbé níwájú Olúwa, fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ àti aṣọ.