< Genesis 16 >

1 Nowe Sarai Abrams wife bare him no children, and she had a maide an Egyptian, Hagar by name.
Sarai, aya Abramu kò bímọ fún un, ṣùgbọ́n ó ní ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin ará Ejibiti kan tí ń jẹ́ Hagari.
2 And Sarai said vnto Abram, Beholde now, the Lord hath restrained me from childe bearing. I pray thee goe in vnto my maide: it may be that I shall receiue a childe by her. And Abram obeyed the voyce of Sarai.
Nítorí náà, Sarai wí fún Abramu pé, “Kíyèsi i Olúwa ti sé mi ní inú, èmi kò sì bímọ, wọlé tọ ọmọ ọ̀dọ̀ mi lọ, bóyá èmi yóò le ti ipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.” Abramu sì gba ohun tí Sarai sọ.
3 Then Sarai Abrams wife tooke Hagar her maide the Egyptian, after Abram had dwelled ten yeere in the land of Canaan, and gaue her to her husband Abram for his wife.
Lẹ́yìn ọdún mẹ́wàá tí Abramu ti ń gbé ni Kenaani ni Sarai mú ọmọbìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Hagari, tí í ṣe ará Ejibiti fún Abramu ọkọ rẹ̀ láti fi ṣe aya.
4 And he went in vnto Hagar, and she conceiued. and when she sawe that she had conceiued, her dame was despised in her eyes.
Abramu sì bá Hagari lòpọ̀, ó sì lóyún. Nígbà tí ó sì ti mọ̀ pé òun lóyún, ó bẹ̀rẹ̀ sì ní kẹ́gàn ọ̀gá rẹ̀.
5 Then Sarai saide to Abram, Thou doest me wrong. I haue giuen my maide into thy bosome, and she seeth that she hath conceiued, and I am despised in her eyes: the Lord iudge betweene me and thee.
Nígbà náà ni Sarai wí fún Abramu pé, “Ìwọ ni ó jẹ́ kí ẹ̀gbin yìí máa jẹ mí, mo fa ọmọ ọ̀dọ̀ mi lé ọ lọ́wọ́, nígbà tí ó sì rí i pé òun lóyún, mo di ẹni ẹ̀gàn ní ojú rẹ̀. Kí Olúwa kí ó ṣe ìdájọ́ láàrín tèmi tìrẹ.”
6 Then Abram saide to Sarai, Beholde, thy maide is in thine hand: doe with her as it pleaseth thee. Then Sarai dealt roughly with her: wherefore she fled from her.
Abramu dáhùn pé, “Ìwọ ló ni ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣe ohunkóhun tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ sí i.” Nígbà náà ni Sarai fi ìyà jẹ Hagari, ó sì sálọ.
7 But the Angel of the Lord founde her beside a fountaine of water in the wildernesse by the fountaine in the way to Shur,
Angẹli Olúwa sì rí Hagari ní ẹ̀gbẹ́ ìsun omi ní ijù, ìsun omi tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà tí ó lọ sí Ṣuri.
8 And he saide, Hagar Sarais maide, whence commest thou? and whither wilt thou goe? And she said, I flie from my dame Sarai.
Ó sì wí pé, “Hagari, ìránṣẹ́ Sarai, níbo ni o ti ń bọ̀, níbo sì ni ìwọ ń lọ?” Ó sì dáhùn pé, “Mo ń sálọ kúrò lọ́dọ̀ ọ̀gá mi Sarai ni.”
9 Then the Angel of the Lord saide to her, Returne to thy dame, and humble thy selfe vnder her hands.
Angẹli Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ kí o sì tẹríba fún un.”
10 Againe the Angel of the Lord saide vnto her, I will so greatly increase thy seede, that it shall not be numbred for multitude.
Angẹli Olúwa náà sì fi kún fún un pé, “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, ìran rẹ kì yóò sì lóǹkà.”
11 Also the Angel of the Lord said vnto her, See, thou art with childe, and shalt beare a sonne, and shalt call his name Ishmael: for the Lord hath heard thy tribulation.
Angẹli Olúwa náà sì wí fún un pé, “Ìwọ ti lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli, nítorí tí Olúwa ti rí ìpọ́njú rẹ.
12 And he shalbe a wilde man: his hande shall be against euery man, and euery mans hand against him. and he shall dwell in the presence of all his brethren.
Òun yóò jẹ́ oníjàgídíjàgan ènìyàn ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára ènìyàn gbogbo, ọwọ́ ènìyàn gbogbo yóò sì wà lára rẹ̀, yóò sì máa gbé ní ìkanra pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀.”
13 Then she called the name of the Lord, that spake vnto her, Thou God lookest on me: for she said, Haue I not also here looked after him that seeth me?
Ó sì pe orúkọ Olúwa tí o bá sọ̀rọ̀ ní, “Ìwọ ni Ọlọ́run tí ó rí mi,” nítorí tí ó wí pé, “Mo ti ri ẹni tí ó rí mi báyìí.”
14 Wherefore the well was called, Beerlahai-roi. lo, it is betweene Kadesh and Bered.
Nítorí náà ni a ṣe ń pe kànga náà ní Beeri-Lahai-Roi; kànga ẹni alààyè tí ó rí mi. Ó wà ní agbede-méjì Kadeṣi àti Beredi.
15 And Hagar bare Abram a sonne, and Abram called his sonnes name, which Hagar bare, Ishmael.
Hagari sì bí ọmọkùnrin kan fún Abramu, Abramu sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli.
16 And Abram was foure score and sixe yeere olde, when Hagar bare him Ishmael.
Abramu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínláàádọ́rùn-ún nígbà tí Hagari bí Iṣmaeli fún un.

< Genesis 16 >