< Ezekiel 7 >

1 Moreover the word of the Lord came vnto me, saying,
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Also thou sonne of man, thus saith the Lord God, An ende is come vnto the lande of Israel: the ende is come vpon the foure corners of the lande.
“Ọmọ ènìyàn, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ilé Israẹli: “‘Òpin! Òpin ti dé sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ náà!
3 Nowe is the ende come vpon thee, and I wil sende my wrath vpon thee, and will iudge thee according to thy wayes, and will laye vpon thee all thine abominations.
Òpin tí dé sí ọ báyìí, èmi yóò sì tú ìbínú mi jáde sí ọ, èmi yóò dájọ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ, èmi yóò sì san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìwà ìríra rẹ.
4 Neither shall mine eye spare thee, neither will I haue pitie: but I will laye thy waies vpon thee: and thine abomination shall bee in the middes of thee, and yee shall knowe that I am the Lord.
Ojú mi kò ní i dá ọ sì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú; ṣùgbọ́n èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gbogbo ìwà ìríra tó wà láàrín rẹ. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
5 Thus saith the Lord God, Beholde, one euil, euen one euill is come.
“Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ibi! Ibi kan ṣoṣo. Kíyèsi, ó bọ̀ ní orí rẹ!
6 An ende is come, the end is come, it watched for thee: beholde, it is come.
Òpin ti dé! Òpin ti dé! Ó ti dìde lòdì sí ọ. Kíyèsi, ó ti dé!
7 The morning is come vnto thee, that dwellest in the lande: the time is come, the day of trouble is neere, and not the sounding againe of the mountaines.
Ìparun ti dé sórí rẹ, ìwọ tó ń gbé ní ilẹ̀ náà. Àkókò náà dé! Ọjọ́ wàhálà ti súnmọ́ etílé! Kì í ṣe ọjọ́ ariwo ayọ̀ lórí òkè.
8 Now I will shortly powre out my wrath vpon thee, and fulfil mine anger vpon thee: I will iudge thee according to thy wayes, and will lay vpon thee all thine abominations.
Mo ṣetán láti tú ìbínú gbígbóná mi lé ọ lórí àti láti lo ìbínú mi lórí rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà rẹ, èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gẹ́gẹ́ bí ìwà ìríra rẹ ni èmi yóò sì san án fún ọ.
9 Neither shall mine eie spare thee, neither will I haue pitie, but I will laye vpon thee according to thy wayes, and thine abominations shalbe in the middes of thee, and ye shall knowe that I am the Lord that smiteth.
Ojú mi kò ní i dá ọ sí, Èmi kò sì ní wò ọ́ pẹ̀lú àánú; èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti fún gbogbo ìwà ìríra tí wà láàrín rẹ. “‘Nígbà náà ní ẹ o mọ̀ pé Èmi Olúwa lo kọlù yín.
10 Beholde, the day, beholde, it is come: the morning is gone forth, the rod florisheth: pride hath budded.
“‘Ọjọ́ náà dé! Kíyèsi ó ti dé! Ìparun ti bú jáde, ọ̀pá ti tanná, ìgbéraga ti rúdí!
11 Crueltie is risen vp into a rod of wickednes: none of them shall remaine, nor of their riches, nor of any of theirs, neither shall there bee lamentation for them.
Ìwà ipá ti di ọ̀pá ìwà búburú; ọ̀pá láti jẹ ẹni búburú ní ìyà. Kò sí nínú wọn tí yóò ṣẹ́kù, tàbí nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn, kò sí nínú ọrọ̀ wọn, kò sí ohun tí ó ní iye.
12 The time is come, the day draweth neere: let not the byer reioyce, nor let him that selleth, mourne: for the wrath is vpon al the multitude thereof.
Àkókò náà dé! Ọjọ́ náà ti dé! Kí òǹrajà má ṣe yọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ki òǹtajà má ṣe ṣọ̀fọ̀; nítorí, ìbínú gbígbóná wà lórí gbogbo ènìyàn.
13 For hee that selleth, shall not returne to that which is solde, although they were yet aliue: for the vision was vnto al the multitude thereof, and they returned not, neither doeth any encourage himselfe in the punishment of his life.
Nítorí pé òǹtajà kì yóò rí gbà padà dúkìá èyí tó tà níwọ̀n ìgbà ti àwọn méjèèjì bá wà láààyè. Nítorí ìran tó kan gbogbo ènìyàn yìí kò ní yí padà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, kò sí ọ̀kan nínú wọn tí yóò gba ara rẹ̀ là.
14 They haue blowen the trumpet, and prepared all, but none goeth to the battel: for my wrath is vpon all the multitude thereof.
“‘Wọ́n ti fọn ìpè ogun, tí wọ́n sì pèsè ohun gbogbo sílẹ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò lọ ojú ogun, nítorí ìbínú gbígbóná mi ti wà lórí gbogbo ènìyàn.
15 The sword is without, and the pestilence, and the famine within: he that is in the field, shall dye with the sword, and he that is in the citie, famine and pestilence shall deuoure him.
Idà wà ní ìta, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn wà nílé, idà yóò pa ẹni tó bá wà ní orílẹ̀-èdè, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn yóò pa ẹni tó bá wà ní ìlú.
16 But they that flee away from them, shall escape, and shalbe in the mountaines, like the doues of the valleis: all they shall mourne, euery one for his iniquitie.
Gbogbo àwọn tí ó bọ́ nínú wọn yóò sálà, wọn yóò sì wà lórí òkè. Bí i àdàbà inú àfonífojì, gbogbo wọn yóò máa ṣọ̀fọ̀, olúkúlùkù nítorí àìṣedéédéé rẹ̀.
17 All handes shalbe weake, and all knees shall fall away as water.
Gbogbo ọwọ́ yóò rọ, gbogbo orúnkún yóò di aláìlágbára bí omi.
18 They shall also girde them selues with sackecloth, and feare shall couer them, and shame shalbe vpon all faces, and baldnes vpon their heads.
Wọn yóò wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ẹ̀rù yóò sì bò wọ́n mọ́lẹ̀, ìtìjú yóò mù wọn, wọn yóò sì fá irun wọn.
19 They shall cast their siluer in the streetes, and their golde shalbe cast farre off: their siluer and their gold can not deliuer them in the day of the wrath of the Lord: they shall not satisfie their soules, neither fill their bowels: for this ruine is for their iniquitie.
“‘Wọn yóò dà fàdákà wọn sí ojú pópó, wúrà wọn yóò sì dàbí èérí fàdákà àti wúrà wọn kò ní le gbà wọ́n ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná Olúwa. Wọn kò ní le jẹun tẹ́ ra wọn lọ́rùn tàbí kí wọn kún ikùn wọn pẹ̀lú oúnjẹ nítorí pé ó ti di ohun ìkọ̀sẹ̀ fún wọn.
20 He had also set the beautie of his ornament in maiestie: but they made images of their abominations, and of their idoles therein: therefore haue I set it farre from them.
Wọ́n ń ṣe ìgbéraga pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ wọn tí ó lẹ́wà, wọn sì ti fi ṣe òrìṣà, wọn sì tún ya àwòrán ìríra wọn níbẹ̀. Nítorí náà, èmi yóò sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí di aláìmọ́ fún wọn.
21 And I will giue it into the handes of the strangers to be spoyled, and to the wicked of the earth to be robbed, and they shall pollute it.
Èmi yóò sì fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe ìjẹ fún àjèjì àti ìkógun fún àwọn ènìyàn búburú ayé, wọn yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́.
22 My face will I turne also from them, and they shall pollute my secret place: for the destroyers shall enter into it, and defile it.
Èmi yóò gbójú mi kúrò lára wọn, àwọn ọlọ́ṣà yóò sì sọ ibi ìṣúra mi di aláìmọ́; àwọn ọlọ́ṣà yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sì bà á jẹ́.
23 Make a chaine: for the lande is full of the iudgement of blood, and the citie is full of crueltie.
“‘Rọ ẹ̀wọ̀n irin! Nítorí pé ilẹ̀ náà kún fún ẹ̀ṣẹ̀ ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìlú náà sí kún fún ìwà ipá.
24 Wherefore I will bring the most wicked of the heathen, and they shall possesse their houses: I will also make the pompe of the mightie to cease, and their holie places shalbe defiled.
Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè ti ó búburú jùlọ láti jogún ilé wọn. Èmi yóò sì fi òpin sí ìgbéraga àwọn alágbára, ibi mímọ́ wọn yóò sì di bíbàjẹ́.
25 When destruction commeth, they shall seeke peace, and shall not haue it.
Nígbà tí ìpayà bá dé, wọn yóò wá àlàáfíà, lórí asán.
26 Calamitie shall come vpon calamitie, and rumour shall bee vpon rumour: then shall they seeke a vision of the Prophet: but the Lawe shall perish from the Priest, and counsel from the Ancient.
Wàhálà lórí wàhálà yóò dé, ìdágìrì lórí ìdágìrì. Nígbà náà ni wọn yóò wá ìran lọ́dọ̀ wòlíì, ṣùgbọ́n ẹ̀kọ́ òfin yóò parun lọ́dọ̀ àlùfáà, bẹ́ẹ̀ ni ìmọ̀ràn yóò ṣègbé lọ́dọ̀ àwọn àgbàgbà.
27 The King shall mourne, and the prince shall be clothed with desolation, and the handes of the people in the land shall be troubled: I wil doe vnto them according to their waies, and according to their iudgements will I iudge them, and they shall knowe that I am the Lord.
Ọba yóò ṣọ̀fọ̀, ọmọ-aládé yóò wà láìní ìrètí, ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yóò wárìrì. Èmi yóò ṣe é fún wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, èmi yóò ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìgbékalẹ̀ wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa.’”

< Ezekiel 7 >