< Ezekiel 6 >

1 Again the worde of the Lord came vnto me, saying,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
2 Sonne of man, Set thy face towardes the mountaines of Israel, and prophecie against them,
“Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
3 And say, Ye mountaines of Israel, heare the worde of the Lord God: thus sayth the Lord God to the mountaines and to the hilles, to the riuers and to the valleis, Beholde, I, euen I will bring a sworde vpon you, and I will destroy your hie places:
wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
4 And your altars shalbe desolate, and your images of the sunne shalbe broken: and I will cast downe your slaine men before your idoles.
Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
5 And I will lay the dead carkeises of the children of Israel before their idoles, and I will scatter your bones round about your altars.
Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
6 In all your dwelling places the cities shalbe desolate, and the hie places shalbe laide waste, so that your altars shalbe made waste and desolate, and your idoles shalbe broken, and cease, and your images of the sunne shalbe cut in pieces, and your workes shalbe abolished.
Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
7 And the slaine shall fall in the middes of you, and ye shall knowe that I am the Lord.
Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
8 Yet will I leaue a remnant, that you may haue some that shall escape the sword among the nations, when you shalbe scattred through the countreyes.
“‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
9 And they that escape of you, shall remember me among the nations, where they shalbe in captiuitie, because I am grieued for their whorish hearts, which haue departed from mee, and for their eyes, which haue gone a whoring after their idoles, and they shalbe displeased in them selues for the euils, which they haue committed in all their abominations.
Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
10 And they shall knowe that I am the Lord, and that I haue not saide in vaine, that I woulde doe this euill vnto them.
Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
11 Thus saith the Lord God, Smite with thine hand, and stretch forth with thy foote, and say, Alas, for all the wicked abominations of the house of Israel: for they shall fall by the sworde, by the famine, and by the pestilence.
“‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
12 He that is farre off, shall dye of the pestilence, and he that is neere, shall fall by the sword, and hee that remaineth and is besieged, shall dye by the famine: thus will I accomplish my wrath vpon them.
Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
13 Then ye shall knowe, that I am ye Lord, when their slaine men shalbe among their idoles round about their altars, vpon euerie hie hill in al the toppes of the mountaines, and vnder euery greene tree, and vnder euerie thicke oke, which is the place where they did offer sweete sauour to all their idoles.
Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
14 So will I stretch mine hand vpon them, and make the lande waste, and desolate from the wildernes vnto Diblath in all their habitations, and they shall know, that I am the Lord.
Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”

< Ezekiel 6 >