< Ezekiel 3 >

1 Moreover he saide vnto me, Sonne of man, eate that thou findest: eate this roule, and goe, and speake vnto the house of Israel.
Síwájú sí i, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ohun tí ó wà níwájú rẹ, jẹ ìwé kíká yìí; kí o sì lọ fi bá ilé Israẹli sọ̀rọ̀.”
2 So I opened my mouth, and he gaue mee this roule to eate.
Mo sì ya ẹnu mi, ó sì mú mi jẹ ìwé kíká náà.
3 And he said vnto me, Sonne of man, cause thy belly to eate, and fill thy bowels with this roule that I giue thee. Then did I eate it, and it was in my mouth as sweete as honie.
Ó tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ìwé kíká tí mo fún ọ yìí, fi bọ́ inú àti ikùn rẹ.” Nígbà náà ni mo jẹ ẹ́, dídùn rẹ̀ dàbí oyin ní ẹnu mi.
4 And he said vnto me, Sonne of man, goe, and enter into the house of Israel, and declare them my wordes.
Ó sì tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, lọ ni ìsinsin yìí bá mi sọ ọ̀rọ̀ mi fún ilé Israẹli.
5 For thou art not sent to a people of an vnknowen tongue, or of an hard language, but to the house of Israel,
A kò rán ọ sí àwọn tó ń sọ èdè àjèjì tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè Israẹli ni mo rán ọ sí
6 Not to many people of an vnknowen tongue, or of an harde language, whose wordes thou canst not vnderstand: yet if I should sende thee to them, they would obey thee.
kì í ṣe sí ọ̀pọ̀ ènìyàn tó ń sọ àjèjì èdè tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, àwọn tí ọ̀rọ̀ wọn le fún ọ láti gbọ́ yé. Dájúdájú bí mo bá rán ọ sí wọn, wọn ìbá sì fetísílẹ̀ sí ọ.
7 But the house of Israel will not obey thee: for they will not obey me: yea, all the house of Israel are impudent and stiffe hearted.
Ṣùgbọ́n ilé Israẹli kò fẹ́ gbọ́ tìrẹ nítorí pé wọn kò fẹ́ láti gbọ́ tèmi, torí pé aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle ni gbogbo ilé Israẹli.
8 Beholde, I haue made thy face strong against their faces, and thy forehead harde against their foreheads.
Ṣùgbọ́n bí i tiwọn lèmi náà yóò ṣe jẹ́ kí ojú àti ọkàn rẹ le.
9 I haue made thy forehead as the adamant, and harder then the flint: feare them not therefore, neither be afraid at their lookes: for they are a rebellious house.
Èmi yóò ṣe iwájú orí rẹ bí òkúta tó le jùlọ, ànító le ju òkúta-ìbọn lọ. Má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí jẹ́ kí wọn ó dáyà já ọ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdílé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.”
10 He said moreouer vnto me, Sonne of man, receiue in thine heart al my words that I speake vnto thee, and heare them with thine eares,
Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, kí o sì gba gbogbo ọ̀rọ̀ yìí sí ọkàn rẹ.
11 And goe and enter to them that are led away captiues vnto the children of thy people, and speake vnto them, and tell them, Thus saith the Lord God: but surely they will not heare, neither will they in deede cease.
Lọ nísinsin yìí sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ tó wà ní ìgbèkùn. Sọ fún wọn pé báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí yálà wọ́n gbọ́ tàbí wọn kò gbọ́.”
12 Then the spirite tooke me vp, and I heard behinde me a noise of a great russhing, saying, Blessed be ye glorie of the Lord out of his place.
Nígbà náà ni ẹ̀mí gbé mi sókè, mo sì gbọ́ ohùn ìró ńlá lẹ́yìn mi tó sọ pé, kí a gbé ògo Olúwa ga láti ibùgbé rẹ̀ wá!
13 I heard also the noyse of the wings of the beasts, that touched one another, and the ratling of the wheeles that were by them, euen a noyse of a great russhing.
Bẹ́ẹ̀ ni mo tún gbọ́ ariwo ìyẹ́ apá àti kẹ̀kẹ́ àwọn ẹ̀dá alààyè náà pẹ̀lú ariwo tó dàbí àrá ńlá.
14 So the spirit lift me vp, and tooke me away and I went in bitternesse, and indignation of my spirite, but the hand of the Lord was strong vpon me.
Ẹ̀mí náà sì gbé mi sókè, ó sì mú mi lọ, mo lọ pẹ̀lú ọkàn kíkorò àti ìbínú nínú ẹ̀mí mi, pẹ̀lú ọwọ́ líle Olúwa ni ara mi.
15 Then I came to them that were led away captiues to Tel-abib, that dwelt by the riuer Chebar, and I sate where they sate, and remained there astonished among them seuen dayes.
Nígbà náà ni mo lọ sí etí odò Kebari níbi tí àwọn ìgbèkùn ń gbé ni Teli-Abibu. Níbẹ̀ níbi tí wọ́n ń gbé, mo jókòó láàrín wọn pẹ̀lú ìyanu, fún ọjọ́ méje.
16 And at the ende of seuen dayes, the worde of the Lord came againe vnto me, saying,
Lẹ́yìn ọjọ́ méje, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
17 Sonne of man, I haue made thee a watchman vnto the house of Israel: therefore heare the worde at my mouth, and giue them warning from me.
“Ọmọ ènìyàn, mo ti fi ọ́ ṣe olùṣọ́ fún ilé Israẹli; nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, fún wọn ní ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.
18 When I shall say vnto the wicked, Thou shalt surely die, and thou giuest not him warning, nor speakest to admonish the wicked of his wicked way, that he may liue, the same wicked man shall die in his iniquitie: but his blood will I require at thine hande.
Bí mo bá sọ fún ènìyàn búburú pé, dájúdájú, ‘Ìwọ yóò kú,’ tí ìwọ kò sì kìlọ̀ fún ènìyàn búburú yìí láti dáwọ́ ìwà ibi rẹ̀ dúró, kí o sì gba ẹ̀mí rẹ̀ là, ènìyàn búburú náà yóò kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
19 Yet if thou warne the wicked, and he turne not from his wickednesse, nor from his wicked way, he shall die in his iniquitie, but thou hast deliuered thy soule.
Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún ènìyàn búburú, tí ó kọ̀ tí kò fi ìwà búburú rẹ̀ sílẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ṣùgbọ́n ọrùn tìrẹ ti mọ́.
20 Likewise if a righteous man turne from his righteousnesse, and commit iniquitie, I will lay a stumbling blocke before him, and he shall die, because thou hast not giuen him warning: he shall die in his sinne, and his righteous deedes, which he hath done, shall not be remembred: but his blood will I require at thine hand.
“Bákan náà, bí olódodo kan bá yípadà, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àìṣòdodo, tí mo sì fi ohun ìkọ̀sẹ̀ sí ọ̀nà rẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Nítorí pé ìwọ kọ̀ láti kìlọ̀ fún un, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, a ó gbàgbé gbogbo ìwà rere tó ti hù tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
21 Neuerthelesse, if thou admonish that righteous man, that the righteous sinne not, and that he doeth not sinne, he shall liue because he is admonished: also thou hast deliuered thy soule.
Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún olódodo tó sì dáwọ́ ìwà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ dúró, dájúdájú òun yóò yè nítorí pé ó ti gba ìkìlọ̀, ọrùn tìrẹ sì mọ́.”
22 And the hande of the Lord was there vpon me, and he said vnto me, Arise, and goe into the fielde, and I will there talke with thee.
Ọwọ́ Olúwa wà lára mi níbẹ̀, ó sì wí fún mi pé, “Dìde, lọ sí ibi tí ó tẹ́jú, èmi yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ níbẹ̀.”
23 So when I had risen vp, and gone foorth into the fielde, beholde, the glorie of the Lord stoode there, as the glorie which I sawe by the riuer Chebar, and I fell downe vpon my face.
Mo sì dìde, mo lọ sí ibi tí ó tẹ́jú. Ògo Olúwa dúró níbẹ̀, ó dàbí irú ògo tí mo rí létí odò Kebari, mo sì dojúbolẹ̀.
24 Then the Spirit entred into me, which set me vp vpon my feete, and spake vnto me, and said to me, Come, and shut thy selfe within thine house.
Nígbà náà ni Ẹ̀mí wọ inú mi, tí ó sì tún gbé mi dúró. Ó sì wí fún mi pé, “Lọ, ti ara rẹ mọ́ inú ilé rẹ
25 But thou, O sonne of man, beholde, they shall put bandes vpon thee, and shall binde thee with them, and thou shalt not goe out among them.
ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, wọn yóò fi okùn dè ọ́ mọ́lẹ̀; dé ibi pé ìwọ kò ní í le rìn káàkiri láàrín àwọn ènìyàn.
26 And I will make thy tongue cleaue to the roofe of thy mouth, that thou shalt be dume, and shalt not be to them as a man that rebuketh: for they are a rebellious house.
Èmi yóò mú kí ahọ́n rẹ lẹ̀ mọ́ àjà ẹnu rẹ, tó bẹ́ẹ̀ ti ìwọ yóò wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́. Ìwọ kò sì ní lè bá wọn wí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ní wọn.
27 But when I shall haue spoken vnto thee, I will open thy mouth, and thou shalt say vnto them, Thus saith the Lord God, He that heareth, let him heare, and he that leaueth off, let him leaue: for they are a rebellious house.
Ṣùgbọ́n nígbà tí èmi bá bá ọ sọ̀rọ̀, Èmi yóò ṣí ọ lẹ́nu, ìwọ yóò sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’ Ẹni tó bá fẹ́ kí ó gbọ́, ẹni tó bá fẹ́ kọ̀, kó kọ̀ nítorí ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.

< Ezekiel 3 >