< Ezekiel 24 >

1 Again in the ninth yeere, in the tenth moneth, in the tenth day of the moneth, came the worde of the Lord vnto me, saying,
Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Sonne of man, write thee the name of the day, euen of this same day: for the King of Babel set himselfe against Ierusalem this same day.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an.
3 Therefore speake a parable vnto the rebellious house, and say vnto them, Thus sayth the Lord God, Prepare a pot, prepare it, and also powre water into it.
Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná, gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
4 Gather the pieces thereof into it, euen euery good piece, as the thigh and the shoulder, and fill it with the chiefe bones.
Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀, gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá. Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀,
5 Take one of the best sheepe, and burne also the bones vnder it, and make it boyle well, and seethe the bones of it therein,
mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran. Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀; sì jẹ́ kí ó hó dáradára sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.
6 Because the Lord God sayth thus, Woe to the bloody citie, euen to the pot, whose skomme is therein, and whose skomme is not gone out of it: bring it out piece by piece: let no lot fall vpon it.
Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà, fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀, tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀! Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí má ṣe ṣà wọ́n mú.
7 For her blood is in the middes of her: shee set it vpon an high rocke, and powred it not vpon on the ground to couer it with dust,
“‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀; à á sí orí àpáta kan lásán kò dà á sí orí ilẹ̀, níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó.
8 That it might cause wrath to arise, and take vengeance: euen I haue set her blood vpon an high rocke that it should not be couered.
Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán, kí o ma bà á wà ni bíbò.
9 Therefore thus saith ye Lord God, Woe to the bloody citie, for I will make ye burning great.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà! Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
10 Heape on much wood: kindle the fire, consume the flesh, and cast in spice, and let the bones be burnt.
Nítorí náà kó igi náà jọ sí i, kí o sì fi iná sí i. Ṣe ẹran náà dáradára, fi tùràrí dùn ún; kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
11 Then set it emptie vpon the coles thereof, that the brasse of it may be hot, and may burne, and that the filthinesse of it may be molten in it, and that the skomme of it may be consumed.
Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀ kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
12 She hath wearied her selfe with lyes, and her great skomme went not out of her: therefore her skomme shall be consumed with fire.
Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ: èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀, èérí náà gan an yóò wà nínú iná.
13 Thou remainest in thy filthines and wickednes: because I would haue purged thee, and thou wast not purged, thou shalt not be purged from thy filthines, till I haue caused my wrath to light vpon thee.
“‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.
14 I the Lord haue spoken it: it shall come to passe, and I will doe it: I will not goe backe, neither will I spare, neither will I repent: according to thy wayes, and according to thy workes shall they iudge thee, sayeth the Lord God.
“‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 Also the worde of ye Lord came vnto me, saying,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé:
16 Sonne of man beholde, I take away from thee the pleasure of thine eyes with a plague: yet shalt thou neither mourne nor weepe, neither shall thy teares runne downe.
“Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀.
17 Cease from sighing: make no mourning for the dead, and binde the tyre of thine head vpon thee, and put on thy shooes vpon thy feete, and couer not thy lips, and eate not the bread of men.
Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ, má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”
18 So I spake vnto the people in the morning, and at euen my wife dyed: and I did in the morning, as I was commanded.
Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.
19 And the people said vnto me, Wilt thou not tell vs what these things meane towarde vs that thou doest so?
Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”
20 Then I answered them, The worde of the Lord came vnto me, saying,
Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
21 Speake vnto the house of Israel, Thus sayth the Lord God, Behold, I will pollute my Sanctuarie, euen the pride of your power, the pleasure of your eyes, and your hearts desire, and your sonnes, and your daughters whom ye haue left, shall fall by the sworde.
Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà.
22 And ye shall doe as I haue done: ye shall not couer your lippes, neither shall ye eate the bread of men.
Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.
23 And your tyre shalbe vpon your heads, and your shooes vpon your feete: ye shall not mourne nor weepe, but ye shall pine away for your iniquities, and mourne one toward another.
Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín.
24 Thus Ezekiel is vnto you a signe: according to all that he hath done, ye shall do: and when this commeth, ye shall know that I am the Lord God.
Esekiẹli yóò jẹ àmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’
25 Also, thou sonne of man, shall it not be in the day when I take from them their power, ye ioy of their honor, ye pleasure of their eyes, and the desire of their heart, their sonnes and their daughters?
“Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn,
26 That he that escapeth in that day, shall come vnto thee to tell thee that which hee hath heard with his eares?
ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ.
27 In that day shall thy mouth be opened to him which is escaped, and thou shalt speake, and be no more dumme, and thou shalt be a signe vnto them, and they shall knowe that I am the Lord.
Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ àmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”

< Ezekiel 24 >