< Exodus 6 >

1 Then the Lord sayd vnto Moses, Nowe shalt thou see, what I will doe vnto Pharaoh: for by a strong hand shall he let them goe, and euen be constrained to driue them out of his land.
Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
2 Moreouer God spake vnto Moses, and sayd vnto him, I am the Lord,
Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa.
3 And I appeared vnto Abraham, to Izhak, and to Iaakob by the Name of Almightie God: but by my Name Iehouah was I not knowen vnto the.
Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára, ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara mi hàn wọ́n.
4 Furthermore as I made my couenant with them to giue them ye land of Canaan, the land of their pilgrimage, wherein they were strangers:
Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì.
5 So I haue also hearde the groning of the children of Israel, whom the Egyptians keepe in bondage, and haue remembred my couenant.
Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú mi.
6 Wherefore say thou vnto the children of Israel, I am the Lord, and I will bring you out from the burdens of the Egyptians, and will deliuer you out of their bondage, and will redeeme you in a stretched out arme, and in great iudgements.
“Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli, ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá.
7 Also I will take you for my people, and will be your God: then ye shall knowe that I the Lord your God bring you out from the burdens of the Egyptians.
Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti.
8 And I will bring you into the land which I sware that I woulde giue to Abraham, to Izhak, and to Iaakob, and I will giue it vnto you for a possession: I am the Lord.
Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’”
9 So Moses told the children of Israel thus: but they hearkened not vnto Moses, for anguish of spirit and for cruel bondage.
Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.
10 Then the Lord spake vnto Moses, saying,
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose.
11 Go speak to Pharaoh King of Egypt, that he let the children of Israel goe out of his land.
“Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
12 But Moses spake before the Lord, saying, Beholde, the children of Israel hearken not vnto me, howe then shall Pharaoh heare mee, which am of vncircumcised lippes?
Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”
13 Then the Lord spake vnto Moses and vnto Aaron, and charged them to goe to the children of Israel and to Pharaoh King of Egypt, to bring the children of Israel out of the lande of Egypt.
Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
14 These bee the heades of their fathers houses: the sonnes of Reuben the first borne of Israel are Hanoch and Pallu, Hezron and Carmi: these are ye families of Reuben.
Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn: àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi. Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.
15 Also the sonnes of Simeon: Iemuel and Iamin, and Ohad, and Iachin, and Zoar, and Shaul the sonne of a Canaanitish woman: these are the families of Simeon.
Àwọn ọmọ Simeoni ni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani. Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.
16 These also are the names of the sonnes of Leui in their generations: Gershon and Kohath and Merari (and the yeres of the life of Leui were an hundreth thirtie and seuen yere)
Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn: Gerṣoni, Kohati àti Merari. Lefi lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
17 The sonnes of Gershon were Libni and Shimi by their families.
Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni: Libni àti Ṣimei.
18 And the sonnes of Kohath, Amram and Izhar, and Hebron, and Vzziel. (and Kohath liued an hundreth thirtie and three yeere)
Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli. Kohati lo ẹ̀tàléláádóje ọdún láyé.
19 Also the sonnes of Merari were Mahali and Mushi: these are ye families of Leui by their kinreds.
Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili àti Muṣi. Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.
20 And Amram tooke Iochebed his fathers sister to his wife, and shee bare him Aaron and Moses (and Amram liued an hundreth thirtie and seuen yeere)
Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un. Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
21 Also the sonnes of Izhar: Korah, and Nepheg, and Zichri.
Àwọn ọmọ Isari ni: Kora, Nefegi àti Sikri.
22 And the sonnes of Vzziel: Mishael, and Elzaphan, and Sithri.
Àwọn ọmọ Usieli ni: Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.
23 And Aaron tooke Elisheba daughter of Amminadab, sister of Nahashon to his wife, which bare him Nadab, and Abihu, Eleazar and Ithamar.
Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
24 Also the sonnes of Korah: Assir, and Elkanah, and Abiasaph: these are the families of the Korhites.
Àwọn ọmọ Kora ni: Asiri, Elkana àti Abiasafu. Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.
25 And Eleazar Aarons sonne tooke him one of the daughters of Putiel to his wife, which bare him Phinehas: these are the principall fathers of the Leuites throughout their families.
Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un. Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.
26 These are Aaron and Moses to whom the Lord said, Bring the children of Israel out of the land of Egypt, according to their armies.
Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”
27 These are that Moses and Aaron, which spake to Pharaoh King of Egypt, that they might bring the children of Israel out of Egypt.
Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.
28 And at that time when the Lord spake vnto Moses in the land of Egypt,
Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti,
29 When the Lord, I say, spake vnto Moses, saying, I am the Lord, speake thou vnto Pharaoh the King of Egypt all that I say vnto thee,
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”
30 Then Moses said before the Lord, Behold, I am of vncircumcised lips, and how shall Pharaoh heare me?
Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”

< Exodus 6 >