< Deuteronomy 6 >

1 These now are the commandements, ordinances, and lawes, which the Lord your God commanded me to teach you, that ye might doe them in the land whither ye go to possesse it:
Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí Olúwa Ọlọ́run yín pàṣẹ fún mi láti kọ́ ọ yín kí ẹ lè kíyèsi i, ní ilẹ̀ náà tí ẹ ó ni lẹ́yìn tí ẹ bá kọjá a Jordani.
2 That thou mightest feare the Lord thy God, and keepe all his ordinances, and his commandements which I commaund thee, thou, and thy sonne, and thy sonnes sonne all the dayes of thy life, euen that thy dayes may be prolonged.
Kí ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn, lẹ́yìn wọn bá à lè bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá wà láyé, nípa pípa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ tí mo fún un yín mọ́, kí ẹ bá à lè pẹ́ lórí ilẹ̀.
3 Heare therefore, O Israel, and take heede to doe it, that it may go well with thee, and that ye may increase mightily in the land that floweth with milke and hony, as the Lord God of thy fathers hath promised thee.
Gbọ́ ìwọ Israẹli, kí o sì ṣọ́ra láti gbọ́rọ̀, kí ó bá à lè dára fún ọ, kí o bá à lè gbilẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ní ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba rẹ ti ṣèlérí fún ọ.
4 Heare, O Israel, The Lord our God is Lord onely,
Gbọ́ ìwọ Israẹli, Olúwa Ọlọ́run wa, Olúwa kan ni.
5 And thou shalt loue the Lord thy God with all thine heart, and with all thy soule, and with all thy might.
Fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ.
6 And these wordes which I commaund thee this day, shalbe in thine heart.
Àwọn àṣẹ tí mo fún un yín lónìí gbọdọ̀ máa wà lóókan àyà yín.
7 And thou shalt rehearse them continually vnto thy children, and shalt talke of them when thou tariest in thine house, and as thou walkest by the way, and when thou liest downe, and when thou risest vp:
Ẹ fi kọ́ àwọn ọmọ yín gidigidi. Bí ẹ bá jókòó nínú ilé, ẹ jíròrò nípa wọn, àti nígbà tí ẹ bá ń rìn ní ojú ọ̀nà, bí ẹ bá dùbúlẹ̀ àti nígbà tí ẹ bá dìde.
8 And thou shalt binde them for a signe vpon thine hand, and they shalbe as frontlets betweene thine eyes.
Ẹ so wọ́n sí ọwọ́ yín fún àmì, ẹ so ó mọ́ iwájú orí yín.
9 Also thou shalt write them vpon ye postes of thine house, and vpon thy gates.
Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ.
10 And when the Lord thy God hath brought thee into the land, which he sware vnto thy fathers, Abraham, Izhak, and Iaakob, to giue to thee, with great and goodly cities which thou buildedst not,
Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá mú yín dé ilẹ̀ náà tí ó ti búra fún àwọn baba yín, fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu láti fi fún un yín, ilẹ̀ tí ó kún fún àwọn ìlú ńlá ńlá tí kì í ṣe ẹ̀yin ló kọ́ ọ,
11 And houses full of all maner of goods which thou filledst not, and welles digged which thou diggedst not, vineyards and oliue trees which thou plantedst not, and when thou hast eaten and art full,
àwọn ilé tí ó kún fún gbogbo ohun mèremère tí kì í ṣe ẹ̀yin ló rà wọ́n, àwọn kànga tí ẹ kò gbẹ́, àti àwọn ọgbà àjàrà àti èso olifi tí kì í ṣe ẹ̀yin ló gbìn wọ́n. Nígbà tí ẹ bá jẹ tí ẹ sì yó,
12 Beware least thou forget the Lord, which brought thee out of the land of Egypt, from the house of bondage.
ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé Olúwa, tí o mú un yín jáde láti Ejibiti wá, kúrò ní oko ẹrú.
13 Thou shalt feare the Lord thy God, and serue him, and shalt sweare by his Name.
Bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ, Òun nìkan ni kí o sì máa sìn, búra ní orúkọ rẹ̀ nìkan.
14 Ye shall not walke after other gods, after any of the gods of the people which are round about you,
Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run àwọn tí ó yí i yín ká;
15 (For the Lord thy God is a ielous God among you: ) least the wrath of the Lord thy God be kindled against thee, and destroy thee from the face of the earth.
torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run owú ni, ìbínú rẹ̀ yóò sì run yín kúrò ní ilẹ̀ náà.
16 Ye shall not tempt the Lord your God, as ye did tempt him in Massah:
Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run yín wò bí ẹ̀yin ti dán wò ní Massa.
17 But ye shall keepe diligently the commandements of the Lord your God, and his testimonies, and his ordinances which he hath commanded thee,
Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń pa àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́ àti àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà tí ó ti fún un yín.
18 And thou shalt doe that which is right and good in the sight of the Lord: that thou mayest prosper, and that thou mayest go in, and possesse that good land which the Lord sware vnto thy fathers,
Ẹ ṣe èyí tí ó dára tí ó sì tọ́ lójú Olúwa, kí ó bá à lè dára fún un yín, kí ẹ̀yin bá à lè lọ láti gba ilẹ̀ dáradára náà tí Ọlọ́run ti fi ìbúra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.
19 To cast out all thine enemies before thee, as the Lord hath sayd.
Ẹ̀yin yóò sì ti àwọn ọ̀tá yín jáde níwájú u yín bí Olúwa ti ṣèlérí.
20 When thy sonne shall aske thee in time to come, saying, What meane these testimonies, and ordinances, and Lawes, which the Lord our God hath commanded you?
Ní ọjọ́ iwájú, bí ọmọ rẹ bá béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin wọ̀nyí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún ọ?”
21 Then shalt thou say vnto thy sonne, We were Pharaohs bondmen in Egypt: but the Lord brought vs out of Egypt with a mightie hand.
Sọ fún un pé: “Ẹrú Farao ní ilẹ̀ Ejibiti ni wá tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa fi ọwọ́ agbára ńlá yọ wá jáde lóko ẹrú Ejibiti.
22 And the Lord shewed signes and wonders great and euill vpon Egypt, vpon Pharaoh, and vpon all his housholde, before our eyes,
Lójú wa ni Olúwa tí ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu: tí ó lágbára tí ó sì ba ni lẹ́rù: lórí Ejibiti àti Farao, àti gbogbo ènìyàn rẹ̀.
23 And brought vs out from thence, to bring vs in, and to giue vs the land which he sware vnto our fathers.
Ṣùgbọ́n ó mú wa jáde láti ibẹ̀ wá láti mú wa wọ inú àti láti fún wa ní ilẹ̀ tí ó ti fì búra fún àwọn baba ńlá wa.
24 Therefore the Lord hath commanded vs, to doe all these ordinances, and to feare the Lord our God, that it may goe euer well with vs, and that he may preserue vs aliue as at this present.
Olúwa pàṣẹ fún wa láti ṣe ìgbọ́ràn sí gbogbo ìlànà wọ̀nyí, láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, kí ó ba à lè máa dára fún wa nígbà gbogbo, kí a sì lè wà láyé, bí a ṣe wà títí di òní.
25 Moreouer, this shall be our righteousnes before the Lord our God, if we take heede to keepe all these commandements, as he hath commanded vs.
Bí a bá ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin wọ̀nyí mọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, bí ó ti pàṣẹ fún wa, èyí ni yóò máa jẹ́ òdodo wa.”

< Deuteronomy 6 >