< Daniel 12 >
1 And at that time shall Michael stand vp, ye great prince, which standeth for ye children of thy people, and there shall be a time of trouble, such as neuer was since there began to be a nation vnto that same time: and at that time thy people shall be deliuered, euery one that shall be foud written in ye boke.
“Ní àkókò náà, ni Mikaeli, ọmọ-aládé ńlá, ẹni tí o ń dáàbò bo àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò dìde. Àkókò ìpọ́njú yóò wà, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí láti ìbẹ̀rẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè títí di àkókò náà. Ṣùgbọ́n ní àkókò náà àwọn ènìyàn rẹ̀, gbogbo àwọn tí a bá ti rí orúkọ wọn nínú ìwé ni a ó gbàlà.
2 And many of them that sleepe in the dust of the earth, shall awake, some to euerlasting life, and some to shame and perpetuall contempt.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn tí ó sùn nínú erùpẹ̀ ilẹ̀ ni yóò jí: àwọn mìíràn sí ìyè àìnípẹ̀kun, àwọn tókù sí ìtìjú àti sí ẹ̀gàn àìnípẹ̀kun.
3 And they that be wise, shall shine, as ye brightnes of the firmament: and they that turne many to righteousnes, shall shine as the starres, for euer and euer.
Àwọn tí ó jẹ́ ọlọ́gbọ́n yóò máa tàn bí ìmọ́lẹ̀ ọ̀run, àti àwọn tí ó ń tọ́nisọ́nà sí òdodo, yóò máa tàn bí ìràwọ̀ láé àti láéláé.
4 But thou, O Daniel, shut vp the words, and seale the boke til the end of the time: many shall run to and from, and knowledge shall be increased.
Ṣùgbọ́n ìwọ Daniẹli, pa ìwé náà dé kí o sì pa ọ̀rọ̀ ọ rẹ̀ mọ́ títí àkókò ìgbẹ̀yìn. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò máa lọ sí ìhín sí ọ̀hún láti jẹ́ kí ìmọ̀ wọn di púpọ̀.”
5 Then I Daniel looked, and behold, there stood other two, ye one on this side of ye brinke of ye riuer, and the other on that side of ye brinke of the riuer.
Nígbà náà, ni èmi Daniẹli, wò, ní iwájú mi àwọn méjì mìíràn dúró, ọ̀kan dúró sí apá ìhín ní etí bèbè odò ẹnìkan náà ní apá òdìkejì ọ̀hún etí i bèbè.
6 And one saide vnto the man clothed in linen, which was vpon ye waters of the riuer, When shalbe the ende of these wonders?
Ọ̀kan lára wọn sọ fún ọkùnrin tí ó wọ aṣọ àlà, ẹni tí ó wà lórí omi odò pé, “Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó kí àwọn nǹkan ìyanu wọ̀nyí tó wá sí ìmúṣẹ?”
7 And I heard ye man clothed in line which was vpon the waters of the riuer, when he helde vp his right hand, and his left hand vnto heauen, and sware by him that liueth for euer, that it shall tarie for a time, two times and an halfe: and when he shall haue accomplished to scatter the power of the holy people, all these things shall be finished.
Ọkùnrin tí ó wọ aṣọ àlà, ẹni tí ó wà lórí omi odò, gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti ọwọ́ òsì rẹ̀, mo gbọ́ tí ó fi ẹni tí ó wà títí láé búra, ó sọ wí pé, “Yóò ṣe ní àkókò kan, àkókò méjì àti ààbọ̀. Nígbà tí agbára àwọn ẹni mímọ́ yóò ti fọ́ tán pátápátá, gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò sì parí.”
8 The I heard it, but I vnderstood it not: the said I, O my Lord, what shalbe ye end of these things?
Èmi gbọ́, ṣùgbọ́n kò yé mi. Nígbà náà ni mo béèrè pé, “Olúwa mi, kí ni yóò jẹ́ àbábọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?”
9 And he said, Go thy way, Daniel: for ye words are closed vp, and sealed, till the ende of the time.
Ó sì dáhùn pé, “Máa lọ ní ọ̀nà rẹ, Daniẹli nítorí tí a ti pa ọ̀rọ̀ náà dé, a sì ti fi èdìdì dì í di ìgbà ìkẹyìn.
10 Many shalbe purified, made white, and tried: but the wicked shall doe wickedly, and none of the wicked shall haue vnderstanding: but the wise shall vnderstand.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni a ó fọ̀ mọ́, wọn yóò wà láìlábàwọ́n, a ó sì tún wọn ṣe, ṣùgbọ́n àwọn ẹni búburú yóò máa ṣe búburú lọ, kò sí ẹni búburú tí òye yóò yé ṣùgbọ́n òye yóò yé àwọn ọlọ́gbọ́n.
11 And from the time that the daily sacrifice shalbe take away and the abominable desolatio set vp, there shalbe a thousand, two hundreth and ninetie daies.
“Láti àkókò tí a ó mú ẹbọ ojoojúmọ́ kúrò, tí a ó sì gbé ìríra tí ó ń fa ìsọdahoro kalẹ̀ yóò sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún àti igba lé àádọ́rùn-ún ọjọ́.
12 Blessed is he that waiteth and commeth to the thousand, three hundreth and fiue and thirtie daies.
Ìbùkún ni fún ẹni tí ó dúró, ti ó sì di òpin ẹgbẹ̀rún àti ọ̀ọ́dúnrún lé àrùndínlógójì ọjọ́.
13 But go thou thy way til the end be: for thou shalt rest and stand vp in thy lot, at the end of ye daies.
“Ṣùgbọ́n ìwọ, máa lọ ní ọ̀nà rẹ, títí di òpin. Ìwọ yóò sinmi, àti ní òpin ọjọ́ ìwọ yóò dìde láti gba èrè rẹ.”