< 2 Samuel 20 >
1 Then there was come thither a wicked man (named Sheba the sonne of Bichri, a man of Iemini) and hee blew the trumpet, and saide, Wee haue no part in Dauid, neither haue we inheritance in the sonne of Ishai: euery man to his tents, O Israel.
Ọkùnrin Beliali kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣeba ọmọ Bikri ará Benjamini; ó sì fún ìpè ó sì wí pé, “Àwa kò ní ipa nínú Dafidi, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ni ìní nínú ọmọ Jese! Kí olúkúlùkù ọkùnrin lọ sí àgọ́ rẹ̀, ẹ̀yin Israẹli!”
2 So euery man of Israel went from Dauid and followed Sheba the sonne of Bichri: but the men of Iudah claue fast vnto their King, from Iorden euen to Ierusalem.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì lọ kúrò lẹ́yìn Dafidi, wọ́n sì ń tọ́ Ṣeba ọmọ Bikri lẹ́yìn, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Juda sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jordani wá títí ó fi dé Jerusalẹmu.
3 When Dauid then came to his house to Ierusalem, the King tooke the ten women his concubines, that hee had left behinde him to keepe the house, and put them in warde, and fed them, but lay no more with them: but they were enclosed vnto the day of their death, liuing in widowhode.
Dafidi sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì sé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.
4 Then sayde the King to Amasa, Assemble me the men of Iudah within three dayes, and be thou here present.
Ọba sì wí fún Amasa pé, “Pe àwọn ọkùnrin Juda fún mi ní ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìn-ín yìí.”
5 So Amasa went to assemble Iudah, but hee taried longer then the time which he had appoynted him.
Amasa sì lọ láti pe àwọn ọkùnrin Juda; ṣùgbọ́n ó sì dúró pẹ́ ju àkókò tí a fi fún un.
6 Then Dauid sayd to Abishai, Now shall Sheba the sonne of Bichri doe vs more harme then did Absalom: take thou therefore thy lords seruants and follow after him, lest he get him walled cities, and escape vs.
Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Nísinsin yìí Ṣeba ọmọ Bikri yóò ṣe wá ní ibi ju ti Absalomu lọ; ìwọ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ, kí o sì lépa rẹ̀, kí ó má ba à rí ìlú olódi wọ̀, kí ó sì bọ́ lọ́wọ́ wa.”
7 And there went out after him Ioabs men, and the Cherethites and the Pelethites, and all the mightie men: and they departed out of Ierusalem, to follow after Sheba the sonne of Bichri.
Àwọn ọmọkùnrin Joabu sì jáde tọ̀ ọ́ lọ, àti àwọn Kereti, àti àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára, wọ́n sì ti Jerusalẹmu jáde lọ, láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
8 When they were at the great stone, which is in Gibeon, Amasa went before them, and Ioabs garment, that hee had put on, was girded vnto him, and vpon it was a sword girded, which hanged on his loynes in the sheath, and as hee went, it vsed to fall out.
Nígbà tí wọ́n dé ibi òkúta ńlá tí ó wà ní Gibeoni, Amasa sì ṣáájú wọn, Joabu sì di àmùrè sí agbádá rẹ̀ tí ó wọ̀, ó sì sán idà rẹ̀ mọ́ ìdí, nínú àkọ̀ rẹ̀, bí ó sì ti ń lọ, ó yọ́ jáde.
9 And Ioab sayde to Amasa, Art thou in health, my brother? and Ioab tooke Amasa by the beard with the right hand to kisse him.
Joabu sì bi Amasa léèrè pé, “Àlàáfíà ha kọ́ ni bí, ìwọ arákùnrin mi?” Joabu sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, di Amasa ní irùngbọ̀n mú láti fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
10 But Amasa tooke no heede to the sworde that was in Ioabs hande: for therewith he smote him in the fift rib, and shed out his bowels to the ground, and smote him not the second time: so he dyed. then Ioab and Abishai his brother followed after Sheba the sonne of Bichri.
Ṣùgbọ́n Amasa kò sì kíyèsi idà tí ń bẹ lọ́wọ́ Joabu, bẹ́ẹ̀ ni òun sì fi gún un ní ikùn, ìfun rẹ̀ sì tú dà sílẹ̀, òun kò sì tún gún un mọ́, Amasa sì kú. Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
11 And one of Ioabs men stoode by him, and saide, He that fauoureth Ioab, and hee that is of Dauids part, let him go after Ioab.
Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Joabu sì dúró tì Amasa, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni tí ó fẹ́ràn Joabu? Ta ni ó sì ń ṣe ti Dafidi, kí ó máa tọ Joabu lẹ́yìn.”
12 And Amasa wallowed in blood in the mids of the way: and when the man sawe that all the people stood still, he remooued Amasa out of the way into the fielde, and cast a cloth vpon him, because he saw that euery one that came by him, stoode still.
Amasa sì ń yíràá nínú ẹ̀jẹ̀ láàrín ọ̀nà. Ọkùnrin náà sì rí i pé gbogbo ènìyàn sì dúró tì í, ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà lọ sínú igbó, ó sì fi aṣọ bò ó, nígbà tí ó rí i pé ẹnikẹ́ni tí ó bá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, á dúró.
13 When hee was remoued out of the way, euerie man went after Ioab, to follow after Sheba the sonne of Bichri.
Nígbà tí ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà gbogbo ènìyàn sì tọ Joabu lẹ́yìn láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
14 And he went through all the tribes of Israel vnto Abel, and Bethmaachah and all places of Berim: and they gathered together, and went also after him.
Ṣeba kọjá nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli sí Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo àwọn ará Beri; wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pẹ̀lú.
15 So they came, and besieged him in Abel, neere to Bethmaachah: and they cast vp a mount against the citie, and the people thereof stood on the ramper, and al the people that was with Ioab, destroyed and cast downe the wall.
Wọ́n wá, wọ́n sì dó tì Ṣeba ní Abeli-Beti-Maaka, wọ́n sì mọ odi ti ìlú náà, odi náà sì dúró ti odi ìlú náà, gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ Joabu sì ń gbìyànjú láti wó ògiri náà lulẹ̀.
16 Then cried a wise woman out of the citie, Heare, heare, I pray you, say vnto Ioab, Come thou hither, that I may speake with thee.
Obìnrin ọlọ́gbọ́n kan sì kígbe sókè láti ìlú náà wá pé, “Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀! Èmi bẹ̀ yín, ẹ sọ fún Joabu pé, ‘Súnmọ́ ìhín yìí èmi ó sì bá a sọ̀rọ̀.’”
17 And when hee came neere vnto her, the woman said, Art thou Ioab? And he answered, Yea. And she said to him, Heare the wordes of thine handmaid. And he answered, I do heare.
Nígbà tí òun sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, obìnrin náà sì wí pé, “Ìwọ ni Joabu bí?” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi náà ni.” Obìnrin náà sì wí fún un pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi ń gbọ́.”
18 Then shee spake thus, They spake in the olde time, saying, They shoulde aske of Abel. and so haue they continued.
Ó sì sọ̀rọ̀ wí pé, “Wọ́n ti ń wí ṣáájú pé, ‘Gba ìdáhùn rẹ ní Abeli,’ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì parí ọ̀ràn náà.
19 I am one of them, that are peaceable and faithful in Israel: and thou goest about to destroy a citie, and a mother in Israel: why wilt thou deuoure the inheritance of the Lord?
Èmi ni ọ̀kan nínú àwọn ẹni àlàáfíà àti olóòtítọ́ ní Israẹli, ìwọ ń wá ọ̀nà láti pa ìlú kan run tí ó jẹ́ ìyá ní Israẹli, èéṣe tí ìwọ ó fi gbé ìní Olúwa mì.”
20 And Ioab answered, and said, God forbid, God forbid it me, that I should deuoure, or destroy it.
Joabu sì dáhùn wí pé, “Kí a má rí i, kí a má rí i lọ́dọ̀ mi pé èmi gbé mì tàbí èmi sì parun.
21 The matter is not so, but a man of mout Ephraim (Sheba ye sonne of Bichri by name) hath lift vp his had against ye King, euen against Dauid: deliuer vs him onely, and I will depart from the citie. And the woman saide vnto Ioab, Beholde, his head shalbe throwen to thee ouer the wall.
Ọ̀ràn náà kò sì rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ọkùnrin kan láti òkè Efraimu, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣeba, ọmọ Bikri, ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ọba, àní sí Dafidi: fi òun nìkan ṣoṣo lé wa lọ́wọ́, èmi ó sì fi ìlú sílẹ̀.” Obìnrin náà sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, orí rẹ̀ ni a ó sì sọ láti inú odi wá.”
22 Then the woman went vnto all the people with her wisedome, and they cut off the head of Sheba the sonne of Bichri, and cast it to Ioab: the he blewe the trumpet, and they retired from the citie, euery man to his tent: and Ioab returned to Ierusalem vnto the King.
Obìnrin náà sì mú ìmọ́ràn rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣeba ọmọ Bikri lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Joabu. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká ní ìlú náà, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀. Joabu sí padà lọ sí Jerusalẹmu àti sọ́dọ̀ ọba.
23 Then Ioab was ouer all the hoste of Israel, and Benaiah the sonne of Iehoiada ouer the Cherethites and ouer the Pelethies,
Joabu sì ni olórí gbogbo ogun Israẹli; Benaiah ọmọ Jehoiada sì jẹ́ olórí àwọn Kereti, àti ti àwọn Peleti.
24 And Adoram ouer the tribute, and Ioshaphat the sonne of Ahilud the recorder,
Adoniramu sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi sì jẹ́ olùkọsílẹ̀ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú.
25 And Sheia was Scribe, and Zadok and Abiathar the Priests,
Ṣefa sì jẹ́ akọ̀wé; Sadoku àti Abiatari sì ni àwọn àlùfáà.
26 And also Ira the Iairite was chiefe about Dauid.
Ira pẹ̀lú, ará Jairi ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dafidi.