< 1 Samuel 28 >

1 Nowe at that time the Philistims assembled their bandes and armie to fight with Israel: therfore Achish said to Dauid, Be sure, thou shalt go out with me to the battel, thou, and thy men.
Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, àwọn Filistini sì kó àwọn ogun wọn jọ, láti bá Israẹli jà. Akiṣi sì wí fún Dafidi pé, “Mọ̀ dájúdájú pé, ìwọ yóò bá mi jáde lọ sí ibi ìjà, ìwọ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ.”
2 And Dauid said to Achish, Surely thou shalt knowe, what thy seruant can doe. And Achish sayde to Dauid, Surely I will make thee keeper of mine head for euer.
Dafidi sì wí fún Akiṣi pé, “Nítòótọ́ ìwọ ó sì mọ ohun tí ìránṣẹ́ rẹ lè ṣe.” Akiṣi sì wí fún Dafidi pé, “Nítorí náà ni èmi ó ṣe fi ìwọ ṣe olùṣọ́ orí mi ni gbogbo ọjọ́.”
3 (Samuel was then dead, and all Israel had lamented him, and buried him in Ramah his owne citie: and Saul had put away the sorcerers, and the soothsayers out of the land)
Samuẹli sì ti kú, gbogbo Israẹli sì sọkún rẹ̀, wọ́n sì sin ín ní Rama ní ìlú rẹ̀. Saulu sì ti mú àwọn abókùúsọ̀rọ̀ ọkùnrin, àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀ obìnrin kúrò ní ilẹ̀ náà.
4 Then the Philistims assembled themselues, and came, and pitched in Shunem: and Saul assembled all Israel, and they pitched in Gilboa.
Àwọn Filistini sì kó ara wọn jọ, wọ́n wá, wọ́n sì dó sí Ṣunemu: Saulu sì kó gbogbo Israẹli jọ, wọ́n sì tẹ̀dó ní Gilboa.
5 And when Saul saw the hoste of the Philistims, he was afraid, and his heart was sore astonied.
Nígbà tí Saulu sì rí ogun àwọn Filistini náà òun sì bẹ̀rù, àyà rẹ̀ sì wárìrì gidigidi.
6 Therefore Saul asked counsel of the Lord, and the Lord answered him not, neither by dreames, nor by Vrim, nor yet by Prophets.
Nígbà tí Saulu sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa kò dá a lóhùn nípa àlá, nípa Urimu tàbí nípa àwọn wòlíì.
7 Then saide Saul vnto his seruants, Seeke me a woman that hath a familiar spirite, that I may goe to her, and aske of her. And his seruants said to him, Beholde, there is a woman at En-dor that hath a familiar spirit.
Saulu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ bá mi wá obìnrin kan tí ó ní ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀ èmi yóò sì tọ̀ ọ́ lọ, èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ̀!” Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, obìnrin kan wà ní Endori tí ó ní ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀.”
8 Then Saul changed him selfe, and put on other raiment, and he went, and two men with him, and they came to the woman by night: and he saide, I pray thee, coniecture vnto me by the familiar spirite, and bring me him vp whome I shall name vnto thee.
Saulu sì pa ara dà, ó sì mú aṣọ mìíràn wọ̀, ó sì lọ, àwọn ọmọkùnrin méjì sì pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ obìnrin náà lóru: òun sì wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, fi ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀ wo nǹkan fún mi, kí o sì mú ẹni tí èmí ó dárúkọ rẹ̀ fún ọ wá sókè fún mi.”
9 And the woman saide vnto him, Beholde, thou knowest what Saul hath done, how he hath destroyed the sorcerers, and the southsayers out of the land: wherefore then seekest thou to take me in a snare to cause me to die?
Obìnrin náà sì dá a lóhùn pé, “Wò ó, ìwọ sá à mọ ohun tí Saulu ṣe, bí òun ti gé àwọn abókùúsọ̀rọ̀ obìnrin, àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀ ọkùnrin kúrò ní ilẹ̀ náà; ǹjẹ́ èéha ṣe tí ìwọ dẹkùn fún ẹ̀mí mi, láti mú kí wọ́n pa mí.”
10 And Saul sware to her by the Lord, saying, As the Lord liueth, no harme shall come to thee for this thing.
Saulu sì búra fún un nípa Olúwa pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ìyà kan kì yóò jẹ́ ọ́ nítorí nǹkan yìí.”
11 Then said the woman, Whom shall I bring vp vnto thee? And he answered, Bring me vp Samuel.
Obìnrin náà sì bi í pé, “Ta ni ẹ̀mí ó mú wá sókè fún ọ?” Òun sì wí pé, “Mú Samuẹli gòkè wá fún mi.”
12 And when the woman sawe Samuel, she cryed with a loude voyce, and the woman spake to Saul, saying, Why hast thou deceiued me? for thou art Saul.
Nígbà tí obìnrin náà sì rí Samuẹli, ó kígbe lóhùn rara: obìnrin náà sì bá Saulu sọ̀rọ̀ pè, “Èéṣe tí ìwọ fi tàn mí jẹ? Nítorí pé Saulu ni ìwọ jẹ́.”
13 And the King said vnto her, Be not afraid: for what sawest thou? And the woman said vnto Saul, I saw gods ascending vp out of the earth.
Ọba sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù; kín ni ìwọ rí?” Obìnrin náà sì wí fún Saulu pé, “Èmi rí ọlọ́run kan tí ń ti ilẹ̀ wá.”
14 Then he said vnto her, What facion is hee of? And she answered, An olde man commeth vp lapped in a mantel: and Saul knewe that it was Samuel, and he enclined his face to the grounde, and bowed him selfe.
Ó sì bi í pé, “Báwo ni ó ti rí i sí.” Ó sì wí pé, “Ọkùnrin arúgbó kan ni ó ń bọ; ó sì fi agbádá bora.” Saulu sì mọ̀ pé, Samuẹli ni; ó sì tẹríba, ó sì wólẹ̀.
15 And Samuel said to Saul, Why hast thou disquieted me, to bring me vp? Then Saul answered, I am in great distresse: for the Philistims make warre against me, and God is departed from me, and answereth me no more, neither by Prophetes, neither by dreames: therefore I haue called thee, that thou mayest tell me, what I shall doe.
Samuẹli sì i wí fún Saulu pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń yọ mí lẹ́nu láti mú mi wá sókè?” Saulu sì dáhùn ó sì wí pé, “Ìpọ́njú ńlá bá mi; nítorí tí àwọn Filistini ń bá mi jagun, Ọlọ́run sì kọ̀ mí sílẹ̀, kò sì dá mi lóhùn mọ́, nípa ọwọ́ àwọn wòlíì, tàbí nípa àlá; nítorí náà ni èmi ṣe pè ọ́, kí ìwọ lè fi ohun tí èmi yóò ṣe hàn mi.”
16 Then said Samuel, Wherefore then doest thou aske of me, seeing the Lord is gone from thee, and is thine enemie?
Samuẹli sì wí pé, “Ó ti ṣe ń bi mí léèrè nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, o sì di ọ̀tá rẹ̀.
17 Euen the Lord hath done to him, as hee spake by mine hande: for the Lord will rent the kingdome out of thine hande, and giue it thy neighbour Dauid.
Olúwa sì ṣe fún ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ti ipa ọwọ́ mi sọ: Olúwa sì yá ìjọba náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi fún aládùúgbò rẹ́, àní Dafidi.
18 Because thou obeyedst not the voyce of the Lord, nor executedst his fierce wrath vpon the Amalekites, therefore hath the Lord done this vnto thee this day.
Nítorí pé ìwọ kò gbọ́ ohùn Olúwa ìwọ kò sì ṣe iṣẹ́ ìbínú rẹ̀ sí Amaleki nítorí náà ni Olúwa sì ṣe nǹkan yìí sí ọ lónìí yìí.
19 Moreouer the Lord wil deliuer Israel with thee into the handes of the Philistims: and to morowe shalt thou and thy sonnes be with me, and the Lord shall giue the hoste of Israel into the handes of the Philistims.
Olúwa yóò sì fi Israẹli pẹ̀lú ìwọ lé àwọn Filistini lọ́wọ́, ní ọ̀la ni ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò pẹ̀lú mi: Olúwa yóò sì fi ogun Israẹli lé àwọn Filistini lọ́wọ́.”
20 Then Saul fell streight way all along on the earth, and was sore afraide because of the wordes of Samuel, so that there was no strength in him: for he had eaten no bread all the day nor all the night.
Lójúkan náà ni Saulu ṣubú lulẹ̀ gbalaja níbí ó ṣe gùn tó, ẹ̀rù sì bà á gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ Samuẹli; agbára kò sí fún un; nítorí pé kò jẹun ní ọjọ́ náà tọ̀sán tòru.
21 Then the woman came vnto Saul, and sawe that he was sore troubled, and said vnto him, See, thine handmaide hath obeyed thy voyce, and I haue put my soule in mine hande, and haue obeyed thy wordes which thou saydest vnto me.
Obìnrin náà sì tọ Saulu wá, ó sì rí i pé ó wà nínú ìbànújẹ́ púpọ̀, ó sì wí fún un pé, “Wò ó, ìránṣẹ́bìnrin rẹ́ ti gbọ́ ohun rẹ̀, èmi sì ti fi ẹ̀mí mi sí ọwọ́ mi, èmi sì ti gbọ́ ọ̀rọ̀ ti ìwọ sọ fún mi.
22 Now therefore, I pray thee, hearke thou also vnto ye voyce of thine handmaid, and let me set a morsell of bread before thee, that thou mayest eat and get thee strength, and go on thy iourney.
Ǹjẹ́, nísinsin yìí èmi bẹ̀ ọ́, gbọ́ ohùn ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi yóò sì fi oúnjẹ díẹ̀ síwájú rẹ̀; sì jẹun, ìwọ yóò sì lágbára, nígbà tí ìwọ bá ń lọ lọ́nà.”
23 But he refused, and said, I will not eate: but his seruants and the woman together compelled him, and he obeyed their voyce: so he arose from the earth, and sate on the bed.
Ṣùgbọ́n ó kọ̀, ó sì wí pé, “Èmi kì yóò jẹun.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rọ̀ ọ́. Ó sì dìde kúrò ni ilẹ̀, ó sì jókòó lórí àkéte.
24 Nowe the woman had a fat calfe in the house, and she hasted, and killed it, and tooke floure and kneaded it, and baked of it vnleauened bread.
Obìnrin náà sì ni ẹgbọrọ màlúù kan ti ó sanra ni ilé, ó sì yára, ó pa á, ó sì mú ìyẹ̀fun, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà àìwú.
25 Then she brought them before Saul, and before his seruants: and when they had eaten, they stoode, and went away the same night.
Ó sì mú un wá síwájú Saulu, àti síwájú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀; wọ́n sì jẹun. Wọ́n sì dìde, wọ́n lọ ní òru náà.

< 1 Samuel 28 >