< Psalms 73 >
1 A psalm of Asaph. Truly God is good to Israel, to those whose minds are pure.
Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
2 But I was stumbling, my feet were starting to slide,
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
3 because I was jealous of self-important people—I saw how well the wicked were doing.
Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
4 They don't ever seem to get sick; they are strong and healthy.
Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
5 They don't have problems like other people; they don't get hit by disasters like everybody else.
Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
6 They wear their pride like a necklace; they clothe themselves with violence.
Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
7 Their eyes bulge out because they're so fat; their minds are full of selfish vanity.
Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
8 They mock people, and speak maliciously; they arrogantly threaten cruelty.
Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
9 They talk irreverently against heaven above, and defame people here on earth.
Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
10 As a result people turn to them and drink in everything they say.
Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
11 “God won't find out,” they say. “The Most High doesn't even know what's going on!”
Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
12 Look at these wicked people! They don't have a care in the world, and they're always making money!
Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
13 It's been pointless to keep my mind pure and my hands clean.
Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
14 I'm cursed with suffering all day long; every morning I'm punished.
Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
15 If I'd talked like this to others, I would have betrayed your people.
Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
16 So I thought about it and tried to understand, but it looked like a lot of hard work to me—
Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
17 until I went into God's Temple. Then I understood what happens to the wicked in the end.
títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
18 For you send them on a slippery path; you throw them down to destruction.
Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
19 How quickly they're destroyed! They come to a terrifying end.
Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
20 Like waking up from a dream, Lord—when you get up you will forget all about them!
Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
21 At that time my thoughts were bitter. I felt like I had been stabbed.
Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
22 I was stupid and ignorant. I was like a brute beast to you.
mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
23 Yet I'm always with you; you hold me by the hand.
Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
24 You tell me what to do; and ultimately you will welcome me in glory.
Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
25 Who is there in heaven for me except you? And I want nothing on earth except you.
Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
26 My body and my mind may fail, but God is the foundation of my life. He is mine forever!
Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
27 Those people who are far from God will die. You destroy all those unfaithful to you.
Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
28 But I love to stay close to God! I have chosen the Lord God to protect me. I will share all that you have done.
Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.