< Joshua 13 >

1 Many years had passed by, and Joshua had grown old. The Lord spoke to him, saying, “You're now an old man, but there's still a great deal of land still to be taken.
Nígbà tí Joṣua sì darúgbó tí ọjọ́ orí rẹ̀ sì pọ̀ jọjọ, Olúwa sọ fún un pé, “Ìwọ ti darúgbó púpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ilẹ̀ sì kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀ fún yín láti gbà.
2 This is the remaining land: the territory of all the Philistines and all the Geshurites,
“Èyí ni ilẹ̀ tí ó kù: “gbogbo àwọn agbègbè àwọn Filistini, àti ti ara Geṣuri:
3 from the Shihur River on the border with Egypt north to the border of Ekron—all of which is counted as Canaanite but comes under the five Philistine lords of Gaza, Ashdod, Ashkelon, Gath, and Ekron. In addition there's the land of the Avvites
láti odò Ṣihori ní ìlà-oòrùn Ejibiti sí agbègbè Ekroni ìhà àríwá, gbogbo rẹ̀ ni a kà kún Kenaani (agbègbè ìjòyè Filistini márùn-ún ní Gasa, Aṣdodu, Aṣkeloni, Gitti àti Ekroni; ti àwọn ará Affimu);
4 in the south, all the land of the Canaanites, and Mearah that belongs to the Sidonians, all the way to Aphek on the border with the Amorites,
láti gúúsù; gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Kenaani, láti Arah ti àwọn ará Sidoni títí ó fi dé Afeki, agbègbè àwọn ará Amori,
5 as well as the land of the Gebalites and the Lebanon area from the town of Baalgad to the slopes of Mount Hermon to Lebo-hamath,
àti ilẹ̀ àwọn ará Gebali; àti gbogbo àwọn Lebanoni dé ìlà-oòrùn, láti Baali-Gadi ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni dé Lebo-Hamati.
6 and the those who live in the hill country from Lebanon to Misrephoth Maim, including all the land of the Sidonians. I myself will drive them out ahead of the Israelites. Just allocate the land to Israel for them to own, as I have commanded you.
“Ní ti gbogbo àwọn olùgbé agbègbè òkè, láti Lebanoni sí Misrefoti-Maimu, àní, gbogbo àwọn ará Sidoni, èmi fúnra mi ní yóò lé wọn jáde ní iwájú àwọn ará Israẹli. Kí o ri dájú pé o pín ilẹ̀ yí fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní, gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi àṣẹ fún ọ,
7 So divide this land among the nine tribes and the half-tribe of Manasseh for them to own.”
pín ilẹ̀ yìí ní ilẹ̀ ìní fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án àti ìdajì ẹ̀yà Manase.”
8 The other half of the tribe of Manasseh, and the tribes of Reuben and Gad, had already received their land grant on the east side of the Jordan, as allotted to them by Moses, the servant of the Lord.
Àwọn ìdajì ẹ̀yà Manase tí ó kù, àti àwọn Reubeni àti àwọn Gadi ti gba ilẹ̀ ìní, tí Mose ti fún wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.
9 It stretched from Aroer on the edge of the Arnon valley, from the town in the middle of the valley, and all the plateau of Medeba, up to Dibon;
Ó sì lọ títí láti Aroeri tí ń bẹ létí àfonífojì Arnoni, àti láti ìlú náà tí ń bẹ ní àárín àfonífojì náà, àti pẹ̀lú gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Medeba títí dé Diboni.
10 and all the towns that belonged to Sihon, king of the Amorites, who ruled in Heshbon, up to the border with the Ammonites.
Gbogbo ìlú Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó ṣe àkóso ní Heṣboni, títí dé ààlà àwọn ará Ammoni.
11 In addition it included Gilead, the land of the Geshurites and Maacathites, all of Mount Hermon, and all of Bashan as far as Salecah,
Àti Gileadi, ní agbègbè àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, gbogbo òkè Hermoni àti gbogbo Baṣani títí dé Saleka,
12 as well as all the land of the kingdom of Og of Bashan, who had ruled in Ashtaroth and Edrei. He was one of the last of the Rephaites. Moses had defeated them and driven them out.
ìyẹn, gbogbo ilẹ̀ ọba Ogu ní Baṣani, tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei, ẹni tí ó kù nínú àwọn Refaimu ìyókù. Mose ti ṣẹ́gun wọn, ó sì ti gba ilẹ̀ wọn.
13 But the Israelites had not driven out the Geshurites or the Maacathites, who still live among them to this very day.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli kò lé àwọn ará Geṣuri àti Maakati jáde, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé ní àárín àwọn ará Israẹli títí di òní yìí.
14 Moses did not allocate any land for the Levites to own. Instead they were allotted the offerings made by fire to the Lord, the God of Israel, as the Lord had promised them.
Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Lefi ni kò fi ogún kankan fún, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ pé ọrẹ àfinásun sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ni ogún tiwọn, gẹ́gẹ́ bí o ti ṣèlérí fún wọn.
15 This was the land that Moses allotted to the tribe of Reuben, by families:
Èyí ni Mose fi fún ẹ̀yà Reubeni ni agbo ilé sí agbo ilé,
16 Their territory stretched from Aroer on the edge of the Arnon valley, from the town in the middle of the valley, and all the plateau of Medeba;
láti agbègbè Aroeri ní etí Arnoni Jọ́ọ́jì àti láti ìlú tí ń bẹ láàrín Jọ́ọ́jì, àti gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọjá Medeba
17 Heshbon and all associated towns on the plateau—Dibon, Bamoth Baal, Beth Baal Meon,
sí Heṣboni àti gbogbo ìlú rẹ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Diboni, Bamoti Baali, Beti-Baali-Mioni,
18 Jahaz, Kedemoth, Mephaath,
Jahisa, Kedemoti, Mefaati,
19 Kiriathaim, Sibmah, Zereth-shahar, on a hill in the valley,
Kiriataimu, Sibma, Sereti Ṣahari lórí òkè ní àfonífojì.
20 Beth-peor, the slopes of Pisgah, Beth-jeshimoth—
Beti-Peori, gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga, àti Beti-Jeṣimoti
21 all the towns of the plateau and all the kingdom of Sihon, the Amorite king, who ruled in Heshbon. He was defeated by Moses, as well as the Midianite leaders Evi, Rekem, Zur, Hur, and Reba, princes who lived in the kingdom and who were allied to Sihon.
gbogbo ìlú tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti gbogbo agbègbè Sihoni ọba Amori, tí ó ṣe àkóso Heṣboni. Mose sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ìjòyè Midiani, Efi, Rekemu, Suri, Huri àti Reba, àwọn ọmọ ọba pawọ́pọ̀ pẹ̀lú Sihoni tí ó gbé ilẹ̀ náà.
22 At the same time the Israelites killed Balaam, son of Beor, the fortune-teller, along with the others who were slaughtered.
Ní àfikún àwọn tí a pa ní ogun, àwọn ọmọ Israẹli fi idà pa Balaamu ọmọ Beori alásọtẹ́lẹ̀.
23 The Jordan was the boundary for the tribe of Reuben. This was the land, the towns and the villages, allotted to the tribe of Reuben, by families.
Ààlà àwọn ọmọ Reubeni ni etí odò Jordani. Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ ni ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Reubeni ní agbo ilé ní agbo ilé.
24 This was the land that Moses allotted to the tribe of Gad, by families:
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ẹ̀yà Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
25 Their territory was Jazer, all the towns of Gilead, and half of the land of the Ammonites up to Aroer, near Rabbah;
Agbègbè ìlú Jaseri, gbogbo ìlú Gileadi àti ìdajì orílẹ̀-èdè àwọn ọmọ ará Ammoni títí dé Aroeri, ní ẹ̀bá Rabba;
26 stretching from Heshbon to Ramath-mizpeh and Betonim, and from Mahanaim to the Debir region.
àti láti Heṣboni lọ sí Ramati-Mispa àti Betonimu, àti láti Mahanaimu sí agbègbè ìlú Debiri,
27 In the Jordan valley lay Beth-haram, Beth-nimrah, Succoth, and Zaphon, the rest of the kingdom of Sihon, king of Heshbon. The boundary ran along the Jordan up to the bottom end of the sea of Kinnereth and then ran east.
àti ní àfonífojì Beti-Haramu, Beti-Nimra, Sukkoti àti Safoni pẹ̀lú ìyókù agbègbè ilẹ̀ Sihoni ọba Heṣboni (ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani, agbègbè rẹ̀ títí dé òpin Òkun Kinnereti).
28 This was the land, the towns and the villages, allotted to the tribe of Gad, by families.
Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ jẹ́ ogún àwọn ọmọ Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
29 This was the land that Moses allotted to the half-tribe of Manasseh, that is half of the tribe of the descendants of Manasseh, by families:
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ìdajì ẹ̀yà Manase, èyí ni pé, fún ìdajì ìdílé irú-ọmọ Manase, ní agbo ilé ní agbo ilé.
30 Their territory stretched from Manahaim through the whole of Bashan, all the kingdom of Og, and all the towns of Jair in Bashan—sixty in all.
Ilẹ̀ náà fẹ̀ dé Mahanaimu àti gbogbo Baṣani, gbogbo agbègbè ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani, èyí tí í ṣe ibùgbé Jairi ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú,
31 Also included was Gilead, and Ashtaroth and Edrei, the towns of king Og in Bashan. This was the land allotted to the descendants of Machir, son of Manasseh, for half of them, by families.
ìdajì Gileadi, àti Aṣtarotu àti Edrei (àwọn ìlú ọba Ogu ní Baṣani). Èyí ni fún irú àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase fún ààbọ̀ àwọn ọmọ Makiri, ní agbo ilé ní agbo ilé.
32 These were the allocations that Moses made when he was in the plains of Moab, on the other side of the Jordan, east of Jericho.
Èyí ni ogún tí Mose fi fún wọn nígbà tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní ìhà kejì Jordani ní ìlà-oòrùn Jeriko.
33 However, Moses did not allot any land to the Levites, for the Lord, the God of Israel, had promised them that he would be their allocation.
Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yà Lefi, Mose kò fi ogún fún un; Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ní ogún wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.

< Joshua 13 >