< Amos 2 >

1 This is what the Lord says: The people of Moab have repeatedly sinned and so I will not hesitate to punish them, because they desecrated the bones of the king of Edom by burning them, turning them into lime.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà, nítorí ó ti sun ún, di eérú, egungun ọba Edomu,
2 So I will send down fire on Moab, and I will burn up the fortresses of Kerioth, and the people of Moab will die in the midst of uproar, battle cries, and the sound of the trumpet.
Èmi yóò rán iná sí orí Moabu èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run. Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè.
3 I will cut down their king and all their princes with him, says the Lord.
Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,” ni Olúwa wí.
4 This is what the Lord says: The people of Judah have repeatedly sinned and so I will not hesitate to punish them, because they rejected the law of the Lord and have not kept his commands. Their lies have led them astray, the same lies that their forefathers followed.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́. Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà, òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé,
5 So I will send down fire on Judah, and I will burn up the fortresses of Jerusalem.
Èmi yóò rán iná sí orí Juda èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”
6 This is what the Lord says: The people of Israel have repeatedly sinned and so I will not hesitate to punish them, because they sell good people for silver, and poor people for a pair of sandals.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Wọ́n ta olódodo fún fàdákà àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
7 They trample the heads of the poor into the dust, and push the needy out of the way. A man and his father have sex with the same servant girl so that my holy name is profaned.
Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀, bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára. Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà, láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́.
8 At every altar they stretch themselves out in clothes taken from debtors as collateral, in the temple of their god they drink wine taken from the people they fined.
Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ, lórí aṣọ tí wọ́n fi jẹ́ ẹ̀jẹ́ ní ilé òrìṣà wọn wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.
9 Yet it was I was the one who destroyed the Amorites before you, even though they were as tall as cedars and as strong as oaks. I destroyed them root and branch.
“Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari. Òun sì le koko bí igi óákù mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
10 It was I who brought you out of the land of Egypt and led you through the desert for forty years so that you could take the Amorites' land.
Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.
11 I appointed some of your sons to be prophets, and some of your young men to be Nazirites. Isn't this true, people of Israel?
“Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?” ni Olúwa wí.
12 But you made the Nazirites sin by drinking wine, and you told the prophets, “Don't tell us what God says.”
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.
13 Now see what I am going to do. I will crush you where you are, as if crushed by a heavy cart loaded down with sheaves of grain.
“Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀ bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
14 Not even your fastest runners will escape; strong men will lose their strength. Even the greatest warrior will not be able to save his life.
Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀ jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
15 The archer will not stand his ground. The quickest on his feet will not be able to get away, and even those on horseback will not save themselves.
Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
16 On that day even the bravest of the mighty warriors will run away naked, says the Lord.
Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí.

< Amos 2 >