< Zechariah 12 >
1 The burden of the word of the Lord upon Israel. Thus saith the Lord, who stretcheth forth the heavens, and layeth the foundations of the earth, and formeth the spirit of man in him:
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa fún Israẹli ni. Olúwa wí, ẹni tí ó na àwọn ọ̀run, tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí ó sì da ẹ̀mí ènìyàn tí ń bẹ ni inú rẹ̀,
2 Behold I will make Jerusalem a lintel of surfeiting to all the people round about: and Juda also shall be in the siege against Jerusalem.
“Kíyèsi í, èmi yóò sọ Jerusalẹmu dí àgọ́ ìwárìrì sí gbogbo ènìyàn yíká, nígbà tí wọn yóò dó ti Juda àti Jerusalẹmu.
3 And it shall come to pass in that day, that I will make Jerusalem a burdensome stone to all people: all that shall lift it up shall be rent and torn, and all the kingdoms of the earth shall be gathered together against her.
Ní ọjọ́ náà, nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé bá parapọ̀ sí i, ni èmi yóò sọ Jerusalẹmu di òkúta ti ko ṣe yí kúrò fún gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn tí ó bá sì fẹ́ yí i ni a ó gé sí wẹ́wẹ́,
4 In that day, saith the Lord, I will strike every horse with astonishment, and his rider with madness: and I will open my eyes upon the house of Juda, and will strike every horse of the nations with blindness.
ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Ni èmi yóò fi ìdágìrì lu gbogbo ẹṣin, àti fi òmùgọ̀ kọlu ẹni tí ń gun un; èmi yóò sì ṣí ojú mi sí ilé Juda, èmi yóò sì bu ìfọ́jú lu gbogbo ẹṣin tí orílẹ̀-èdè.
5 And the governors of Juda shall say in their heart: Let the inhabitants of Jerusalem be strengthened for me in the Lord of hosts, their God.
Àti àwọn baálẹ̀ Juda yóò sì wí ni ọkàn wọn pé, ‘Àwọn ara Jerusalẹmu ni agbára mi nípa Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run wọn.’
6 In that day I will make the governors of Juda like a furnace of fire amongst wood, and as a firebrand amongst hay: and they shall devour all the people round about, to the right hand, and to the left: and Jerusalem shall be inhabited again in her own place in Jerusalem.
“Ní ọjọ́ náà, ni èmi yóò ṣe àwọn baálẹ̀ Juda bí ààrò iná kan láàrín igi, àti bi ẹ̀fúùfù iná láàrín ìtí; wọn yóò sì jẹ gbogbo àwọn ènìyàn run yíká lápá ọ̀tún àti lápá òsì, a ó sì tún máa gbé inú Jerusalẹmu ní ipò rẹ̀.
7 And the Lord shall save the tabernacles of Juda, as in the beginning: that the house of David, and the glory of the inhabitants of Jerusalem, may not boast and magnify themselves against Juda.
“Olúwa pẹ̀lú yóò kọ́ tètè gba àgọ́ Juda là ná, kí ògo ilé Dafidi àti ògo àwọn ara Jerusalẹmu má ba gbé ara wọn ga sí Juda.
8 In that day shall the Lord protect the inhabitants of Jerusalem, and he that hath offended among them in that day shall be as David: and the house of David, as that of God, as an angel of the Lord in their sight.
Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò dáàbò bò àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu; ẹni tí ó bá sì ṣe àìlera nínú wọn ní ọjọ́ náà, yóò dàbí Dafidi; ilé Dafidi yóò sì dàbí Ọlọ́run, bí angẹli Olúwa níwájú wọn.
9 And it shall come to pass in that day, that I will seek to destroy all the nations that come against Jerusalem.
Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, èmi yóò wá láti pa gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè run tí ó wá kọjú ìjà sí Jerusalẹmu.”
10 And I will pour out upon the house of David, and upon the inhabitants of Jerusalem, the spirit of grace, and of prayers: and they shall look upon me, whom they have pierced: and they shall mourn for him as one mourneth for an only son, and they shall grieve over him, as the manner is to grieve for the death of the firstborn.
“Èmi ó sì tu ẹ̀mí oore-ọ̀fẹ́ àti ẹ̀bẹ̀ sórí ilé Dafidi àti sórí Jerusalẹmu, wọn ó sì máa wo ẹni tí wọn tí gún ni ọ̀kọ̀, wọn ó sì máa ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, bí ẹnìkan ti ń ṣọ̀fọ̀ fún ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo àti gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí wọn yóò sì wà ni ìbànújẹ́, bí ẹni tí ń banújẹ́ fún àkọ́bí rẹ̀.
11 In that day there shall be a great lamentation in Jerusalem like the lamentation of Adadremmon in the plain of Mageddon.
Ní ọjọ́ náà ni ẹkún, ńlá ńlá yóò wà ni Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ọ̀fọ̀ Hadadi Rimoni ni àfonífojì Megido.
12 And the land shall mourn: families and families apart: the families of the house of David apart, and their women apart:
Ilẹ̀ náà yóò ṣọ̀fọ̀, ìdílé, kọ̀ọ̀kan fun ara rẹ, lọ́tọ̀ọ̀tọ̀; ìdílé Dafidi lọ́tọ̀; àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀; ìdílé Natani lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ́.
13 The families of the house of Nathan apart, and their women apart: the families of the house of Levi apart, and their women apart: the families of Semei apart, and their women apart.
Ìdílé Lefi lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀; ìdílé Ṣimei lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀.
14 All the rest of the families, families and families apart, and their women apart.
Gbogbo àwọn ìdílé tí o kù, ìdílé, ìdílé, lọ́tọ̀ọ̀tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀ọ̀tọ̀.