< Psalms 136 >
1 Praise the Lord, for he is good: for his mercy endureth for ever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;
2 Praise ye the God of gods: for his mercy endureth for ever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run àwọn ọlọ́run:
3 Praise ye the Lord of lords: for his mercy endureth for ever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa àwọn olúwa,
4 Who alone doth great wonders: for his mercy endureth for ever.
Fún Òun nìkan tí ń ṣiṣẹ́ ìyanu ńlá;
5 Who made the heavens in understanding: for his mercy endureth for ever.
Fún ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run;
6 Who established the earth above the waters: for his mercy endureth for ever.
Fún ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lórí omi;
7 Who made the great lights: for his mercy endureth for ever.
Fún ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá;
8 The sun to rule over the day: for his mercy endureth for ever.
Òòrùn láti jẹ ọba ọ̀sán;
9 The moon and the stars to rule the night: for his mercy endureth for ever.
Òṣùpá àti ìràwọ̀ láti jẹ ọba òru;
10 Who smote Egypt with their firstborn: for his mercy endureth for ever.
Fún ẹni tí ó kọlu Ejibiti lára àwọn àkọ́bí wọn;
11 Who brought Israel from among them: for his mercy endureth for ever.
Ó sì mú Israẹli jáde kúrò láàrín wọn;
12 With a mighty hand and a stretched out arm: for his mercy endureth for ever.
Pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà;
13 Who divided the Red Sea into parts: for his mercy endureth for ever.
Fún ẹni tí ó pín Òkun pupa ní ìyà;
14 And brought out Israel through the midst thereof: for his mercy endureth for ever.
Ó sì mú Israẹli kọjá láàrín rẹ̀
15 And overthrew Pharao and his host in the Red Sea: for his mercy endureth for ever.
Ṣùgbọ́n ó bi Farao àti ogun rẹ̀ ṣubú nínú Òkun pupa;
16 Who led his people through the desert: for his mercy endureth for ever.
Fún ẹni tí ó sin àwọn ènìyàn rẹ̀ la aginjù já
17 Who smote great kings: for his mercy endureth for ever.
Fún ẹni tí ó kọlu àwọn ọba ńlá;
18 And slew strong kings: for his mercy endureth for ever.
Ó sì pa àwọn ọba olókìkí
19 Sehon king of the Amorrhites: for his mercy endureth for ever.
Sihoni, ọba àwọn ará Amori
20 And Og king of Basan: for his mercy endureth for ever.
Àti Ogu, ọba Baṣani;
21 And he gave their land for an inheritance: for his mercy endureth for ever.
Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,
22 For an inheritance to his servant Israel: for his mercy endureth for ever.
Ìní fún Israẹli, ìránṣẹ́ rẹ̀,
23 For he was mindful of us in our affliction: for his mercy endureth for ever.
Ẹni tí ó rántí wa ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ wa;
24 And he redeemed us from our enemies: for his mercy endureth for ever.
Ó sì dá wa ní ìdè lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa;
25 Who giveth food to all flesh: for his mercy endureth for ever.
Ẹni tí ó fi oúnjẹ fún àwọn ẹ̀dá gbogbo
26 Give glory to the God of heaven: for his mercy endureth for ever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run;