< Isaiah 24 >
1 Behold the Lord shall lay waste the earth, and shall strip it, and shall afflict the face thereof, and scatter abroad the inhabitants thereof.
Kíyèsi i, Olúwa yóò sọ ohun gbogbo dòfo ní ilẹ̀ ayé yóò sì pa á run òun yóò pa ojú u rẹ̀ rẹ́ yóò sì fọ́n àwọn olùgbé ibẹ̀ káàkiri—
2 And it shall be as with the people, so with the priest: and as with the servant, so with his master: as with the handmaid, so with her mistress: as with the buyer, so with the seller: as with the lender, so with the borrower: as with him that calleth for his money, so with him that oweth.
bákan náà ni yóò sì rí fún àlùfáà àti àwọn ènìyàn, fún ọ̀gá àti ọmọ ọ̀dọ̀, fún ìyá-ilé àti ọmọbìnrin, fún olùtà àti olùrà, fún ayáni àti atọrọ fún ayánilówó àti onígbèsè.
3 With desolation shall the earth be laid waste, and it shall be utterly spoiled: for the Lord hath spoken this word.
Ilé ayé ni a ó sọ di ahoro pátápátá a ó sì jẹ gbogbo rẹ̀ run. Olúwa ni ó ti sọ ọ̀rọ̀ yìí.
4 The earth mourned, and faded away, and is weakened: the world faded away, the height of the people of the earth is weakened.
Ilẹ̀ ayé ti gbẹ ó sì sá, ayé ń ṣòjòjò, àárẹ̀ mú un, àwọn ẹni gíga ilẹ̀ ayé wà nínú ìpọ́njú
5 And the earth is infected by the inhabitants thereof: because they have transgressed the laws, they have changed the ordinance, they have broken the everlasting covenant.
àwọn ènìyàn ayé ti bà á jẹ́; wọ́n ti pa àwọn òfin run wọ́n ṣe lòdì sí àwọn ìlànà wọ́n sì ti ba májẹ̀mú ayérayé jẹ́.
6 Therefore shall a curse devour the earth, and the inhabitants thereof shall sin: and therefore they that dwell therein shall be mad, and few men shall be left.
Nítorí náà, ègún kan ti jẹ ayé run; àwọn ènìyàn rẹ̀ ní láti ru ẹ̀bi wọn. Nítorí náà, àwọn olùgbé ayé ti gbiná dànù, àwọn ẹ̀tàhóró ló sì kù.
7 The vintage hath mourned, the vine hath languished away, all the merryhearted have sighed.
Wáìnì tuntun ti gbẹ, àjàrà sì ti rọ, gbogbo àwọn aláríyá sì kérora.
8 The mirth of timbrels hath ceased, the noise of them that rejoice is ended, the melody of the harp is silent.
Àríyá ti ṣaworo ti dákẹ́ ariwo àwọn tí ń ṣàjọyọ̀ ti dáwọ́ dúró ayọ̀ dùùrù ti dákẹ́ jẹ́ẹ́.
9 They shall not drink wine with a song: the drink shall be bitter to them that drink it.
Kò ṣe é ṣe fún wọn láti máa mu wáìnì pẹ̀lú orin kíkọ mọ́ ọtí líle ti di ìkorò fún àwọn ọ̀mu.
10 The city of vanity is broken down, every house is shut up, no man cometh in.
Ìlú tí a run ti dahoro, ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé kọ̀ọ̀kan ni a dí pa.
11 There shall be a crying for wine in the streets: all mirth is forsaken: the joy of the earth is gone away.
Ní òpópónà ni wọ́n ti ń kígbe fún wáìnì gbogbo ayọ̀ ọ wọn ti di ìbànújẹ́, gbogbo àríyá ni a lé kúrò lórí ilẹ̀ ayé.
12 Desolation is left in the city, and calamity shall oppress the gates.
Ìlú ni a ti fi sílẹ̀ ní ahoro, ìlẹ̀kùn rẹ̀ ni a sì tì pa bámú bámú.
13 For it shall be thus in the midst of the earth, in the midst of the people, as if a few olives, that remain, should be shaken out of the olive tree: or grapes, when the vintage is ended.
Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí ní orí ilẹ̀ ayé àti láàrín àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a lu igi olifi, tàbí gẹ́gẹ́ bí i pàǹtí tí ó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí a kórè èso tán.
14 These shall lift up their voice, and shall give praise: when the Lord shall be glorified, they shall make a joyful noise from the sea.
Wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì hó fún ayọ̀; láti ìwọ̀-oòrùn ni wọn yóò ti polongo ọláńlá Olúwa.
15 Therefore glorify ye the Lord in instruction: the name of the Lord God of Israel in the islands of the sea.
Nítorí náà ní ìlà-oòrùn ẹ fi ògo fún Olúwa; gbé orúkọ Olúwa ga, àní Ọlọ́run Israẹli, ní àwọn erékùṣù ti inú Òkun.
16 From the ends of the earth we have heard praises, the glory of the just one. And I said: My secret to myself, my secret to myself, woe is me: the prevaricators have prevaricated, and with the prevarication of transgressors they have prevaricated.
Láti òpin ayé wá ni a ti gbọ́ orin; “Ògo ni fún olódodo n nì.” Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Mo ṣègbé, mo ṣègbé! “Ègbé ni fún mi! Alárékérekè dalẹ̀! Pẹ̀lú ìhàlẹ̀ ni àgàbàgebè fi dalẹ̀!”
17 Fear, and the pit, and the snare are upon thee, O thou inhabitant of the earth.
Ìpayà, isà òkú, àti ìdẹ̀kùn ń dúró dè ọ́, ìwọ ènìyàn ilẹ̀ ayé.
18 And it shall come to pass, that he that shall flee from the noise of the fear, shall fall into the pit: and he that shall rid himself out of the pit, shall be taken in the snare: for the flood-gates from on high are opened, and the foundations of the earth shall be shaken.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá nítorí ariwo ìpayà yóò ṣubú sínú ihò, ẹnikẹ́ni tí ó bá sì yọ́ jáde nínú ihò ni ìdẹ̀kùn yóò gbámú. Ibodè ọ̀run ti wà ní ṣíṣí sílẹ̀, ìpìlẹ̀ ayé mì tìtì.
19 With breaking shall the earth be broken, with crushing shall the earth be crushed, with trembling shall the earth be moved.
Ilẹ̀ ayé ti fọ́ ilẹ̀ ayé ti fọ́ dànù, a ti mi ilẹ̀ ayé rìrìrìrì.
20 With shaking shall the earth be shaken as a drunken man, and shall be removed as the tent of one night: and the iniquity thereof shall be heavy upon it, and it shall fell, and not rise again.
Ilẹ̀ ayé yí gbiri bí ọ̀mùtí, ó bì síwá sẹ́yìn bí ahéré nínú afẹ́fẹ́; ẹ̀bi ìṣọ̀tẹ̀ rẹ̀ ń pa á lẹ́rù tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣubú láìní lè dìde mọ́.
21 And it shall come to pass, that in that day the Lord shall visit upon the host of heaven on high, and upon the kings of the earth, on the earth.
Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò jẹ ẹ́ ní yà gbogbo agbára tí ó wà lókè lọ́run àti àwọn ọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé.
22 And they shall be gathered together as in the gathering of one bundle into the pit, and they shall be shut up there in prison: and after many days they shall be visited.
A ó sì kó wọn jọ pọ̀, gẹ́gẹ́ bí ará túbú jọ sínú ihò, a ó tì wọ́n mọ́ inú túbú, a ó sì bẹ̀ wọ́n wò lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
23 And the moon shall blush, and the sun shall be ashamed, when the Lord of hosts shall reign in mount Sion, and in Jerusalem, and shall be glorified in the sight of his ancients.
A ó rẹ òṣùpá sílẹ̀, ojú yóò sì ti oòrùn; nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò jẹ ọba ní orí òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu, àti níwájú àwọn àgbàgbà rẹ ní ògo.